< Ecclesiastes 2 >

1 Mo rò nínú ọkàn mi, “Wá nísinsin yìí, èmi yóò sì dán ọ wò pẹ̀lú ìgbádùn láti ṣe àwárí ohun tí ó dára.” Ṣùgbọ́n eléyìí náà jásí asán.
Mǝn kɵnglümdǝ: «Ⱪeni, mǝn ɵzümgǝ tamaxining tǝmini tetiƣuzup baⱪimǝn; kɵnglüm eqilsun!» — dedim. Biraⱪ mana, bumu bimǝniliktur.
2 “Mo wí fún ẹ̀rín pé òmùgọ̀ ni. Àti fún ìre-ayọ̀ pé kí ni ó ń ṣe?”
Mǝn külkǝ-qaⱪqaⱪⱪa «Tǝlwilik!» wǝ tamaxiƣa «Uning zadi nemǝ paydisi?» — dedim.
3 Mo tiraka láti dun ara mi nínú pẹ̀lú ọtí wáìnì, àti láti fi ọwọ́ lé òmùgọ̀—ọkàn mi sì ń tọ́ mi pẹ̀lú ọgbọ́n. Mo fẹ́ wo ohun tí ó yẹ ní ṣíṣe fún ènìyàn ní abẹ́ ọ̀run ní ìwọ̀nba ọjọ́ ayé rẹ̀.
Kɵnglümdǝ ɵz bǝdinimni xarab bilǝn ⱪandaⱪ roⱨlandurƣili bolidiƣanliⱪini (danaliⱪ bilǝn ɵzümni yetǝkligǝn ⱨalda) bilixkǝ berilip izdǝndim, xuningdǝk «sanaⱪliⱪ künliridǝ insan baliliriƣa yahxiliⱪ yǝtküzidiƣan nemǝ paydiliⱪ ixlar bar?» degǝn tügünni yǝxsǝm dǝp ǝhmiⱪanilikni ⱪandaⱪ tutup yetixim kerǝklikini intilip izdidim.
4 Mo ṣe àwọn iṣẹ́ ńlá ńlá. Mo kọ́ ilé púpọ̀ fún ara mi, mo sì gbin ọgbà àjàrà púpọ̀.
Mǝn uluƣ ⱪuruluxlarƣa kirixtim; ɵzüm üqün ɵylǝrni saldim; ɵzüm üqün üzümzarlarni tiktim;
5 Mo ṣe ọgbà àti àgbàlá, mo sì gbin onírúurú igi eléso sí inú wọn.
Ɵzüm üqün xaⱨanǝ baƣ-baƣqilarni yasidim; ularda ⱨǝrhil mewǝ beridiƣan dǝrǝhlǝrni tiktim;
6 Mo gbẹ́ adágún láti máa bu omi rin àwọn igi tí ó ń hù jáde nínú ọgbà.
Ɵzüm üqün ormandiki baraⱪsan dǝrǝhlǝrni obdan suƣirix üqün, kɵlqǝklǝrni yasap qiⱪtim;
7 Mo ra àwọn ẹrú ọkùnrin àti àwọn ẹrú obìnrin, mo sì tún ní àwọn ẹrú mìíràn tí a bí sí ilé mi. Mo sì tún ní ẹran ọ̀sìn ju ẹnikẹ́ni ní Jerusalẹmu lọ.
Ⱪullarƣa wǝ dedǝklǝrgǝ igǝ boldum; ɵyümdǝ ulardin tuƣulƣanlarmu meningki idi; Yerusalemda mǝndin ilgiri bolƣanlarning ⱨǝmmisiningkidin kɵp mal-waranlar, ⱪoy wǝ kala padilirim bar boldi.
8 Mo kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara mi àti àwọn ohun ìṣúra ti ọba àti ìgbèríko. Mo ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin, àti dídùn inú ọmọ ènìyàn, aya àti obìnrin púpọ̀.
Ɵz-ɵzümgǝ altun-kümüxlǝrni, padixaⱨlarning ⱨǝm ⱨǝrⱪaysi ɵlkilǝrning ⱨǝrhil ǝtiwarliⱪ alaⱨidǝ gɵⱨǝrlirini yiƣdim; ⱪiz-yigit nahxiqilarƣa ⱨǝmdǝ adǝm balilirining dilkɵyǝrlirigǝ, yǝni kɵpligǝn güzǝl kenizǝklǝrgǝ igǝ boldum.
