< Ecclesiastes 8 >

1 Ta ni ó dàbí ọlọ́gbọ́n ènìyàn? Ta ni ó mọ ìtumọ̀ ohun gbogbo? Ọgbọ́n a máa mú ojú ènìyàn dán ó sì máa ń pààrọ̀ ìrínisí rẹ̀.
Kto jest mądrym człowiekiem? Kto zna wyjaśnienie rzeczy? Mądrość człowieka rozjaśnia jego oblicze i odmienia srogość jego twarzy.
2 Mo sọ wí pé, pa òfin ọba mọ́, nítorí pé, ìwọ ti ṣe ìbúra níwájú Ọlọ́run.
[Radzę ci], abyś przestrzegał rozkazu króla, a to ze względu na przysięgę Boga.
3 Má ṣe jẹ́ kí ojú kán ọ láti kúrò ní iwájú ọba, má ṣe dúró nínú ohun búburú, nítorí yóò ṣe ohunkóhun tí ó bá tẹ́ ẹ lọ́rùn.
Nie spiesz się z odejściem sprzed jego oblicza ani nie upieraj się przy złej sprawie. Czyni bowiem wszystko tak, jak mu się podoba.
4 Níwọ́n ìgbà tí ọ̀rọ̀ ọba ni àṣẹ, ta ni ó le è sọ fún un wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe?”
Gdzie słowo króla, tam i jego moc. Któż mu powie: Co czynisz?
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa àṣẹ rẹ̀ mọ́, kò ní wá sí ìpalára kankan, àyà ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò sì mọ àsìkò tí ó tọ́ àti ọ̀nà tí yóò gbà ṣe é.
Kto przestrzega przykazania, nie zazna niczego złego. A serce mądrego zna czas i sąd.
6 Ohun gbogbo ni ó ní àsìkò àti ọ̀nà tí ó tọ́ láti ṣe, ṣùgbọ́n, òsì ènìyàn pọ̀ sí orí ara rẹ̀.
Na każdą sprawę jest czas i sąd, dlatego wielkie nieszczęście trzyma się człowieka.
7 Níwọ́n ìgbà tí kò sí ẹni tí ó mọ ọjọ́-ọ̀lá, ta ni ó le è sọ fún un ohun tí ó ń bọ̀?
Nie wie bowiem, co będzie. Kto mu oznajmi, kiedy [co] się przydarzy?
8 Kò sí ẹni tí ó lágbára lórí afẹ́fẹ́ láti gbà á dúró, nítorí náà, kò sí ẹni tí ó ní agbára lórí ọjọ́ ikú rẹ̀. Bí ó ti jẹ́ wí pé kò sí ẹni tí a dá sílẹ̀ nígbà ogun, bẹ́ẹ̀ náà ni ìkà kò ní fi àwọn tí ó ń ṣe é sílẹ̀; bí ó ti jẹ́ wí pé kò sí ẹni tí a dá sílẹ̀ nígbà ogun, bẹ́ẹ̀ náà ni ìwà búburú kò le gba àwọn tí ó ń ṣe é sílẹ̀.
Nie ma człowieka, który miałby władzę nad duchem, żeby powstrzymać ducha, ani moc nad dniem śmierci. Nie ma też zwolnienia z tego boju, a niegodziwych nie wybawi ich niegodziwość.
9 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo ti rí, tí mo sì ń múlò ní ọkàn mi sí gbogbo iṣẹ́ tí a ti ṣe lábẹ́ oòrùn. Ìgbà kan wà tí ẹnìkan ń ṣe olórí àwọn tókù fún ìpalára rẹ̀.
To wszystko widziałem, gdy zwróciłem swoje serce do każdego dzieła, którego się dokonuje pod słońcem. [Bywa] czas, kiedy jeden człowiek panuje nad drugim ku jego krzywdzie.
10 Nígbà náà ni mo tún rí ìsìnkú ènìyàn búburú—àwọn tí wọ́n máa ń wá tí wọ́n sì ń lọ láti ibi mímọ́ kí wọn sì gba ìyìn ní ìlú tàbí tí wọ́n ti ṣe èyí. Eléyìí pẹ̀lú kò ní ìtumọ̀.
