< Esther 3 >

1 Lẹ́yìn àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí, ọba Ahaswerusi dá Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi lọ́lá, ọba gbé e ga, ó si fún un ní àga ọlá tí ó ju ti gbogbo àwọn ọlọ́lá tókù lọ.
Aftir these thingis kyng Assuerus enhaunside Aaman, the sone of Amadathi, that was of the kynrede of Agag, and settide his trone aboue alle the princes whiche he hadde.
2 Gbogbo àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ọba wọn kúnlẹ̀ wọ́n sì fi ọlá fun Hamani, nítorí ọba ti pàṣẹ èyí nípa tirẹ̀. Ṣùgbọ́n Mordekai kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún un.
And alle the seruauntis of the kyng, that lyuyden in the yatis of the paleis, kneliden, and worschipiden Aaman; for the emperour hadde comaundid so to hem; Mardochee aloone bowide not the knees, nethir worschipide hym.
3 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà béèrè lọ́wọ́ Mordekai pé, “Èéṣe tí ìwọ kò ṣe pa àṣẹ ọba mọ́.”
`To whom the children of the kyng seiden, that saten bifore at the yatis of the paleis, Whi kepist `thou not the comaundementis of the kyng, othere wise than othere men?
4 Ní ojoojúmọ́ ni wọ́n máa n sọ fún un ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti ṣe bẹ́ẹ̀. Nítorí náà, wọ́n sọ fún Hamani nípa rẹ̀ láti wò ó bóyá ó lè gba irú ìwà tí Mordekai ń hù yìí, nítorí tí ó ti sọ fún wọn pé Júù ni òun.
And whanne thei seiden ful ofte these thingis, and he nolde here, thei tolden to Aaman, `and wolden wite, whether he contynuede in sentence; for he hadde seid to hem, that he was a Jew.
5 Nígbà tí Hamani rí i pé Mordekai kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún òun, ó bínú.
And whanne Aaman hadde herd this thing, and hadde preued `bi experience, that Mardochee bowide not the kne to hym, nethir worschipide hym, he was ful wrooth,
6 Síbẹ̀ kò mọ irú ènìyàn tí Mordekai jẹ́, ó kẹ́gàn láti pa Mordekai nìkan. Dípò bẹ́ẹ̀ Hamani ń wá láti pa gbogbo ènìyàn Mordekai run, àwọn Júù jákèjádò gbogbo ìjọba Ahaswerusi.
and he ledde for nouyt to sette hise hondis on Mardochee aloone; for he hadde herd, that Mardochee was of the folc of Jewis, and more he wolde leese al the nacioun of Jewis, that weren in the rewme of Assuerus.
7 Ní ọdún kejìlá ọba Ahaswerusi, ní oṣù kìn-ín-ní, èyí ni oṣù Nisani, wọ́n da puri (èyí tí í ṣe, ìbò) ní iwájú Hamani láti yan ọjọ́ kan àti oṣù, ìbò náà sì wáyé ní oṣù kejìlá, oṣù Addari.
In the firste monethe, whos nam is Nysan, in the tweluethe yeer of the rewme of Assuerus, lot was sent in to a vessel, which lot is seid in Ebrew phur, `bifor Aaman, in what dai and in what monethe the folk of Jewis ouyte to be slayn; and the tweluethe monethe yede out, which is clepid Adar.
8 Nígbà náà ni Hamani sọ fún ọba Ahaswerusi pé, “Àwọn ènìyàn kan wà tí wọ́n fọ́nká tí wọ́n sì túká ní ara àwọn ènìyàn ní gbogbo àgbáyé ìjọba rẹ̀ tí ìṣe wọn yàtọ̀ sí ti gbogbo àwọn tókù tí wọn kò sì pa òfin ọba mọ́; èyí kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti gbà fún wọn bẹ́ẹ̀.
