< Ephesians 6 >

1 Ẹ̀yin ọmọ, ẹ máa gbọ́ tí àwọn òbí i yín nínú Olúwa, nítorí pé èyí ní ó tọ́.
Vós, filhos, sêde obedientes a vossos paes no Senhor, porque isto é justo.
2 “Bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ,” èyí tí í ṣe òfin kìn-ín-ní pẹ̀lú ìlérí,
Honra a teu pae e a tua mãe, que é o primeiro mandamento com promessa,
3 “ki ó lé dára fún ọ, àti kí ìwọ lè wà pẹ́ ní ayé.”
Para que te vá bem, e vivas muito tempo sobre a terra.
4 Àti ẹ̀yin baba, ẹ má ṣe mú àwọn ọmọ yín bínú, ṣùgbọ́n ẹ máa tọ́ wọn nínú ẹ̀kọ́ àti ìkìlọ̀ Olúwa.
E vós, paes, não provoqueis a ira a vossos filhos, mas creae-os na doutrina e admoestação do Senhor.
5 Ẹ̀yin ọmọ ọ̀dọ̀, ẹ máa gbọ́ ti àwọn olúwa yín nípá ti ara, pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì, nínú òtítọ́ ọkàn yín, bí ẹni pé sí Kristi.
Vós, servos, obedecei a vossos senhores segundo a carne, com temor e tremor, na sinceridade de vosso coração, como a Christo;
6 Gbọ́ ọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́nu kì í ṣe láti rí ojúrere wọn nígbà tí ojú wọn bá ń bẹ lára rẹ, ṣùgbọ́n bí ẹrú Kristi, ní ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọ́run láti inú ọkàn rẹ.
Não servindo á vista, como agradando a homens, mas como servos de Christo, fazendo de coração a vontade de Deus,
7 Ẹ máa fi gbogbo ọkàn yin ṣe iṣẹ́ ìsìn bí sí Olúwa, kì í sí ṣe sí ènìyàn.
Servindo de boa vontade ao Senhor, e não aos homens.
8 Bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé ohun rere tí olúkúlùkù bá ṣe òun náà ní yóò sí gbà padà lọ́dọ̀ Olúwa, ìbá à ṣe ẹrú, tàbí òmìnira.
Sabendo que cada um receberá do Senhor todo o bem que fizer, seja servo, seja livre.
9 Àti ẹ̀yin ọ̀gá, ẹ máa ṣe irú ìtọ́jú kan náà sí àwọn ẹrú yin, ẹ máa dín ìbẹ̀rù yín kù bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé Olúwa ẹ̀yin tìkára yín ń bẹ ní ọ̀run; kò sì ṣí ojúsàájú ènìyàn lọ́dọ̀ rẹ̀.
E vós senhores, fazei o mesmo para com elles, deixando as ameaças, sabendo tambem que o Senhor d'elles e vosso está no céu, e que para com elle não ha accepção de pessoas.
10 Ní àkótán, ara mí, ẹ jẹ́ alágbára nínú Olúwa, àti nínú agbára ipá rẹ̀.
No demais, irmãos meus, fortalecei-vos no Senhor e na força do seu poder.
11 Ẹ gbé gbogbo ìhámọ́ra Ọlọ́run wọ̀, kí ẹ̀yin lè kọ ojú ìjà sí àrékérekè èṣù.
Revesti-vos de toda a armadura de Deus, para que possaes estar firmes contra as astutas ciladas do diabo.
12 Nítorí pé kì í ṣe ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara ní àwa ń bá jìjàkadì, ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè, àwọn ọlọ́lá, àwọn aláṣẹ ìbí òkùnkùn ayé yìí, àti àwọn ẹ̀mí búburú ní ojú ọ̀run. (aiōn g165)
Porque não temos que luctar contra a carne e o sangue, mas sim contra os principados, contra as potestades, contra os principes das trevas d'este seculo, contra as malicias espirituaes em os ares. (aiōn g165)
13 Nítorí náà, ẹ gbé gbogbo ìhámọ́ra Ọlọ́run wọ̀, kí ẹ̀yin lè dúró tiiri sí ọjọ́ ibi, nígbà tí ẹ̀yin bá sì ti ṣe ohun gbogbo tan kí ẹ sì dúró.
