< Esther 4 >

1 Nígbà tí Mordekai gbọ́ gbogbo nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì fi eérú kun ara, ó jáde lọ sí inú ìlú ó kígbe sókè ó sì sọkún kíkorò.
A Mardocheusz, dowiedziawszy się wszystkiego, co się było stało, rozdarł szaty swe, i oblekł się w wór, a posypawszy się popiołem, wyszedł w pośród miasta, i wołał głosem wielkim i żałośnym.
2 Ṣùgbọ́n ó lọ sí ẹnu-ọ̀nà ọba nìkan, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wọ aṣọ ọ̀fọ̀ tì a gbà láààyè láti wọ ibẹ̀.
I przyszedł aż przed bramę królewską; bo się nie godziło wnijść w bramę królewską obleczonemu w wór.
3 Ní gbogbo ìgbèríko tí àṣẹ ikú ọba dé, ọ̀fọ̀ ńlá dé bá àwọn Júù, pẹ̀lú àwẹ̀, ẹkún àti ìpohùnréré ẹkún. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wà nínú aṣọ ọ̀fọ̀ tí wọ́n fi eérú kúnra.
W każdej także krainie i miejscu, gdziekolwiek rozkazanie królewskie, i wyrok jego przyszedł, była wielka żałość między Żydami, post, i płacz, i narzekanie, a w worze, i na popiele wiele ich leżało.
4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ìwẹ̀fà Esteri wá, wọ́n sọ nípa Mordekai fún un, ayaba sì wà nínú ìbànújẹ́ ńlá. Ó fi aṣọ ránṣẹ́ sí i kí ó wọ̀ ọ́ dípò aṣọ ọ̀fọ̀ tí ó wọ̀, ṣùgbọ́n òun kò gbà wọ́n.
Przetoż przyszedłszy panny Estery, i komornicy jej, oznajmili jej to; i zasmuciła się królowa bardzo i posłała szaty, aby obleczono Mardocheusza, zdjąwszy z niego wór jego. Ale ich on nie przyjął.
5 Nígbà náà ni Esteri pe Hataki, ọ̀kan nínú àwọn ìwẹ̀fà ọba tí a yàn láti máa jíṣẹ́ fún un, ó pàṣẹ fún un pé kí ó béèrè ohun tí ó ń dààmú Mordekai àti ohun tí ó ṣe é.
Tedy zawoławszy Estera Atacha, jednego z komorników królewskich, którego jej był dał za sługę, rozkazała mu z strony Mardocheusza, aby się dowiedział, co i przeczby to było.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Hataki jáde lọ bá Mordekai ní ìta gbangba ìlú níwájú ẹnu-ọ̀nà ọba.
Wyszedł tedy Atach do Mardocheusza na ulicę miejską, która była przed bramą królewską;
7 Mordekai sọ ohun gbogbo tí ó ṣẹlẹ̀ fún un, papọ̀ pẹ̀lú iye owó tí Hamani ti ṣe ìpinnu láti san sínú àpò ìṣúra ọba fún ìparun àwọn Júù.
I oznajmił mu Mardocheusz wszystko, co mu się przydało, i o tej sumie srebra, którą obiecał Haman odważyć do skarbu królewskiego przeciwko Żydom, aby byli wytraceni.
8 Ó sì tún fún un ní ọ̀kan lára ìwé tí ó gbé jáde fún ìparun wọn, èyí tí a tẹ̀ jáde ní Susa, láti fihan Esteri kí ó sì ṣe àlàyé e rẹ̀ fún un, ó sì sọ fún un pé kí ó bẹ̀ ẹ́ kí ó lọ síwájú ọba láti bẹ̀bẹ̀ fún àánú, kí ó bẹ̀bẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀.
Nadto dał mu przepis wyroku, który był przybity w Susan na wytracenie ich, aby okazał Esterze, i oznajmił jej; a żeby jej rozkazał, aby szła do króla, i prosiła go, a przyczyniła się do niego za ludem swoim.