And Aaman seide to the king Assuerus, A puple is scaterid bi alle the prouynces of thi rewme, and is departid fro it silf togidere, and vsith newe lawis and cerymonyes, and ferthermore it dispisith also the comaundementis of the kyng; and thou knowest best, that it spedith not to thi rewme, `that it encreesse in malice bi licence.
9 Tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, kí a gbé òfin kan jáde tí yóò pa wọ́n run, èmi yóò sì fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà sínú ìṣúra ọba fún àwọn ọkùnrin tí wọn o ṣe iṣẹ́ náà.”
If it plesith thee, `deme thou that it perisch, and Y schal paie ten thousynde of talentis to the keperis of thi tresour.
10 Nítorí náà, ọba sì bọ́ òrùka èdìdì tí ó wà ní ìka rẹ̀, ó sì fi fún Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, ọ̀tá àwọn Júù.
Therfor the kyng took `fro his hond the ryng which he vside, and yaf it to Aaman, the sone of Amadathi, of the kynrede of Agag, to the enemy of Jewis.
11 Ọba sọ fún Hamani pé, “Pa owó náà mọ́, kí o sì ṣe ohun tí ó wù ọ́ fún àwọn ènìyàn náà.”
And the kyng seide to hym, The siluer, which thou bihiytist, be thin; do thou of the puple that, that plesith thee.
12 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹtàlá oṣù kìn-ín-ní àkọ́kọ́, wọ́n pe àwọn akọ̀wé ọba jọ. Wọ́n kọ ọ́ ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé, ó kọ̀wé sí àwọn ènìyàn kọ̀ọ̀kan ní èdè wọn gbogbo èyí tí Hamani ti pàṣẹ sí àwọn akọ̀wé ọba, sí baálẹ̀ ìgbèríko kọ̀ọ̀kan àti àwọn ọlọ́lá àwọn onírúurú ènìyàn. A kọ èyí ní orúkọ ọba Ahaswerusi fúnra rẹ̀ ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀.
And the scryuens of the kyng weren clepid in the firste monethe Nysan, in the threttenthe dai of the same monethe; and it was writun, as Aaman hadde comaundid, to alle prynces of the kyng, and to domesmen of prouynces and of dyuerse folkis, that ech folk myyte rede and here, `for dyuersite of langagis, bi the name of kyng Assuerus. And lettris aseelid with
13 A sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìgbèríko ọba pẹ̀lú àṣẹ láti parun, láti pa gbogbo àwọn Júù èwe àti àgbà, obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́—ní ọjọ́ kan kí wọn sì parẹ́, ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kejìlá, oṣù Addari kí a sì kó àwọn ohun ìní wọn.
the ring of the kyng weren sent bi the corouris of the kyng to alle hise prouynces, that thei schulden sle, and `do awei alle Jewis, fro a child to an eld man, litle children and wymmen, in o dai, that is, in the thrittenthe dai of the tweluethe monethe, which is clepid Adar; and that thei schulden take awei the goodis of Jewis.
14 Kí ẹ mú àdàkọ ìwé náà kí a tẹ̀ ẹ́ jáde bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ó sì di mí mọ̀ fún àwọn ènìyàn ìlú nítorí kí wọ́n le múra fún ọjọ́ náà.
Forsothe the sentence `in schort of the pistlis was this, that alle prouyncis schulden wite, and make hem redi to the forseid dai.
15 Àwọn ìránṣẹ́ náà sì jáde, wọ́n tẹ̀síwájú nípa àṣẹ ọba, ìkéde náà sì jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa. Ọba àti Hamani jókòó wọ́n ń mu, ṣùgbọ́n ìlú Susa wà nínú ìdààmú.
And the coroures, that weren sent, hastiden to fille the comaundement of the kyng; and anoon the comaundement hangide in Susa, `while the kyng and Aaman maden feeste, and `the while that alle Jewis wepten, that weren in the citee.

< Esther 3 >