< Ephesians 2 >

1 Ní ti ẹ̀yin, ẹ̀yin ni ó sì ti sọ di ààyè, nígbà ti ẹ̀yin ti kú nítorí ìrékọjá àti àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín,
I was ożywił, którzyście byli umarli w upadkach i w grzechach.
2 nínú èyí tí ẹ̀yin ti gbé rí, àní bí ìlànà ti ayé yìí, gẹ́gẹ́ bí aláṣẹ agbára ojú ọ̀run, ẹ̀mí tí n ṣiṣẹ́ ni ìsinsin yìí nínú àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn. (aiōn g165)
W którycheście niekiedy chodzili według zwyczaju świata tego i według książęcia, który ma władzę na powietrzu, ducha tego, który teraz jest skuteczny w synach niedowiarstwa. (aiōn g165)
3 Nínú àwọn ẹni tí gbogbo wa pẹ̀lú ti wà rí nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara wa, a ń mú ìfẹ́ ara àti ti inú ṣẹ, àti nípa ìṣẹ̀dá àwa sì ti jẹ́ ọmọ ìbínú, gẹ́gẹ́ bí àwọn ìyókù pẹ̀lú.
Między którymi i my wszyscy obcowaliśmy niekiedy w pożądliwościach ciała naszego, czyniąc to, co się podobało ciału i myślom, i byliśmy z przyrodzenia dziećmi gniewu, jako i drudzy.
4 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run, ẹni tí í ṣe ọlọ́rọ̀ ni àánú, nítorí ìfẹ́ ńlá rẹ̀ tí ó fi fẹ́ wa,
Lecz Bóg, który jest bogaty w miłosierdziu, dla wielkiej miłości swojej, którą nas umiłował.
5 nígbà tí àwa tilẹ̀ ti kú nítorí ìrékọjá wa, ó sọ wá di ààyè pẹ̀lú Kristi, oore-ọ̀fẹ́ ni a ti fi gbà yín là.
I gdyśmy byli umarłymi w grzechach, ożywił nas pospołu z Chrystusem, (gdyż łaską zbawieni jesteście)
6 Ọlọ́run sì ti jí wa dìde pẹ̀lú Kristi, ó sì ti mú wa jókòó pẹ̀lú rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run nínú Kristi Jesu.
I pospołu z nim wzbudził, i pospołu z nim posadził na niebiesiech w Chrystusie Jezusie,
7 Pé ni gbogbo ìgbà tí ń bọ̀ kí ó bà á lè fi ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí o pọ̀ rékọjá hàn fún wa nínú ìṣeun rẹ̀ sì wà nínú Kristi Jesu. (aiōn g165)
Aby okazał w przyszłych wiekach ono nader obfite bogactwo łaski swojej, z dobrotliwości swojej przeciwko nam w Chrystusie Jezusie. (aiōn g165)
8 Nítorí oore-ọ̀fẹ́ ní a fi gbà yín là nípa ìgbàgbọ́. Èyí kì í ṣe nípa agbára ẹ̀yin fúnra yín: ẹ̀bùn Ọlọ́run ni,
Albowiem łaską jesteście zbawieni przez wiarę, i to nie jest z was, dar to Boży jest;
9 kì í ṣe nípa àwọn iṣẹ́, kí ẹnikẹ́ni má ba à ṣògo.
Nie z uczynków, aby się kto nie chlubił.
10 Nítorí àwa ni iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ tí a ti dá nínú Kristi Jesu fún àwọn iṣẹ́ rere, èyí tí Ọlọ́run ti pèsè tẹ́lẹ̀, fún wa láti ṣe.
Albowiem czynem jego jesteśmy stworzeni w Chrystusie Jezusie ku uczynkom dobrym, które przedtem Bóg zgotował, abyśmy w nich chodzili.
11 Nítorí náà ẹ rántí pé, nígbà àtijọ́ rí, ẹ̀yin tí ẹ ti jẹ́ Kèfèrí nípa ti ìbí, tí àwọn tí a ń pè ní “aláìkọlà” láti ọwọ́ àwọn tí ń pe ara wọn “akọlà” (èyí ti a fi ọwọ́ ènìyàn ṣe sí ni ní ara).
