< Ephesians 1 >

1 Paulu, aposteli Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, Sí àwọn ènìyàn mímọ́ tí ó wà ní Efesu, àti sí àwọn olóòtítọ́ nínú Kristi Jesu:
Paweł, Apostoł Jezusa Chrystusa przez wolę Bożą, świętym, którzy są w Efezie, i wiernym w Chrystusie Jezusie.
2 Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wá àti Jesu Kristi Olúwa.
Łaska wam i pokój niech będzie od Boga, Ojca naszego, i Pana Jezusa Chrystusa.
3 Ògo ni fún Ọlọ́run àti Baba Jesu Kristi Olúwa wa, ẹni tí ó ti bùkún wa láti inú ọ̀run wá pẹ̀lú àwọn ìbùkún ẹ̀mí gbogbo nínú Kristi.
Błogosławiony niech będzie Bóg i Ojciec Pana naszego Jezusa Chrystusa, który nas ubłogosławił wszelkiem błogosławieństwem duchownem w niebieskich rzeczach w Chrystusie;
4 Àní, gẹ́gẹ́ bí o ti yàn wá nínú rẹ̀ ṣáájú ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, láti jẹ́ mímọ́ àti aláìlábùkù níwájú rẹ̀ nínú ìfẹ́
Jako nas wybrał w nim przed założeniem świata, abyśmy byli świętymi i nienaganionymi przed oblicznością jego w miłości.
5 ẹni tí ò ti yàn wá tẹ́lẹ̀ sí ìsọdọmọ nípa Jesu Kristi fún ara rẹ̀, ní ìbámu ìdùnnú ìfẹ́ rẹ̀,
Który nas przenaznaczył ku przysposobieniu za synów przez Jezusa Chrystusa dla siebie samego, według upodobania woli swojej,
6 fún ìyìn ògo oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, èyí tí ò ti fi fún wa nínú Àyànfẹ́ rẹ̀.
Ku chwale sławnej łaski swojej, którą nas udarował w onym umiłowanym:
7 Nínú rẹ̀ ni àwa rí ìràpadà gba nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ àti ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ní ìbámu pẹ̀lú ọrọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run
W którym mamy odkupienie przez krew jego, to jest odpuszczenie grzechów, według bogactwa łaski jego,
8 èyí tí ó fún wa lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọgbọ́n àti ìmòye,
Którą hojnie pokazał przeciwko nam we wszelkiej mądrości i roztropności.
9 Ó ti sọ ohun ìjìnlẹ̀ ìfẹ́ rẹ̀ di mí mọ̀ fún wa gẹ́gẹ́ bí ìdùnnú rere rẹ̀, èyí ti o pinnu nínú Kristi,
Oznajmiwszy nam tajemnicę woli swojej według upodobania swego, które był postanowił w samym sobie;
10 èyí tí yóò jẹ jáde ní kíkún àkókò, láti ṣe àkójọpọ̀ àwọn ohun tí ọ̀run àti ti ayé lábẹ́ Kristi.
Aby w rozrządzeniu zupełności czasów w jedno zgromadził wszystkie rzeczy w Chrystusie, i te, które są na niebiesiech, i te, które są na ziemi;
11 Nínú rẹ̀ ni a yàn wá fẹ́ lẹ́yìn tí ó ti yàn wá tẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu ẹni tí ń ṣiṣẹ́ ohun gbogbo ní ìbámu ìfẹ́ rẹ̀,
W nim, mówię, w którymeśmy i do działu przypuszczeni, przenaznaczeni będąc według postanowienia tego, który sprawuje wszystko według rady woli swojej;
12 kí àwa kí ó le wà fún ìyìn ògo rẹ̀, àwa tí a ti ni ìrètí ṣáájú nínú Kristi.