9 Hataki padà ó sì lọ ṣàlàyé fún Esteri ohun tí Mordekai sọ.
Tedy przyszedłszy Atach oznajmił Esterze słowa Mardocheuszowe.
10 Nígbà náà ni Esteri pàṣẹ fún Hataki pé kí ó sọ fún Mordekai,
I rzekła Estera do Atacha, wskazując przezeń do Mardocheusza:
11 “Gbogbo àwọn ìjòyè ọba àti àwọn ènìyàn agbègbè ìjọba rẹ̀ mọ̀ wí pé: fún ẹnikẹ́ni ọkùnrin tàbí obìnrin kan tàbí tí ó bá bá ọba sọ̀rọ̀ láìjẹ́ pé a ránṣẹ́ pè é (ọba ti gbé òfin kan kalẹ̀ pé) kíkú ni yóò kú. Ohun kan tí ó le yẹ èyí ni pé, kí ọba na ọ̀pá wúrà rẹ̀ sí i kí ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí. Ṣùgbọ́n, ọgbọ̀n ọjọ́ ti kọjá tí a ti pè mí láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba.”
Wszyscy słudzy królewscy, i lud krain królewskich wiedzą, że ktobykolwiek (mąż albo biała głowa) wszedł do króla do sieni wnętrznej, nie będąc wezwany, to prawo o nim jest, aby był zabity, oprócz na kogoby wyciągnął król sceptr złoty, ten żyw z ostanie. Alem ja nie była wezwana, abym weszła do króla, już przez trzydzieści dni.
12 Nígbà tí a sọ ọ̀rọ̀ Esteri fún Mordekai,
A gdy oznajmiono Mardocheuszowi słowa Estery.
13 nígbà náà ni Mordekai sọ kí a dá Esteri lóhùn pé, “Má ṣe rò nínú ara rẹ pé nítorí pé ìwọ wà ní ilé ọba ìwọ nìkan là láàrín gbogbo àwọn Júù.
Rzekł Mardocheusz, aby zasię powiedziano Esterze: Nie mniemaj w umyśle twoim, abyś zachowana być miała w domu królewskim mimo wszystkich Żydów.
14 Nítorí bí ìwọ bá dákẹ́ ní àkókò yìí, ìrànlọ́wọ́ àti ìtúsílẹ̀ fún àwọn Júù yóò dìde láti ibòmíràn, ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ìdílé baba à rẹ yóò ṣègbé. Ta ni ó mọ̀ wí pé nítorí irú àkókò yìí ni o ṣe wà ní ipò ayaba?”
Albowiem, jeźli ty tak cale milczeć będziesz na ten czas, ulżenie i wybawienie przyjdzie Żydom skąd inąd, ale ty i dom ojca twego zginiecie; a któż wie, jeźliś nie dla tego czasu dostąpiła królestwa?
15 Nígbà náà ni Esteri rán iṣẹ́ yìí sí Mordekai:
I rzekła Estera, aby zasię oznajmiono Mardocheuszowi:
16 “Lọ, kí o kó gbogbo àwọn Júù tí ó wà ní Susa jọ, kí ẹ sì gbààwẹ̀ fún mi. Ẹ má ṣe jẹun tàbí omi fún ọjọ́ mẹ́ta, ní òru àti ní ọ̀sán. Èmi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi náà yóò gbààwẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin náà ti ṣe. Nígbà tí ẹ bá ṣe èyí, èmi yóò tọ ọba lọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lòdì sí òfin. Bí mo bá sì ṣègbé, mo ṣègbé.”
Idź, zbierz wszystkich Żydów, którzy się znajdują w Susan, a pośćcie za mię, a nie jedzcie ani pijcie przez trzy dni, w nocy ani we dnie. Ja też, i panny moje także, będę pościła; tedy wnijdę do króla, choć to nie według prawa, a jeźli zginę, niech zginę.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Mordekai lọ, ó sì sọ gbogbo ohun tí Esteri pàṣẹ fún un.
Tedy szedł Mardocheusz, i uczynił wszystko, co mu była rozkazała Estera.

< Esther 4 >