Przetoż pamiętajcie, że wy niekiedy będąc poganami w ciele, którzyście byli zwani nieobrzezką od onych, których zwano obrzezką w ciele, która się ręką dzieje;
12 Ẹ rántí pé ni àkókò náà ẹ̀yin wà láìní Kristi, ẹ jẹ́ àjèjì sí Israẹli, àti àjèjì sí àwọn májẹ̀mú ìlérí náà, láìní ìrètí, àti láìní Ọlọ́run ni ayé.
Iżeście byli naonczas bez Chrystusa, oddaleni od społeczności Izraelskiej i obcymi od umów obietnicy, nadziei nie mający i bez Boga na świecie.
13 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nínú Kristi Jesu ẹ̀yin tí ó ti jìnà réré nígbà àtijọ́ rí ni a mú súnmọ́ tòsí, nípa ẹ̀jẹ̀ Kristi.
Ale teraz w Chrystusie Jezusie wy, którzyście niekiedy byli dalekimi, staliście się bliskimi przez krew Chrystusową,
14 Nítorí òun ni àlàáfíà wa, ẹni tí o ti ṣe méjèèjì ni ọ̀kan, tí ó sì ti wó ògiri ìkélé ti ìkórìíra èyí tí ń bẹ láàrín yín.
Albowiem on jest pokojem naszym, który oboje jednem uczynił i średnią ścianę, która była przegrodą, rozwalił;
15 Ó sì ti fi òpin sí ọ̀tá náà nínú ara rẹ̀, àní sí òfin àti àṣẹ wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ nínú ìlànà, kí ó lè sọ àwọn méjèèjì di ẹni tuntun kan nínú ara rẹ̀, kí ó sì ṣe ìlàjà
Nieprzyjaźń, to jest zakon przykazań, który zależał w ustawach, skaziwszy przez ciało swoje, aby dwóch stworzył w samym sobie w jednego nowego człowieka, czyniąc pokój;
16 àti kí ó lè mú àwọn méjèèjì bá Ọlọ́run làjà nínú ara kan nípa àgbélébùú; nípa èyí tí yóò fi pa ìṣọ̀tá náà run.
I pojednał obydwóch w jednem ciele z Bogiem przez krzyż, zgładziwszy nieprzyjaźń przezeń.
17 Ó sì ti wá, ó sì ti wàásù àlàáfíà fún ẹ̀yin tí o jìnnà réré, àti àlàáfíà fún àwọn tí o súnmọ́ tòsí.
I przyszedłszy opowiedział pokój wam, którzyście dalekimi i którzyście bliskimi.
18 Nítorí nípa rẹ̀ ni àwa méjèèjì ti ni àǹfààní sọ́dọ̀ baba nípa Ẹ̀mí kan.
Albowiem przezeń mamy przystęp obie strony w jednym Duchu do Ojca.
19 Ǹjẹ́ nítorí náà ẹ̀yin kì í ṣe àlejò àti àjèjì mọ́, ṣùgbọ́n àjùmọ̀jogún ọmọ ìbílẹ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn ará ilé Ọlọ́run;
A przetoż już więcej nie jesteście gośćmi i przychodniami, ale spółmieszczaninami świętych i domownikami Bożymi.
20 a sì ń gbé yín ró lórí ìpìlẹ̀ àwọn aposteli, àti àwọn wòlíì, pẹ̀lú Jesu Kristi fúnra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí pàtàkì òkúta igun ilé.
Zbudowani na fundamencie Apostołów i proroków, którego jest gruntownym węgielnym kamieniem sam Jezus Chrystus,
21 Nínú rẹ ni gbogbo ilé náà, tí a ń kọ wà papọ̀ ṣọ̀kan tí ó sì ń dàgbàsókè láti di tẹmpili mímọ́ kan nínú Olúwa.
Na którym wszystko budowanie wespół spojone rośnie w kościół święty w Panu;
22 Nínú rẹ̀ ni a ń gbé ẹ̀yin pẹ̀lú ró pẹ̀lú fún ibùjókòó Ọlọ́run nínú Ẹ̀mí rẹ̀.
Na którym też i wy się wespół budujecie, abyście byli mieszkaniem Bożem w Duchu Świętym.

< Ephesians 2 >