Widziałem więc niegodziwych pogrzebanych, którzy przychodzili do miejsca świętego i odchodzili z niego, a zapomniano o nich w mieście, gdzie tak czynili. I to również jest marnością.
11 Nígbà tí a kò bá tètè ṣe ìdájọ́ fún ẹlẹ́ṣẹ̀ kíákíá, ọkàn àwọn ènìyàn a máa kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìmọ̀ láti ṣe ibi.
Ponieważ wyroku za zły czyn nie wykonuje się od razu, serce synów ludzkich jest w nich zawzięte [i gotowe] na to, aby popełniali zło.
12 Bí ènìyàn búburú tó dẹ́ṣẹ̀ nígbà ọgọ́rùn-ún tilẹ̀ wà láààyè fún ìgbà pípẹ́, mo mọ̀ wí pé yóò dára fún ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó bẹ̀rù níwájú rẹ̀.
I chociaż grzesznik po stokroć czyni zło i jego dni się przedłużą, to jednak wiem, że szczęści się tym, którzy boją się Boga, którzy się boją jego oblicza.
13 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dára fún ènìyàn búburú, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fa ọjọ́ rẹ̀ gún tí ó dà bí òjìji, nítorí tí kò bẹ̀rù níwájú Ọlọ́run.
Ale niegodziwemu nie szczęści się i nie przedłuży on swoich dni, [przeminą bowiem] jak cień, ponieważ nie boi się Boga.
14 Ohun mìíràn tún wà tí kò ní ìtumọ̀, tí ó ń ṣẹlẹ̀ láyé olódodo tí ó ń gba ohun tí ó tọ́ sí òṣìkà àti ènìyàn búburú tí ó ń gba ohun tí ó tọ́ sí olódodo. Mo sọ wí pé eléyìí gan an kò ní ìtumọ̀.
Jest też marność, która się dzieje na ziemi: są [ludzie] sprawiedliwi, którym się zdarza to, na co [zasługują] uczynki niegodziwych; są też [ludzie] niegodziwi, którym się zdarza to, na co [zasługują] uczynki sprawiedliwych. Powiedziałem, że i to jest marnością.
15 Nítorí náà mo kan sáárá sí ìgbádùn ayé, nítorí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ní abẹ́ oòrùn ju pé kí ó jẹ, kí ó mu, kí inú rẹ̀ sì dùn lọ. Nígbà náà ni ìdùnnú yóò bá a rìn nínú iṣẹ́ ẹ rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé ti Ọlọ́run tí fi fún un lábẹ́ oòrùn.
Chwaliłem więc radość, [gdyż] nie ma dla człowieka nic lepszego pod słońcem nad to, by jadł, pił i radował się. To bowiem zostanie mu z jego trudu po [wszystkie] dni jego życia, które pod słońcem dał mu Bóg.
16 Nígbà tí mo lo ọkàn mi láti mọ ọgbọ́n àti láti wo wàhálà ènìyàn ní ayé.
Gdy zwróciłem swoje serce na to, aby poznać mądrość i rozważać sprawy, jakie się dzieją na ziemi, z powodu których oczy [człowieka] nie zaznają snu ani we dnie, ani w nocy;
17 Nígbà náà ni mo rí gbogbo ohun tí Ọlọ́run tí ṣe, kò sí ẹnìkan tí ó le è mòye ohun tí ó ń lọ lábẹ́ oòrùn. Láìbìkítà gbogbo ìyànjú rẹ̀ láti wá rí jáde, ènìyàn kò le è mọ ìtumọ̀ rẹ̀, kódà bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn rò wí pé òun mọ̀ ọ́n, kò le è ní òye rẹ̀ ní pàtó.
Wówczas zobaczyłem całe dzieło Boga – [to], że człowiek nie potrafi zgłębić sprawy, która się dzieje pod słońcem. Choćby człowiek starał się do tego dojść, nie zgłębi tego; choćby nawet mądry [zamierzył to] poznać, nie zdoła tego zgłębić.

< Ecclesiastes 8 >