< Ecclesiastes 8 >

1 Ta ni ó dàbí ọlọ́gbọ́n ènìyàn? Ta ni ó mọ ìtumọ̀ ohun gbogbo? Ọgbọ́n a máa mú ojú ènìyàn dán ó sì máa ń pààrọ̀ ìrínisí rẹ̀.
Kdo se může vrovnati moudrému, a kdo může vykládati všelikou věc? Moudrost člověka osvěcuje oblíčej jeho, a nestydatost tváři jeho proměňuje.
2 Mo sọ wí pé, pa òfin ọba mọ́, nítorí pé, ìwọ ti ṣe ìbúra níwájú Ọlọ́run.
Jáť radím: Výpovědi královské ostříhej, a však podlé přísahy Boží.
3 Má ṣe jẹ́ kí ojú kán ọ láti kúrò ní iwájú ọba, má ṣe dúró nínú ohun búburú, nítorí yóò ṣe ohunkóhun tí ó bá tẹ́ ẹ lọ́rùn.
Nepospíchej odjíti od tváři jeho, aniž trvej v zpouře; nebo cožť by koli chtěl, učinil by.
4 Níwọ́n ìgbà tí ọ̀rọ̀ ọba ni àṣẹ, ta ni ó le è sọ fún un wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe?”
Nebo kde slovo královské, tu i moc jeho, a kdo dí jemu: Co děláš?
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa àṣẹ rẹ̀ mọ́, kò ní wá sí ìpalára kankan, àyà ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò sì mọ àsìkò tí ó tọ́ àti ọ̀nà tí yóò gbà ṣe é.
Kdo ostříhá přikázaní, nezví o ničem zlém. I čas i příčiny zná srdce moudrého.
6 Ohun gbogbo ni ó ní àsìkò àti ọ̀nà tí ó tọ́ láti ṣe, ṣùgbọ́n, òsì ènìyàn pọ̀ sí orí ara rẹ̀.
Nebo všeliké předsevzetí má čas a příčiny. Ale i to neštěstí veliké člověka se přídrží,
7 Níwọ́n ìgbà tí kò sí ẹni tí ó mọ ọjọ́-ọ̀lá, ta ni ó le è sọ fún un ohun tí ó ń bọ̀?
Že neví, co budoucího jest. Nebo jak se stane, kdo mu oznámí?
8 Kò sí ẹni tí ó lágbára lórí afẹ́fẹ́ láti gbà á dúró, nítorí náà, kò sí ẹni tí ó ní agbára lórí ọjọ́ ikú rẹ̀. Bí ó ti jẹ́ wí pé kò sí ẹni tí a dá sílẹ̀ nígbà ogun, bẹ́ẹ̀ náà ni ìkà kò ní fi àwọn tí ó ń ṣe é sílẹ̀; bí ó ti jẹ́ wí pé kò sí ẹni tí a dá sílẹ̀ nígbà ogun, bẹ́ẹ̀ náà ni ìwà búburú kò le gba àwọn tí ó ń ṣe é sílẹ̀.
Není člověka, kterýž by moci měl nad životem, aby zadržel duši, aniž má moc nade dnem smrti; nemá ani braně v tom boji, aniž vysvobodí bezbožnost bezbožného.
9 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo ti rí, tí mo sì ń múlò ní ọkàn mi sí gbogbo iṣẹ́ tí a ti ṣe lábẹ́ oòrùn. Ìgbà kan wà tí ẹnìkan ń ṣe olórí àwọn tókù fún ìpalára rẹ̀.
Ve všem tom viděl jsem, přiloživ mysl svou ke všemu tomu, co se děje pod sluncem, že časem panuje člověk nad člověkem k jeho zlému.
10 Nígbà náà ni mo tún rí ìsìnkú ènìyàn búburú—àwọn tí wọ́n máa ń wá tí wọ́n sì ń lọ láti ibi mímọ́ kí wọn sì gba ìyìn ní ìlú tàbí tí wọ́n ti ṣe èyí. Eléyìí pẹ̀lú kò ní ìtumọ̀.