Portanto tomae toda a armadura de Deus, para que possaes resistir no dia mau, e, havendo feito tudo, ficar firmes.
14 Ẹ dúró nítorí náà lẹ́yìn tí ẹ fi àmùrè òtítọ́ dì ẹ̀gbẹ́ yin, tí ẹ sì ti di ìgbàyà òdodo mọ́ra.
Estae pois firmes, tendo cingidos os vossos lombos com a verdade, e vestidos com a couraça da justiça;
15 Tí ẹ sì ti fi ìmúra ìyìnrere àlàáfíà wọ ẹsẹ̀ yín ní bàtà.
E calçados os pés com a preparação do evangelho da paz
16 Ní àfikún, ẹ mú àpáta ìgbàgbọ́, nípa èyí tí ẹ̀yin lè máa fi paná gbogbo ọfà iná ẹni ibi náà.
Tomando sobretudo o escudo da fé, com o qual possaes apagar todos os dardos inflammados do maligno.
17 Kí ẹ sì mú àṣíborí ìgbàlà, àti idà ẹ̀mí, tí í ṣe ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Tomae tambem o capacete da salvação, e a espada do Espirito, que é a palavra de Deus:
18 Pẹ̀lú gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ni kí ẹ máa gbàdúrà nígbà gbogbo nínú Ẹ̀mí, kí ẹ sì máa ṣọ́ra sí i nínú ìdúró ṣinṣin gbogbo àti ẹ̀bẹ̀ fún gbogbo ènìyàn mímọ́.
Orando em todo o tempo com toda a oração e supplica em espirito, e vigiando n'isto com toda a perseverança e supplica por todos os sanctos,
19 Kí ẹ sì máa gbàdúrà fún mí pẹ̀lú, kí Ọlọ́run lè fún mí ní ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí èmi lè máa fì ìgboyà sọ àwọn ohun ìjìnlẹ̀ ìyìnrere náà.
E por mim; para que me seja dada, no abrir da minha bocca, a palavra com confiança, para fazer notorio o mysterio do evangelho.
20 Nítorí èyí tí èmí jẹ́ ikọ̀ nínú ẹ̀wọ̀n, kí èmi lè máa fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mí láti máa sọ.
Pelo qual sou embaixador em cadeias; para que possa fallar d'elle livremente, como me convém fallar.
21 Tikiku, arákùnrin olùfẹ́ àti ìránṣẹ́ olóòtítọ́ nínú Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dí mí mọ̀ fún yín, kí ẹ̀yin pẹ̀lú lè mọ̀ bí nǹkan ti rí fún mí àti bí mo tí ń ṣe sí.
Ora, para que vós tambem possaes saber os meus negocios, e o que eu faço, Tychico, irmão amado, e fiel ministro do Senhor, vos informará de tudo.
22 Ẹni tí mo rán sí yín nítorí èyí náà, kí ẹ lè mọ̀ bí a tí wà, kì òun lè tu ọkàn yín nínú.
O qual vos enviei para o mesmo fim, para que saibaes os nossos negocios, e elle console os vossos corações.
23 Àlàáfíà fún àwọn ará, àti ìfẹ́ pẹ̀lú ìgbàgbọ́, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wà, àti Olúwa wà Jesu Kristi.
Paz seja com os irmãos, e caridade com fé da parte de Deus Pae e da do Senhor Jesus Christo.
24 Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó fẹ́ Olúwa wa Jesu Kristi ni àìṣẹ̀tàn.
A graça seja com todos os que amam a nosso Senhor Jesus Christo em sinceridade. Amen.

< Ephesians 6 >