< Ephesians 5 >

1 Nítorí náà, ẹ máa ṣe àfarawé Ọlọ́run bí àwọn olùfẹ́ ọmọ,
Fiți deci imitatori ai lui Dumnezeu, ca niște copii iubiți.
2 ẹ sì máa rìn ní ìfẹ́, gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti fẹ́ wa, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún wa ní ọrẹ àti ẹbọ fún Ọlọ́run fún òórùn dídùn.
Umblați în dragoste, după cum și Hristos ne-a iubit pe noi și S-a dat pe Sine însuși pentru noi, ca jertfă și ca sacrificiu pentru Dumnezeu, ca o mireasmă de bun miros.
3 Ṣùgbọ́n àgbèrè àti gbogbo ìwà èérí, tàbí ojúkòkòrò, kí a má tilẹ̀ dárúkọ rẹ̀ láàrín yín mọ́, bí ó ti yẹ àwọn ènìyàn mímọ́.
Dar nici măcar să nu se pomenească între voi, cum se cuvine sfinților, de desfrânare sexuală și de orice necurăție sau lăcomie,
4 Ìbá à ṣe ìwà ọ̀bùn, àti ìṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀, tàbí ìṣẹ̀fẹ̀ àwọn ohun tí kò tọ́; ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa dúpẹ́.
nici de spurcăciune, nici de vorbărie prostească, nici de glume, care nu se cuvin, ci de mulțumiri.
5 Nítorí ẹ̀yin mọ èyí dájú pé, kò sí panṣágà, tàbí aláìmọ́ ènìyàn, tàbí wọ̀bìà (tí í ṣé abọ̀rìṣà), tí yóò ni ìpín kan ni ìjọba Kristi àti Ọlọ́run.
Să știi că nici un desfrânat, nici un necurat, nici un lacom, nici un idolatru nu are moștenire în Împărăția lui Hristos și a lui Dumnezeu.
6 Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni fi ọ̀rọ̀ asán tàn yín jẹ: nítorí nípasẹ̀ nǹkan wọ̀nyí ní ìbínú Ọlọ́run fi ń bọ̀ wá sórí àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn.
Nimeni să nu vă amăgească cu vorbe deșarte, căci din pricina acestor lucruri vine mânia lui Dumnezeu peste copiii neascultătorilor.
7 Nítorí náà ẹ má ṣe jẹ́ alájọpín pẹ̀lú wọn.
De aceea, nu fiți părtași la ei.
8 Nítorí ẹ̀yin tí jẹ́ òkùnkùn lẹ́ẹ̀kan ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin dí ìmọ́lẹ̀, nípa tí Olúwa: ẹ máa rín gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀
Căci odinioară erați întuneric, dar acum sunteți lumină în Domnul. Umblați ca niște copii ai luminii,
9 (nítorí èso Ẹ̀mí ni ìṣoore, àti òdodo àti òtítọ́).
căci roada Duhului este în toată bunătatea, dreptatea și adevărul,
10 Ẹ sì máa wádìí ohun tí í ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa.
dovedind ceea ce este plăcut Domnului.
11 Ẹ má sì ṣe bá àwọn oníṣẹ́ òkùnkùn kẹ́gbẹ́ pọ̀, ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa bá wọn wí.
Nu aveți nici o părtășie cu faptele fără roade ale întunericului, ci mai degrabă chiar le mustrați.
12 Nítorí ìtìjú tilẹ̀ ni láti máa sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí àwọn aláìgbọ́ràn ń ṣe ní ìkọ̀kọ̀.
Căci este o rușine chiar să vorbești despre lucrurile pe care le fac ei în ascuns.
13 Ṣùgbọ́n ohun gbogbo tí a tú síta ni ìmọ́lẹ̀ ń fì hàn: nítorí ohunkóhun tí ó bá fi nǹkan hàn, ìmọ́lẹ̀ ni.
Dar toate lucrurile, când sunt mustrate, sunt descoperite de lumină, căci tot ce descoperă este lumină.
14 Nítorí náà ni ó ṣe wí pé, “Jí, ìwọ̀ ẹni tí ó sun, sí jíǹde kúrò nínú òkú Kristi yóò sì fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
De aceea zice: “Deșteaptă-te, tu, care dormi, și scoală-te din morți, și Hristos va străluci peste tine.”
15 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa rìn ní ìwà pípé, kì í ṣé bí àwọn òmùgọ̀, ṣùgbọ́n bí àwọn ọlọ́gbọ́n;
De aceea, păziți-vă bine cum umblați, nu ca niște neînțelepți, ci ca niște înțelepți,
16 ẹ máa ra ìgbà padà, nítorí búburú ní àwọn ọjọ́.
răscumpărând timpul, căci zilele sunt rele.
