< Ecclesiastes 3 >

1 Àsìkò wà fún ohun gbogbo, àti ìgbà fún gbogbo nǹkan ní abẹ́ ọ̀run.
Il y a une saison pour toute chose, et un temps pour toute chose sous le ciel:
2 Ìgbà láti bí àti ìgbà kíkú, ìgbà láti gbìn àti ìgbà láti fàtu.
un temps pour naître, et un moment pour mourir; le moment de planter, et un temps pour arracher ce qui a été planté;
3 Ìgbà láti pa àti ìgbà láti mú láradá ìgbà láti wó lulẹ̀ àti ìgbà láti kọ́.
un temps à tuer, et un temps de guérison; un moment pour se décomposer, et un temps pour se construire;
4 Ìgbà láti sọkún àti ìgbà láti rín ẹ̀rín ìgbà láti ṣọ̀fọ̀ àti ìgbà láti jó,
un temps pour pleurer, et un temps pour rire; un temps de deuil, et un temps pour danser;
5 ìgbà láti tú òkúta ká àti ìgbà láti ṣà wọ́n jọ ìgbà láti súnmọ́ àti ìgbà láti fàsẹ́yìn,
un temps pour jeter les pierres, et un temps pour rassembler les pierres; un temps à embrasser, et un temps pour s'abstenir d'embrasser;
6 ìgbà láti wá kiri àti ìgbà láti ṣàì wá kiri ìgbà láti pamọ́ àti ìgbà láti jù nù,
un temps à chercher, et un temps à perdre; un temps à conserver, et un temps pour s'en débarrasser;
7 ìgbà láti ya àti ìgbà láti rán ìgbà láti dákẹ́ àti ìgbà láti sọ̀rọ̀,
un temps à déchirer, et un temps pour coudre; un temps pour garder le silence, et un temps de parole;
8 ìgbà láti ní ìfẹ́ àti ìgbà láti kórìíra ìgbà fún ogun àti ìgbà fún àlàáfíà.
un temps pour aimer, et un temps pour la haine; un temps pour la guerre, et un temps pour la paix.
9 Kí ni òṣìṣẹ́ jẹ ní èrè nínú wàhálà rẹ̀?
Quel profit a celui qui travaille dans ce qu'il peine?
10 Mo ti rí àjàgà tí Ọlọ́run gbé lé ọmọ ènìyàn.
J'ai vu le fardeau que Dieu a donné aux fils des hommes pour les accabler.
11 Ó ti ṣe ohun gbogbo dáradára ní àsìkò tirẹ̀, ó sì ti fi èrò nípa ayérayé sí ọkàn ọmọ ènìyàn, síbẹ̀, wọn kò le ṣe àwárí ìdí ohun tí Ọlọ́run ti ṣe láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin.
Il a rendu chaque chose belle en son temps. Il a aussi mis l'éternité dans leur cœur, sans que l'homme puisse découvrir l'œuvre que Dieu a faite depuis le commencement jusqu'à la fin.
12 Mo mọ̀ wí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ju pé kí inú wọn dùn kí wọn sì ṣe rere níwọ̀n ìgbà tí wọ́n sì wà láààyè.
Je sais qu'il n'y a rien de mieux pour eux que de se réjouir et de faire le bien tant qu'ils vivent.
13 Wí pé: kí olúkúlùkù le è jẹ, kí wọn sì mu, kí wọn sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú gbogbo iṣẹ́ wọn ẹ̀bùn Ọlọ́run ni èyí jẹ́.
Aussi, que chacun mange et boive, et jouisse du bien dans tout son travail, c'est un don de Dieu.
14 Mo mọ̀ wí pé ohun gbogbo tí Ọlọ́run ṣe ni yóò wà títí láé, kò sí ohun tí a lè fi kún un tàbí kí a yọ kúrò nínú rẹ̀. Ọlọ́run ṣe èyí kí ènìyàn le è ní ìbẹ̀rù rẹ̀ ni.
Je sais que tout ce que Dieu fait, c'est pour toujours. Rien ne peut y être ajouté, rien ne peut en être retranché; et Dieu a fait cela pour que les hommes craignent devant lui.
15 Ohun tí ó wà ti wà tẹ́lẹ̀, ohun tí ó ń bọ̀ wá ti wà tẹ́lẹ̀, Ọlọ́run yóò sì mú kí àwọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn tún ṣẹlẹ̀.
Ce qui est a déjà été, et ce qui doit être a déjà été. Dieu cherche de nouveau ce qui est passé.
16 Mo sì tún rí ohun mìíràn ní abẹ́ ọ̀run dípò ìdájọ́, òdodo ni ó wà níbẹ̀ dípò ètò òtítọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ni o wà níbẹ̀.
J'ai vu sous le soleil que, dans le lieu de la justice, il y avait de la méchanceté, et dans le lieu de la justice, il y avait de la méchanceté.
17 Mo wí nínú ọkàn mi, “Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olódodo àti ènìyàn búburú, nítorí pé àsìkò yóò wà fún gbogbo iṣẹ́, àti àsìkò ṣe ìdájọ́ gbogbo ìṣe.”
Je disais en mon cœur: « Dieu jugera les justes et les méchants, car il y a là un temps pour toute chose et pour toute œuvre. »
18 Mo tún rò pé “Ọlọ́run ń dán wa wò láti fihàn wá wí pé bí ẹranko ni ènìyàn rí.
Je disais en mon cœur: « Quant aux fils des hommes, Dieu les éprouve, afin qu'ils voient qu'ils sont eux-mêmes comme des animaux.
19 Ó ní láti jẹ́ ohun ìrántí pé ìpín ènìyàn rí bí i tẹranko ìpín kan náà ń dúró dè wọ́n. Bí ọ̀kan ti ń kú náà ni èkejì yóò kú. Àwọn méjèèjì ni irú èémí kan náà, ènìyàn kò sàn ju ẹranko lọ, nítorí pé asán ni yíyè jẹ́ fún wọn.
Car ce qui arrive aux fils des hommes arrive aux animaux. Il leur arrive même une chose. Comme l'un meurt, l'autre meurt aussi. Oui, ils ont tous le même souffle; et l'homme n'a aucun avantage sur les animaux, car tout est vanité.
20 Ibìkan náà ni gbogbo wọn ń lọ, wọ́n wá láti inú erùpẹ̀, inú erùpẹ̀ náà ni wọn yóò tún padà sí.
Tous vont au même endroit. Tous sont issus de la poussière, et tous retournent à la poussière.
21 Ta ni ó mọ̀ bóyá ẹ̀mí ènìyàn ń lọ sí òkè tí ẹ̀mí ẹranko sì ń lọ sí ìsàlẹ̀ nínú ilẹ̀ ni?”
Qui connaît l'esprit de l'homme, s'il monte vers le haut, et l'esprit de l'animal, s'il descend vers la terre? ".
22 Nígbà náà, ni mo wá rí i wí pé, kò sí ohun tí ó sàn fún ènìyàn ju kí ó gbádùn iṣẹ́ rẹ̀, nítorí pé ìpín tirẹ̀ ni èyí. Tàbí ta ni ó le è mú kí ó rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀ kò sí!
C'est pourquoi j'ai vu qu'il n'y a rien de mieux que l'homme se réjouisse de ses œuvres, car c'est là sa part; car qui peut lui faire voir ce qui sera après lui?

< Ecclesiastes 3 >