Abyśmy my byli ku chwale sławy jego, którzyśmy pierwej nadzieję mieli w Chrystusie,
13 Àti ẹ̀yin pẹ̀lú darapọ̀ nínú Kristi nígbà tí ẹ̀yin gbọ́ ọ̀rọ̀ òtítọ́ náà àní ìyìnrere ìgbàlà yin. Nígbà tí ẹ̀yin gbàgbọ́, a fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe èdìdì ayé yin nínú rẹ, èyí tí a ti ṣe ìlérí rẹ̀ tẹ́lẹ̀,
W którym i wy nadzieję macie, usłyszawszy słowo prawdy, to jest Ewangieliję zbawienia waszego, przez którą też uwierzywszy, jesteście zapieczętowani Duchem onym Świętym obiecanym,
14 èyí tí ó jẹ́ ìdánilójú àṣansílẹ̀ ogún wa títí yóò fi di àkókò ìràpadà àwọn tí í ṣe ti Ọlọ́run sí ìyìn ògo rẹ̀.
Który jest zadatkiem dziedzictwa naszego na wykupienie nabytej własności, ku chwale sławy jego.
15 Nítorí ìdí èyí, nígbà tí mo ti gbúròó ìgbàgbọ́ ti ń bẹ láàrín yín nínú Jesu Olúwa, àti ìfẹ́ yín sí gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
Przetoż i ja usłyszawszy o tej wierze, którą macie w Panu Jezusie, i o miłości ku wszystkim świętym,
16 Èmi kò sì sinmi láti máa dúpẹ́ nítorí yín, àti láti máa rántí yín nínú àdúrà mi.
Nie przestaję dziękować za was, wzmiankę czyniąc o was w modlitwach moich,
17 Mo sì ń béèrè nígbà gbogbo pé kí Ọlọ́run Jesu Kristi Olúwa wa, Baba ògo, lè fún yín ni Ẹ̀mí nípa ti ọgbọ́n àti ti ìfihàn kí ẹ̀yin kí ó tún lè mọ̀ ọ́n sí i.
Aby Bóg Pana naszego Jezusa Chrystusa, Ojciec on chwały, dał wam Ducha mądrości i objawienia ku poznaniu samego siebie;
18 Mo tún ń gbàdúrà bákan náà wí pé kí ojú ọkàn yín lè mọ́lẹ̀; kí ẹ̀yin lè mọ ohun tí ìrètí ìpè rẹ̀ jẹ́, àti ọrọ̀ ògo rẹ̀ èyí tí í ṣe ogún àwọn ènìyàn mímọ́,
Ażeby oświecił oczy myśli waszej, abyście wiedzieli, która jest nadzieja powołania jego i które jest bogactwo chwały dziedzictwa jego w świętych;
19 àti aláìlẹ́gbẹ́ títóbi agbára rẹ̀ fún àwa tí a gbàgbọ́. Gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ agbára rẹ̀,
I która jest ona przewyższająca wielkość mocy jego przeciwko nam, którzy wierzymy według skutecznej mocy siły jego,
20 èyí tí ó fi sínú Kristi, nígbà tí o ti jí dìde kúrò nínú òkú, tí ó sì mú un jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún nínú àwọn ọ̀run.
Której dokazał w Chrystusie, gdy go wzbudził od umarłych i posadził na prawicy swojej na niebiesiech,
21 Ó gbéga ju gbogbo ìjọba, àti àṣẹ, àti agbára, àti òye àti gbogbo orúkọ tí a ń dá, kì í ṣe ni ayé yìí nìkan, ṣùgbọ́n ni èyí tí ń bọ̀ pẹ̀lú. (aiōn g165)
Wysoko nad wszystkie księstwa i zwierzchności, i mocy, i państwa, i nad wszelkie imię, które się mianuje, nie tylko w tym wieku, ale i w przyszłym; (aiōn g165)
22 Ọlọ́run sì ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì fi í ṣe orí lórí ohun gbogbo fún ìjọ,
I wszystko poddał pod nogi jego, a onego dał za głowę nad wszystkim kościołowi,
23 èyí tí i ṣe ara rẹ̀, ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹni tí ó kún ohun gbogbo ní gbogbo ọ̀nà.
Który jest ciałem jego i pełnością tego, który wszystko we wszystkich napełnia.

< Ephesians 1 >