A tehdáž viděl jsem bezbožné pohřbené, že se zase navrátili, ale kteříž z místa svatého odešli, v zapomenutí dáni jsou v městě tom, v kterémž dobře činili. I to také jest marnost.
11 Nígbà tí a kò bá tètè ṣe ìdájọ́ fún ẹlẹ́ṣẹ̀ kíákíá, ọkàn àwọn ènìyàn a máa kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìmọ̀ láti ṣe ibi.
Nebo že ne i hned ortel dochází pro skutek zlý, protož vroucí jest k tomu srdce synů lidských, aby činili zlé věci.
12 Bí ènìyàn búburú tó dẹ́ṣẹ̀ nígbà ọgọ́rùn-ún tilẹ̀ wà láààyè fún ìgbà pípẹ́, mo mọ̀ wí pé yóò dára fún ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó bẹ̀rù níwájú rẹ̀.
A ačkoli hříšník činí zle na stokrát, a vždy se mu odkládá, já však vím, že dobře bude bojícím se Boha, kteříž se bojí oblíčeje jeho.
13 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dára fún ènìyàn búburú, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fa ọjọ́ rẹ̀ gún tí ó dà bí òjìji, nítorí tí kò bẹ̀rù níwájú Ọlọ́run.
S bezbožným pak nedobře se díti bude, aniž se prodlí dnové jeho; minou jako stín, proto že jest bez bázně před oblíčejem Božím.
14 Ohun mìíràn tún wà tí kò ní ìtumọ̀, tí ó ń ṣẹlẹ̀ láyé olódodo tí ó ń gba ohun tí ó tọ́ sí òṣìkà àti ènìyàn búburú tí ó ń gba ohun tí ó tọ́ sí olódodo. Mo sọ wí pé eléyìí gan an kò ní ìtumọ̀.
Jest marnost, kteráž se děje na zemi: Že bývají spravedliví, jimž se však vede, jako by činili skutky bezbožných; zase bývají bezbožní, kterýmž se však vede, jako by činili skutky spravedlivých. Protož jsem řekl: I to také jest marnost.
15 Nítorí náà mo kan sáárá sí ìgbádùn ayé, nítorí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ní abẹ́ oòrùn ju pé kí ó jẹ, kí ó mu, kí inú rẹ̀ sì dùn lọ. Nígbà náà ni ìdùnnú yóò bá a rìn nínú iṣẹ́ ẹ rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé ti Ọlọ́run tí fi fún un lábẹ́ oòrùn.
A tak chválil jsem veselí, proto že nic nemá lepšího člověk pod sluncem, jediné aby jedl a pil, a veselil se, a že to pozůstává jemu z práce jeho ve dnech života jeho, kteréž dal jemu Bůh pod sluncem.
16 Nígbà tí mo lo ọkàn mi láti mọ ọgbọ́n àti láti wo wàhálà ènìyàn ní ayé.
A ač jsem se vydal srdcem svým na to, abych moudrost vystihnouti mohl, a vyrozuměti bídě, kteráž bývá na zemi, pro kterouž ani ve dne ani v noci nespí,
17 Nígbà náà ni mo rí gbogbo ohun tí Ọlọ́run tí ṣe, kò sí ẹnìkan tí ó le è mòye ohun tí ó ń lọ lábẹ́ oòrùn. Láìbìkítà gbogbo ìyànjú rẹ̀ láti wá rí jáde, ènìyàn kò le è mọ ìtumọ̀ rẹ̀, kódà bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn rò wí pé òun mọ̀ ọ́n, kò le è ní òye rẹ̀ ní pàtó.
A však viděl jsem při každém skutku Božím, že nemůže člověk vystihnouti skutku dějícího se pod sluncem. O čež pracuje člověk, vyhledati chtěje, ale nenalézá; nýbrž byť i myslil moudrý, že se doví, nebude moci nic najíti.

< Ecclesiastes 8 >