< Ecclesiastes 3 >
1 Àsìkò wà fún ohun gbogbo, àti ìgbà fún gbogbo nǹkan ní abẹ́ ọ̀run.
Alt har sin tid, og en tid er der satt for hvert foretagende under himmelen.
2 Ìgbà láti bí àti ìgbà kíkú, ìgbà láti gbìn àti ìgbà láti fàtu.
Å fødes har sin tid og å dø har sin tid, å plante har sin tid og å rykke op det som er plantet, har sin tid;
3 Ìgbà láti pa àti ìgbà láti mú láradá ìgbà láti wó lulẹ̀ àti ìgbà láti kọ́.
å drepe har sin tid og å læge har sin tid; å rive ned har sin tid og å bygge op har sin tid;
4 Ìgbà láti sọkún àti ìgbà láti rín ẹ̀rín ìgbà láti ṣọ̀fọ̀ àti ìgbà láti jó,
å gråte har sin tid og å le har sin tid; å klage har sin tid og å danse har sin tid;
5 ìgbà láti tú òkúta ká àti ìgbà láti ṣà wọ́n jọ ìgbà láti súnmọ́ àti ìgbà láti fàsẹ́yìn,
å kaste bort stener har sin tid og å samle stener har sin tid; å ta i favn har sin tid og å holde sig fra favntak har sin tid;
6 ìgbà láti wá kiri àti ìgbà láti ṣàì wá kiri ìgbà láti pamọ́ àti ìgbà láti jù nù,
å søke har sin tid og å tape har sin tid; å gjemme har sin tid og å kaste bort har sin tid;
7 ìgbà láti ya àti ìgbà láti rán ìgbà láti dákẹ́ àti ìgbà láti sọ̀rọ̀,
å sønderrive har sin tid og å sy sammen har sin tid; å tie har sin tid og å tale har sin tid;
8 ìgbà láti ní ìfẹ́ àti ìgbà láti kórìíra ìgbà fún ogun àti ìgbà fún àlàáfíà.
å elske har sin tid og å hate har sin tid; krig har sin tid og fred har sin tid.
9 Kí ni òṣìṣẹ́ jẹ ní èrè nínú wàhálà rẹ̀?
Hvad vinning har den som gjør noget, av det strev han har med det?
10 Mo ti rí àjàgà tí Ọlọ́run gbé lé ọmọ ènìyàn.
Jeg så den plage som Gud har gitt menneskenes barn å plage sig med.
11 Ó ti ṣe ohun gbogbo dáradára ní àsìkò tirẹ̀, ó sì ti fi èrò nípa ayérayé sí ọkàn ọmọ ènìyàn, síbẹ̀, wọn kò le ṣe àwárí ìdí ohun tí Ọlọ́run ti ṣe láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin.
Alt har han gjort skjønt i sin tid; også evigheten har han lagt i deres hjerte, men således at mennesket ikke til fulle kan forstå det verk Gud har gjort, fra begynnelsen til enden.
12 Mo mọ̀ wí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ju pé kí inú wọn dùn kí wọn sì ṣe rere níwọ̀n ìgbà tí wọ́n sì wà láààyè.
Jeg skjønte at de intet annet gode har enn å glede sig og å gjøre sig til gode i livet;
13 Wí pé: kí olúkúlùkù le è jẹ, kí wọn sì mu, kí wọn sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú gbogbo iṣẹ́ wọn ẹ̀bùn Ọlọ́run ni èyí jẹ́.
men når et menneske, hvem det så er, får ete og drikke og unne sig gode dager til gjengjeld for alt sitt strev, så er også det en Guds gave.
14 Mo mọ̀ wí pé ohun gbogbo tí Ọlọ́run ṣe ni yóò wà títí láé, kò sí ohun tí a lè fi kún un tàbí kí a yọ kúrò nínú rẹ̀. Ọlọ́run ṣe èyí kí ènìyàn le è ní ìbẹ̀rù rẹ̀ ni.
Jeg skjønte at alt hvad Gud gjør, det varer evig; intet kan legges til og intet kan tas fra. Så har Gud gjort det, forat vi skal frykte ham.
15 Ohun tí ó wà ti wà tẹ́lẹ̀, ohun tí ó ń bọ̀ wá ti wà tẹ́lẹ̀, Ọlọ́run yóò sì mú kí àwọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn tún ṣẹlẹ̀.
Hvad der er, det var allerede før, og hvad der skal bli, det har også vært før; Gud søker frem igjen det forgangne.
16 Mo sì tún rí ohun mìíràn ní abẹ́ ọ̀run dípò ìdájọ́, òdodo ni ó wà níbẹ̀ dípò ètò òtítọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ni o wà níbẹ̀.
Fremdeles så jeg under solen at på dommersetet, der satt gudløsheten, og hvor rettferdighet skulde råde, der rådet gudløshet.
17 Mo wí nínú ọkàn mi, “Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olódodo àti ènìyàn búburú, nítorí pé àsìkò yóò wà fún gbogbo iṣẹ́, àti àsìkò ṣe ìdájọ́ gbogbo ìṣe.”
Da sa jeg i mitt hjerte: Gud skal dømme den rettferdige så vel som den gudløse; for hos ham er det fastsatt en tid for hvert foretagende og for alt hvad som gjøres.
18 Mo tún rò pé “Ọlọ́run ń dán wa wò láti fihàn wá wí pé bí ẹranko ni ènìyàn rí.
Jeg sa i mitt hjerte: Dette skjer for menneskenes barns skyld, forat Gud kan prøve dem, og forat de kan se at de i sig selv ikke er annet enn dyr;
19 Ó ní láti jẹ́ ohun ìrántí pé ìpín ènìyàn rí bí i tẹranko ìpín kan náà ń dúró dè wọ́n. Bí ọ̀kan ti ń kú náà ni èkejì yóò kú. Àwọn méjèèjì ni irú èémí kan náà, ènìyàn kò sàn ju ẹranko lọ, nítorí pé asán ni yíyè jẹ́ fún wọn.
for det går menneskenes barn som det går dyrene; den samme skjebne rammer dem; som den ene dør, så dør den andre, og en livsånde har de alle; mennesket har ikke noget fortrin fremfor dyret; for alt er tomhet.
20 Ibìkan náà ni gbogbo wọn ń lọ, wọ́n wá láti inú erùpẹ̀, inú erùpẹ̀ náà ni wọn yóò tún padà sí.
De farer alle til ett sted; de er alle blitt til av støvet, og de vender alle tilbake til støvet.
21 Ta ni ó mọ̀ bóyá ẹ̀mí ènìyàn ń lọ sí òkè tí ẹ̀mí ẹranko sì ń lọ sí ìsàlẹ̀ nínú ilẹ̀ ni?”
Hvem vet om menneskenes ånd stiger op, og om dyrets ånd farer ned til jorden?
22 Nígbà náà, ni mo wá rí i wí pé, kò sí ohun tí ó sàn fún ènìyàn ju kí ó gbádùn iṣẹ́ rẹ̀, nítorí pé ìpín tirẹ̀ ni èyí. Tàbí ta ni ó le è mú kí ó rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀ kò sí!
Og jeg så at intet er bedre for mennesket enn at han gleder sig ved sitt arbeid; for det er det gode som blir ham til del; for hvem lar ham få se det som skal komme efter ham?