< Esther 4 >

1 Nígbà tí Mordekai gbọ́ gbogbo nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì fi eérú kun ara, ó jáde lọ sí inú ìlú ó kígbe sókè ó sì sọkún kíkorò.
Kiedy Mardocheusz dowiedział się o wszystkim, co się stało, rozdarł swoje szaty i przyodział się w wór, następnie [posypał się] popiołem, wyszedł na środek miasta i lamentował głośno i gorzko.
2 Ṣùgbọ́n ó lọ sí ẹnu-ọ̀nà ọba nìkan, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wọ aṣọ ọ̀fọ̀ tì a gbà láààyè láti wọ ibẹ̀.
I doszedł aż do bramy królewskiej, gdyż nie wolno było wejść w bramę królewską przyodzianemu w wór.
3 Ní gbogbo ìgbèríko tí àṣẹ ikú ọba dé, ọ̀fọ̀ ńlá dé bá àwọn Júù, pẹ̀lú àwẹ̀, ẹkún àti ìpohùnréré ẹkún. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wà nínú aṣọ ọ̀fọ̀ tí wọ́n fi eérú kúnra.
W każdej prowincji, gdzie tylko dotarł rozkaz króla i jego dekret, [nastała] wielka żałoba wśród Żydów, nastał też post, płacz i lament, a wielu leżało w worze i w popiele.
4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ìwẹ̀fà Esteri wá, wọ́n sọ nípa Mordekai fún un, ayaba sì wà nínú ìbànújẹ́ ńlá. Ó fi aṣọ ránṣẹ́ sí i kí ó wọ̀ ọ́ dípò aṣọ ọ̀fọ̀ tí ó wọ̀, ṣùgbọ́n òun kò gbà wọ́n.
Przyszły więc służące Estery i jej eunuchowie i opowiedzieli jej [o tym]. Wtedy królowa bardzo się zasmuciła i posłała szaty, aby ubrać Mardocheusza i zdjąć z niego wór. Ale [on ich] nie przyjął.
5 Nígbà náà ni Esteri pe Hataki, ọ̀kan nínú àwọn ìwẹ̀fà ọba tí a yàn láti máa jíṣẹ́ fún un, ó pàṣẹ fún un pé kí ó béèrè ohun tí ó ń dààmú Mordekai àti ohun tí ó ṣe é.
Wtedy Estera zawołała Hataka, [jednego] z eunuchów króla, którego on dał jej do posługi, i rozkazała mu pójść do Mardocheusza, aby się dowiedział, co to ma znaczyć i dlaczego tak się stało.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Hataki jáde lọ bá Mordekai ní ìta gbangba ìlú níwájú ẹnu-ọ̀nà ọba.
Wyszedł więc Hatak do Mardocheusza na plac miejski, który był przed bramą królewską;
7 Mordekai sọ ohun gbogbo tí ó ṣẹlẹ̀ fún un, papọ̀ pẹ̀lú iye owó tí Hamani ti ṣe ìpinnu láti san sínú àpò ìṣúra ọba fún ìparun àwọn Júù.
I Mardocheusz opowiedział mu wszystko, co mu się przydarzyło, także o sumie srebra, którą Haman obiecał odważyć do skarbca królewskiego za Żydów, aby zostali wytraceni.
8 Ó sì tún fún un ní ọ̀kan lára ìwé tí ó gbé jáde fún ìparun wọn, èyí tí a tẹ̀ jáde ní Susa, láti fihan Esteri kí ó sì ṣe àlàyé e rẹ̀ fún un, ó sì sọ fún un pé kí ó bẹ̀ ẹ́ kí ó lọ síwájú ọba láti bẹ̀bẹ̀ fún àánú, kí ó bẹ̀bẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ponadto dał mu odpis dekretu o ich zagładzie, który ogłoszono w Suzie, aby pokazał [go] Esterze, powiadomił ją i rozkazał, aby poszła do króla, błagając go o swój lud i wstawiając się za nim.
