< Esther 3 >

1 Lẹ́yìn àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí, ọba Ahaswerusi dá Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi lọ́lá, ọba gbé e ga, ó si fún un ní àga ọlá tí ó ju ti gbogbo àwọn ọlọ́lá tókù lọ.
After - the things these he made great the king Ahasuerus Haman [the] son of Hammedatha the Agagite and he exalted him and he placed seat his above all the officials who [were] with him.
2 Gbogbo àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ọba wọn kúnlẹ̀ wọ́n sì fi ọlá fun Hamani, nítorí ọba ti pàṣẹ èyí nípa tirẹ̀. Ṣùgbọ́n Mordekai kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún un.
And all [the] servants of the king who [were] at [the] gate of the king [were] kneeling and bowing down to Haman for thus he had commanded to him the king and Mordecai not he knelt and not he bowed down.
3 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà béèrè lọ́wọ́ Mordekai pé, “Èéṣe tí ìwọ kò ṣe pa àṣẹ ọba mọ́.”
And they said [the] servants of the king who [were] at [the] gate of the king to Mordecai why? [are] you transgressing [the] commandment of the king.
4 Ní ojoojúmọ́ ni wọ́n máa n sọ fún un ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti ṣe bẹ́ẹ̀. Nítorí náà, wọ́n sọ fún Hamani nípa rẹ̀ láti wò ó bóyá ó lè gba irú ìwà tí Mordekai ń hù yìí, nítorí tí ó ti sọ fún wọn pé Júù ni òun.
And it was (just as spoke they *Q(K)*) to him a day and a day and not he listened to them and they told to Haman to see ¿ will they stand [the] words of Mordecai that he had told to them that he [was] a Jew.
5 Nígbà tí Hamani rí i pé Mordekai kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún òun, ó bínú.
And he saw Haman that not Mordecai [was] kneeling and bowing down to him and he was filled Haman rage.
6 Síbẹ̀ kò mọ irú ènìyàn tí Mordekai jẹ́, ó kẹ́gàn láti pa Mordekai nìkan. Dípò bẹ́ẹ̀ Hamani ń wá láti pa gbogbo ènìyàn Mordekai run, àwọn Júù jákèjádò gbogbo ìjọba Ahaswerusi.
And he despised in view his to stretch out a hand on Mordecai to only him if people had told to him [the] people of Mordecai and he sought Haman to annihilate all the Jews who [were] in all [the] kingdom of Ahasuerus [the] people of Mordecai.
7 Ní ọdún kejìlá ọba Ahaswerusi, ní oṣù kìn-ín-ní, èyí ni oṣù Nisani, wọ́n da puri (èyí tí í ṣe, ìbò) ní iwájú Hamani láti yan ọjọ́ kan àti oṣù, ìbò náà sì wáyé ní oṣù kejìlá, oṣù Addari.
In the month first that [is] [the] month of Nisan in year two [plus] ten of the king Ahasuerus someone cast Pur it [is] the lot before Haman from day - to day and from month to month (and it fell the lot on three [plus] ten day of month *X*) two [plus] ten that [is] [the] month of Adar.
8 Nígbà náà ni Hamani sọ fún ọba Ahaswerusi pé, “Àwọn ènìyàn kan wà tí wọ́n fọ́nká tí wọ́n sì túká ní ara àwọn ènìyàn ní gbogbo àgbáyé ìjọba rẹ̀ tí ìṣe wọn yàtọ̀ sí ti gbogbo àwọn tókù tí wọn kò sì pa òfin ọba mọ́; èyí kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti gbà fún wọn bẹ́ẹ̀.
And he said Haman to the king Ahasuerus there it [is] a people one scattered and separated among the peoples in all [the] provinces of kingdom your and laws their [are] differing from every people and [the] laws of the king not they [are] doing and for the king not [is] appropriate to let remain them.
9 Tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, kí a gbé òfin kan jáde tí yóò pa wọ́n run, èmi yóò sì fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà sínú ìṣúra ọba fún àwọn ọkùnrin tí wọn o ṣe iṣẹ́ náà.”
If [is] on the king good let it be written to destroy them and ten thousand talent[s] of silver I will weigh out on [the] hands of [the] doers of the work to bring [it] into [the] treasuries of the king.
10 Nítorí náà, ọba sì bọ́ òrùka èdìdì tí ó wà ní ìka rẹ̀, ó sì fi fún Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, ọ̀tá àwọn Júù.
And he removed the king signet-ring his from on hand his and he gave it to Haman [the] son of Hammedatha the Agagite [the] opposer of the Jews.
11 Ọba sọ fún Hamani pé, “Pa owó náà mọ́, kí o sì ṣe ohun tí ó wù ọ́ fún àwọn ènìyàn náà.”
And he said the king to Haman the silver [is] given to you and the people to do with it according to the good in view your.
12 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹtàlá oṣù kìn-ín-ní àkọ́kọ́, wọ́n pe àwọn akọ̀wé ọba jọ. Wọ́n kọ ọ́ ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé, ó kọ̀wé sí àwọn ènìyàn kọ̀ọ̀kan ní èdè wọn gbogbo èyí tí Hamani ti pàṣẹ sí àwọn akọ̀wé ọba, sí baálẹ̀ ìgbèríko kọ̀ọ̀kan àti àwọn ọlọ́lá àwọn onírúurú ènìyàn. A kọ èyí ní orúkọ ọba Ahaswerusi fúnra rẹ̀ ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀.
And they were summoned [the] scribes of the king in the month first on thir-teenth day in it and it was written according to all that he commanded Haman to [the] satraps of the king and to the governors who - [were] over province and province and to [the] officials of people and people province and province according to writing its and people and people according to language its in [the] name of the king Ahasuerus [it was] written and [it was] sealed with [the] signet-ring of the king.
13 A sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìgbèríko ọba pẹ̀lú àṣẹ láti parun, láti pa gbogbo àwọn Júù èwe àti àgbà, obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́—ní ọjọ́ kan kí wọn sì parẹ́, ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kejìlá, oṣù Addari kí a sì kó àwọn ohun ìní wọn.
And they were sent documents by [the] hand of the runners to all [the] provinces of the king to annihilate to kill and to destroy all the Jews from young man and unto old [man] little one[s] and women on a day one on [day] thir-teen of month two [plus] ten that [is] [the] month of Adar and spoil their to take as plunder.
14 Kí ẹ mú àdàkọ ìwé náà kí a tẹ̀ ẹ́ jáde bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ó sì di mí mọ̀ fún àwọn ènìyàn ìlú nítorí kí wọ́n le múra fún ọjọ́ náà.
copy of The writing [was] to be given law in every province and province [was] disclosed to all the peoples to be ready for the day this.
15 Àwọn ìránṣẹ́ náà sì jáde, wọ́n tẹ̀síwájú nípa àṣẹ ọba, ìkéde náà sì jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa. Ọba àti Hamani jókòó wọ́n ń mu, ṣùgbọ́n ìlú Susa wà nínú ìdààmú.
The runners they went out being hasty at [the] word of the king and the law it was given in Susa the citadel and the king and Haman they sat down to drink and the city of Susa it was in confusion.

< Esther 3 >