17 Nítorí náà, ẹ má ṣé jẹ aláìlóye, ṣùgbọ́n ẹ máa mòye ohun tí ìfẹ́ Olúwa jásí.
De aceea, nu fiți nebuni, ci înțelegeți care este voia Domnului.
18 Ẹ má sí ṣe mú wáìnì ní àmupara, nínú èyí tí rúdurùdu wà; ṣùgbọ́n ẹ kún fún Ẹ̀mí Mímọ́.
Nu vă îmbătați cu vin, în care este risipire, ci umpleți-vă de Duhul Sfânt,
19 Ẹ sì máa bá ara yín sọ̀rọ̀ nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin Ẹ̀mí, ẹ máa kọrin, kí ẹ sì máa kọrin dídùn ní ọkàn yín sí Olúwa.
vorbindu-vă unul altuia în psalmi, imnuri și cântări spirituale, cântând și făcând în inima voastră cântece de mulțumire Domnului,
20 Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo fún ohun gbogbo lọ́wọ́ Ọlọ́run, àní Baba, ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wá.
mulțumind întotdeauna lui Dumnezeu, Tatăl, în numele Domnului nostru Isus Hristos, cu privire la toate lucrurile,
21 Ẹ máa tẹríba fún ara yín ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
supunându-vă unul altuia în frica lui Hristos.
22 Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí fún Olúwa.
Neveste, supuneți-vă bărbaților voștri, ca Domnului.
23 Nítorí pé ọkọ ni ó ń ṣe orí aya, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí i ṣe orí ìjọ, tí òun si ń ṣe ara rẹ̀, Òun sì ni Olùgbàlà rẹ̀.
Căci soțul este capul soției, după cum și Hristos este capul adunării, fiind El însuși mântuitorul trupului.
24 Nítorí náà gẹ́gẹ́ bí ìjọ tí i tẹríba fún Kristi, bẹ́ẹ̀ sì ní kì àwọn aya máa ṣe sí ọkọ wọn ní ohun gbogbo.
Dar, după cum Adunarea este supusă lui Hristos, tot așa și soțiile să fie supuse în totul propriilor lor soți.
25 Ẹ̀yin ọkọ, ẹ fẹ́ràn àwọn aya yín, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí fẹ́ràn ìjọ, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún un.
Bărbaților, iubiți-vă nevestele, după cum și Hristos a iubit Adunarea și S-a dat pe Sine însuși pentru ea,
26 Kí òun lè sọ ọ́ di mímọ́ lẹ́yìn tí ó tí fi ọ̀rọ̀ wẹ̀ ẹ́ nínú agbada omí.
ca să o sfințească, după ce a curățat-o prin spălarea cu apă și cu cuvântul,
27 Kí òun lé mú un wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀ bí ìjọ tí ó ní ògo ní àìlábàwọ́n, tàbí àlébù kan, tàbí irú nǹkan bá-wọ̀n-ọn-nì: ṣùgbọ́n kí ó lè jẹ́ mímọ́ àti aláìlábùkù.
ca să Se înfățișeze pe Sine însuși în chip glorios, fără pată, fără riduri sau altceva de acest fel, ci ca să fie sfântă și fără cusur.
28 Bẹ́ẹ̀ ní ó tọ́ kí àwọn ọkùnrin máa fẹ́ràn aya wọn gẹ́gẹ́ bí ara àwọn fúnra wọn.
Tot așa și soții trebuie să iubească pe soțiile lor ca pe propriile lor trupuri. Cel care își iubește propria soție se iubește pe sine însuși.
29 Nítorí kò sì ẹnìkan tí ó ti kórìíra ara rẹ̀; bí kò ṣe pé kí ó máa bọ́ ọ kí ó sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Kristi sì ti ń ṣe sí ìjọ.
Căci nimeni nu și-a urât vreodată propriul trup, ci îl hrănește și îl îngrijește, așa cum face și Domnul cu adunarea,
30 Nítorí pé àwa ni ẹ̀yà ara rẹ̀, àti tí ẹran-ara rẹ̀, àti egungun ara rẹ̀.
pentru că suntem mădulare ale trupului său, din carnea și oasele sale.
31 Nítorí èyí ní ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀, òun yóò sì dàpọ̀ mọ́ aya rẹ̀, àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.
“Pentru aceasta, omul va lăsa pe tatăl său și pe mama sa și se va uni cu soția sa. Atunci cei doi vor deveni un singur trup.”
32 Àṣírí ńlá ní èyí: ṣùgbọ́n èmí ń sọ nípá ti Kristi àti tí ìjọ.
Acest mister este mare, dar eu vorbesc despre Cristos și despre Adunare.
33 Ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù yín fẹ́ràn aya rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun fúnra rẹ̀; kí aya kí ó sì bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀.
Cu toate acestea, fiecare dintre voi trebuie să-și iubească și el soția ca pe sine însuși; iar soția să vadă că își respectă soțul.

< Ephesians 5 >