9 Hataki padà ó sì lọ ṣàlàyé fún Esteri ohun tí Mordekai sọ.
Przyszedł więc Hatak i przekazał Esterze słowa Mardocheusza.
10 Nígbà náà ni Esteri pàṣẹ fún Hataki pé kí ó sọ fún Mordekai,
I Estera odpowiedziała Hatakowi i poleciła mu iść do Mardocheusza:
11 “Gbogbo àwọn ìjòyè ọba àti àwọn ènìyàn agbègbè ìjọba rẹ̀ mọ̀ wí pé: fún ẹnikẹ́ni ọkùnrin tàbí obìnrin kan tàbí tí ó bá bá ọba sọ̀rọ̀ láìjẹ́ pé a ránṣẹ́ pè é (ọba ti gbé òfin kan kalẹ̀ pé) kíkú ni yóò kú. Ohun kan tí ó le yẹ èyí ni pé, kí ọba na ọ̀pá wúrà rẹ̀ sí i kí ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí. Ṣùgbọ́n, ọgbọ̀n ọjọ́ ti kọjá tí a ti pè mí láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba.”
Wszyscy słudzy króla oraz lud z prowincji królewskich wiedzą, że ktokolwiek – mężczyzna lub kobieta – wejdzie do króla na dziedziniec wewnętrzny, nie będąc wezwany, podlega tylko jednemu prawu – ma zostać zabity, z wyjątkiem tego, nad którym król wyciągnie złote berło, ten zostanie przy życiu. Ale mnie nie wezwano, aby wejść do króla, już od trzydziestu dni.
12 Nígbà tí a sọ ọ̀rọ̀ Esteri fún Mordekai,
I powiedziano Mardocheuszowi słowa Estery.
13 nígbà náà ni Mordekai sọ kí a dá Esteri lóhùn pé, “Má ṣe rò nínú ara rẹ pé nítorí pé ìwọ wà ní ilé ọba ìwọ nìkan là láàrín gbogbo àwọn Júù.
Wtedy Mardocheusz polecił przekazać Esterze taką odpowiedź: Nie myśl sobie, że ty jedna spośród wszystkich Żydów ocalejesz w domu królewskim.
14 Nítorí bí ìwọ bá dákẹ́ ní àkókò yìí, ìrànlọ́wọ́ àti ìtúsílẹ̀ fún àwọn Júù yóò dìde láti ibòmíràn, ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ìdílé baba à rẹ yóò ṣègbé. Ta ni ó mọ̀ wí pé nítorí irú àkókò yìí ni o ṣe wà ní ipò ayaba?”
Jeśli bowiem ty całkowicie będziesz milczeć w tym czasie, uwolnienie i wybawienie dla Żydów przyjdzie z innego miejsca, ale ty i dom twego ojca zginiecie. A kto wie, czy nie na tę właśnie chwilę dostąpiłaś godności królestwa?
15 Nígbà náà ni Esteri rán iṣẹ́ yìí sí Mordekai:
Estera poleciła, by odpowiedziano Mardocheuszowi:
16 “Lọ, kí o kó gbogbo àwọn Júù tí ó wà ní Susa jọ, kí ẹ sì gbààwẹ̀ fún mi. Ẹ má ṣe jẹun tàbí omi fún ọjọ́ mẹ́ta, ní òru àti ní ọ̀sán. Èmi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi náà yóò gbààwẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin náà ti ṣe. Nígbà tí ẹ bá ṣe èyí, èmi yóò tọ ọba lọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lòdì sí òfin. Bí mo bá sì ṣègbé, mo ṣègbé.”
Idź, zbierz wszystkich Żydów, którzy się znajdują w Suzie, i pośćcie za mnie, nie jedzcie ani nie pijcie przez trzy dni, nocą i dniem. Ja także i moje służące będziemy pościć, a potem wejdę do króla, choć to niezgodne z prawem. A jeśli zginę, to zginę.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Mordekai lọ, ó sì sọ gbogbo ohun tí Esteri pàṣẹ fún un.
Poszedł więc Mardocheusz i uczynił wszystko, co mu rozkazała Estera.

< Esther 4 >