< Ecclesiastes 3 >

1 Àsìkò wà fún ohun gbogbo, àti ìgbà fún gbogbo nǹkan ní abẹ́ ọ̀run.
Pentru fiecare lucru este un sezon și un timp pentru fiecare scop sub cer.
2 Ìgbà láti bí àti ìgbà kíkú, ìgbà láti gbìn àti ìgbà láti fàtu.
Un timp pentru a se naște și un timp pentru a muri; un timp pentru a sădi și un timp pentru a smulge ce este sădit;
3 Ìgbà láti pa àti ìgbà láti mú láradá ìgbà láti wó lulẹ̀ àti ìgbà láti kọ́.
Un timp pentru a ucide și un timp pentru a vindeca; un timp pentru a dărâma și un timp pentru a zidi;
4 Ìgbà láti sọkún àti ìgbà láti rín ẹ̀rín ìgbà láti ṣọ̀fọ̀ àti ìgbà láti jó,
Un timp pentru a plânge și un timp pentru a râde; un timp pentru a jeli și un timp pentru a dansa;
5 ìgbà láti tú òkúta ká àti ìgbà láti ṣà wọ́n jọ ìgbà láti súnmọ́ àti ìgbà láti fàsẹ́yìn,
Un timp pentru a arunca pietre și un timp pentru a aduna pietre; un timp pentru a îmbrățișa și un timp pentru a se înfrâna de la îmbrățișare;
6 ìgbà láti wá kiri àti ìgbà láti ṣàì wá kiri ìgbà láti pamọ́ àti ìgbà láti jù nù,
Un timp pentru a obține și un timp pentru a pierde; un timp pentru a ține și un timp pentru a arunca;
7 ìgbà láti ya àti ìgbà láti rán ìgbà láti dákẹ́ àti ìgbà láti sọ̀rọ̀,
Un timp pentru a rupe și un timp pentru a coase; un timp pentru a păstra tăcere și un timp pentru a vorbi;
8 ìgbà láti ní ìfẹ́ àti ìgbà láti kórìíra ìgbà fún ogun àti ìgbà fún àlàáfíà.
Un timp pentru a iubi și un timp pentru a urî; un timp pentru război și un timp pentru pace.
9 Kí ni òṣìṣẹ́ jẹ ní èrè nínú wàhálà rẹ̀?
Ce folos are cel ce lucrează în ceea ce muncește?
10 Mo ti rí àjàgà tí Ọlọ́run gbé lé ọmọ ènìyàn.
Eu am văzut osteneala pe care Dumnezeu a dat-o fiilor oamenilor pentru a fi umiliți prin ea.
11 Ó ti ṣe ohun gbogbo dáradára ní àsìkò tirẹ̀, ó sì ti fi èrò nípa ayérayé sí ọkàn ọmọ ènìyàn, síbẹ̀, wọn kò le ṣe àwárí ìdí ohun tí Ọlọ́run ti ṣe láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin.
El a făcut fiecare lucru frumos la timpul lui; de asemenea a așezat lumea în inima lor, așa că nimeni nu poate cuprinde lucrarea pe care Dumnezeu o face de la început până la sfârșit.
12 Mo mọ̀ wí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ju pé kí inú wọn dùn kí wọn sì ṣe rere níwọ̀n ìgbà tí wọ́n sì wà láààyè.
Știu că nu este nimic bun în ei, decât pentru cineva să se bucure și să facă bine în viața sa.
13 Wí pé: kí olúkúlùkù le è jẹ, kí wọn sì mu, kí wọn sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú gbogbo iṣẹ́ wọn ẹ̀bùn Ọlọ́run ni èyí jẹ́.
Și de asemenea ca orice om să mănânce și să bea și să se bucure de binele din toată munca lui, ea este darul lui Dumnezeu.
14 Mo mọ̀ wí pé ohun gbogbo tí Ọlọ́run ṣe ni yóò wà títí láé, kò sí ohun tí a lè fi kún un tàbí kí a yọ kúrò nínú rẹ̀. Ọlọ́run ṣe èyí kí ènìyàn le è ní ìbẹ̀rù rẹ̀ ni.
Știu că orice face Dumnezeu va fi pentru totdeauna, nimic nu poate fi adăugat la aceasta nici ceva luat de la ea; și Dumnezeu face aceasta, ca oamenii să se teamă înaintea lui.
15 Ohun tí ó wà ti wà tẹ́lẹ̀, ohun tí ó ń bọ̀ wá ti wà tẹ́lẹ̀, Ọlọ́run yóò sì mú kí àwọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn tún ṣẹlẹ̀.
Ceea ce a fost este acum, și ceea ce va fi a fost deja; și Dumnezeu cere ceea ce a trecut.
16 Mo sì tún rí ohun mìíràn ní abẹ́ ọ̀run dípò ìdájọ́, òdodo ni ó wà níbẹ̀ dípò ètò òtítọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ni o wà níbẹ̀.
Și, mai mult, eu am văzut sub soare locul judecății, și acolo era stricăciune; și locul dreptății, și acolo era nelegiuire.
17 Mo wí nínú ọkàn mi, “Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olódodo àti ènìyàn búburú, nítorí pé àsìkò yóò wà fún gbogbo iṣẹ́, àti àsìkò ṣe ìdájọ́ gbogbo ìṣe.”
Am spus în inima mea: Dumnezeu va judeca pe cel drept și pe cel stricat, pentru că este un timp acolo pentru fiecare scop și pentru fiecare lucrare.
18 Mo tún rò pé “Ọlọ́run ń dán wa wò láti fihàn wá wí pé bí ẹranko ni ènìyàn rí.
Am spus în inima mea, referitor la starea fiilor oamenilor, ca Dumnezeu să le facă cunoscut și ca ei să vadă că sunt animale.
19 Ó ní láti jẹ́ ohun ìrántí pé ìpín ènìyàn rí bí i tẹranko ìpín kan náà ń dúró dè wọ́n. Bí ọ̀kan ti ń kú náà ni èkejì yóò kú. Àwọn méjèèjì ni irú èémí kan náà, ènìyàn kò sàn ju ẹranko lọ, nítorí pé asán ni yíyè jẹ́ fún wọn.
Căci ceea ce se întâmplă fiilor oamenilor se întâmplă și animalelor; un singur lucru li se întâmplă: cum moare unul, așa moare și celălalt; da, au toți o suflare; așa că omul nu are întâietate față de un animal, pentru că totul este deșertăciune.
20 Ibìkan náà ni gbogbo wọn ń lọ, wọ́n wá láti inú erùpẹ̀, inú erùpẹ̀ náà ni wọn yóò tún padà sí.
Toți merg într-un singur loc; toți sunt din țărână și toți se întorc din nou în țărână.
21 Ta ni ó mọ̀ bóyá ẹ̀mí ènìyàn ń lọ sí òkè tí ẹ̀mí ẹranko sì ń lọ sí ìsàlẹ̀ nínú ilẹ̀ ni?”
Cine cunoaște duhul omului care merge în sus și duhul animalului care merge jos în pământ?
22 Nígbà náà, ni mo wá rí i wí pé, kò sí ohun tí ó sàn fún ènìyàn ju kí ó gbádùn iṣẹ́ rẹ̀, nítorí pé ìpín tirẹ̀ ni èyí. Tàbí ta ni ó le è mú kí ó rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀ kò sí!
De aceea am priceput că nu este nimic mai bun, decât ca un om să se bucure în propriile lucrări; căci aceasta este partea lui; căci cine îl va aduce să vadă ce va fi după el?

< Ecclesiastes 3 >