< Esther 6 >

1 Ní òru ọjọ́ náà ọba kò le è sùn; nítorí náà, ó pàṣẹ kí wọn mú ìwé ìrántí wá, àkọsílẹ̀ ìjọba rẹ̀, wọ́n mú un wá wọ́n sì kà á sí létí.
در آن شب، خواب از پادشاه برفت و امرفرمود که کتاب تذکره تواریخ ایام رابیاورند تا آن را در حضور پادشاه بخوانند.۱
2 Wọ́n rí àkọsílẹ̀ níbẹ̀ pé Mordekai tí sọ àṣírí Bigitana àti Tereṣi, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà, tí wọ́n ń gbèrò láti pa ọba Ahaswerusi.
و درآن، نوشته‌ای یافتند که مردخای درباره بغتان وترش خواجه‌سرایان پادشاه و حافظان آستانه وی که قصد دست درازی بر اخشورش پادشاه کرده بودند، خبر داده بود.۲
3 Ọba béèrè pé, “Kí ni ọlá àti iyì tí Mordekai ti gbà fún èyí?” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dáhùn pé, “Kò tí ì sí ohun tí a ṣe fún un.”
و پادشاه پرسید که «چه حرمت و عزت به عوض این (خدمت ) به مردخای عطا شد؟» بندگان پادشاه که او را خدمت می‌کردند جواب دادند که «برای او چیزی نشد.»۳
4 Ọba wí pé, “Ta ni ó wà nínú àgbàlá?” Nísinsin yìí, Hamani ṣẹ̀ṣẹ̀ wọ àgbàlá ìta ààfin ni láti sọ fún ọba nípa síso Mordekai lórí igi tí ó ti rì fún un.
پادشاه گفت: «کیست در حیاط؟» (و هامان به حیاط بیرونی خانه پادشاه آمده بود تا به پادشاه عرض کند که مردخای را برداری که برایش حاضر ساخته بود مصلوب کنند. )۴
5 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dáhùn pé, “Hamani ni ó wà níbẹ̀ ó dúró sí inú àgbàlá.” Ọba pàṣẹ pé, “Ẹ mú un wọlé wá.”
و خادمان پادشاه وی را گفتند: «اینک هامان در حیاطایستاده است.» پادشاه فرمود تا داخل شود.۵
6 Nígbà tí Hamani wọlé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni kí a ṣe fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti bu ọlá fún?” Nísinsin yìí Hamani sì ro èyí fúnra rẹ̀ pé, “Ta ni ó wà níbẹ̀ tí ọba fẹ́ dá lọ́lá ju èmi lọ?”
و چون هامان داخل شد پادشاه وی را گفت: «با کسی‌که پادشاه رغبت دارد که او را تکریم نماید، چه باید کرد؟» و هامان در دل خود فکرکرد: «کیست غیر از من که پادشاه به تکریم نمودن او رغبت داشته باشد؟»۶
7 Nítorí náà Hamani dá ọba lóhùn pé, “Fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá,
پس هامان به پادشاه گفت: «برای شخصی که پادشاه به تکریم نمودن او رغبت دارد،۷
8 jẹ́ kí wọn kí ó mú aṣọ ọba èyí tí ọba ń wọ̀ àti ẹṣin tí ọba máa ń gùn, pẹ̀lú ọ̀kan lára adé ọba kí a fi dé e ní orí.
لباس ملوکانه را که پادشاه می‌پوشد و اسبی را که پادشاه بر آن سوار می‌شودو تاج ملوکانه‌ای را که بر سر او نهاده می‌شود، بیاورند.۸
9 Jẹ́ kí a fi aṣọ àti ẹṣin lé ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ọba tí ó ga jùlọ lọ́wọ́, kí wọn wọ aṣọ náà fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá, kí wọn sì sìn ín gun ẹṣin jákèjádò gbogbo ìgboro ìlú, kí wọn máa kéde níwájú rẹ̀ pé, ‘Èyí ni a ṣe fún ọkùnrin náà ẹni tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá!’”
و لباس و اسب را به‌دست یکی ازامرای مقرب ترین پادشاه بدهند و آن را به شخصی که پادشاه به تکریم نمودن او رغبت داردبپوشانند و بر اسب‌سوار کرده، و در کوچه های شهر بگردانند و پیش روی او ندا کنند که با کسی‌که پادشاه به تکریم نمودن او رغبت دارد، چنین کرده خواهد شد.»۹
10 Ọba pàṣẹ fún Hamani pé, “Lọ lẹ́sẹ̀kan náà. Mú aṣọ náà àti ẹṣin kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ṣe sọ fún Mordekai ará a Júù, ẹni tí ó jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba. Má ṣe fi ohunkóhun sílẹ̀ nínú ohun tí o ti yàn.”
آنگاه پادشاه به هامان فرمود: «آن لباس واسب را چنانکه گفتی به تعجیل بگیر و با مردخای یهود که در دروازه پادشاه نشسته است، چنین معمول دار و از هرچه گفتی چیزی کم نشود.»۱۰
11 Bẹ́ẹ̀ ni Hamani ṣe mú aṣọ àti ẹṣin náà. Ó fi wọ Mordekai, Mordekai sì wà lórí ẹṣin jákèjádò gbogbo ìgboro ìlú, ó sì ń kéde níwájú rẹ̀ pé, “Èyí ni a ó ṣe fún ọkùnrin náà ẹni tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá!”
پس هامان آن لباس و اسب را گرفت ومردخای را پوشانیده و او را سوار کرده، درکوچه های شهر گردانید و پیش روی او ندامی کرد که «با کسی‌که پادشاه به تکریم نمودن اورغبت دارد چنین کرده خواهد شد.»۱۱
12 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Mordekai padà sí ẹnu-ọ̀nà ọba. Ṣùgbọ́n Hamani sáré lọ ilé, ó sì bo orí rẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́,
ومردخای به دروازه پادشاه مراجعت کرد. اماهامان ماتم‌کنان و سرپوشیده، به خانه خودبشتافت.۱۲
13 Hamani sì sọ ohun gbogbo tí ó ṣẹlẹ̀ sí i fún Sereṣi ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Àwọn olùbádámọ̀ràn rẹ̀ àti ìyàwó o rẹ̀ sọ fún un pé, “Níwọ́n ìgbà tí Mordekai ti jẹ́ ẹ̀yà Júù, níwájú ẹni tí ìṣubú rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀, ìwọ kò lè rí ẹ̀yìn in rẹ̀—dájúdájú ìwọ yóò parun!”
و هامان به زوجه خود زرش و همه دوستان خویش، ماجرای خود را حکایت نمود وحکیمانش و زنش زرش او را گفتند: «اگر این مردخای که پیش وی آغاز افتادن نمودی از نسل یهود باشد، بر او غالب نخواهی آمد، بلکه البته پیش او خواهی افتاد.»۱۳
14 Bí wọ́n ṣe ń bá a sọ̀rọ̀, àwọn ìwẹ̀fà ọba wọlé, wọ́n sì kán Hamani lójú láti lọ sí ibi àsè tí Esteri ti pèsè.
و ایشان هنوز با اوگفتگو می‌کردند که خواجه‌سرایان پادشاه رسیدند تا هامان را به ضیافتی که استر مهیا ساخته بود، به تعجیل ببرند.۱۴

< Esther 6 >