9 Mo di ẹni ńlá ju ẹnikẹ́ni tí ó wà ní Jerusalẹmu ṣáájú mi. Nínú gbogbo èyí, ọgbọ́n mi kò fi mí sílẹ̀.
Uluƣ boldum, Yerusalemda mǝndin ilgiri bolƣanlarning ⱨǝmmisidin ziyadǝ ronaⱪ taptim; xundaⱪ bolƣini bilǝn danaliⱪim mǝndin kǝtmidi.
10 Èmi kò jẹ́ kí ojú mi ṣe aláìrí ohun tí ó bá ń fẹ́. N kò sì jẹ́ kí ọkàn mi ó ṣe aláìní ìgbádùn. Ọkàn mi yọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ mi, èyí sì ni èrè fún gbogbo wàhálà mi.
Kɵzlirimgǝ nemǝ yaⱪⱪan bolsa, mǝn xuni uningdin ayimidim; ɵz kɵnglümgǝ ⱨeqⱪandaⱪ huxalliⱪni yaⱪ demidim; qünki kɵnglüm barliⱪ ǝjrimdin xadlandi; mana, bular ɵz ǝjrimdin bolƣan nesiwǝm idi.
11 Síbẹ̀, nígbà tí mo wo gbogbo ohun tí ọwọ́ mi ti ṣe àti ohun tí mo ti ṣe wàhálà láti ní: gbogbo rẹ̀, asán ni. Ó dàbí ẹni gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́, kò sí èrè kan ní abẹ́ oòrùn; ọgbọ́n àti òmùgọ̀, asán ni.
Andin ɵz ⱪolum yasiƣanlirining ⱨǝmmisigǝ, xundaⱪla singdürgǝn ǝjrimning nǝtijisigǝ ⱪarisam, mana, ⱨǝmmisi bimǝnilik wǝ xamalni ⱪoƣliƣandǝk ix idi; bular ⱪuyax astidiki ⱨeq paydisi yoⱪ ixlardur.
12 Nígbà náà ni mo tún bẹ̀rẹ̀ sí ọgbọ́n, àti ìsínwín àti àìgbọ́n kí ni ọba tí ó jẹ lẹ́yìn tí ọba kan kú le è ṣe ju èyí tí ọba ìṣáájú ti ṣe lọ.
Andin zeⱨnimni yiƣip uni danaliⱪⱪa, tǝlwilik wǝ ǝhmiⱪanilikkǝ ⱪaraxⱪa ⱪoydum; qünki padixaⱨtin keyin turidiƣan adǝm nemǝ ⱪilalaydu? — ⱪilsimu alliⱪaqan ⱪilinƣan ixlardin ibarǝt bolidu, halas!
13 Mo sì ri wí pé ọgbọ́n dára ju òmùgọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ ti dára ju òkùnkùn lọ.
Xuning bilǝn nur ⱪarangƣuluⱪtin ǝwzǝl bolƣandǝk, danaliⱪning biƣǝrǝzliktin ǝwzǝllikini kɵrüp yǝttim.
14 Ojú ọlọ́gbọ́n ń bẹ lágbárí rẹ̀, nígbà tí aṣiwèrè ń rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n mo wá padà mọ̀ wí pé ìpín kan náà ni ó ń dúró de ìsọ̀rí àwọn ènìyàn méjèèjì.
Dana kixining kɵzliri bexididur, ǝhmǝⱪ bolsa ⱪarangƣuluⱪta mangidu; biraⱪ ularƣa ohxax birla ixning bolidiƣanliⱪini qüxinip yǝttim.
15 Nígbà náà ni mo rò nínú ọkàn wí pé, “Irú ìpín tí òmùgọ̀ ní yóò bá èmi náà pẹ̀lú kí wá ni ohun tí mo jẹ ní èrè nípa ọgbọ́n?” Mo sọ nínú ọkàn mi wí pé, “Asán ni eléyìí pẹ̀lú.”
Kɵnglümdǝ: «Əhmǝⱪkǝ bolidiƣan ix mangimu ohxax bolidu; ǝmdi mening xundaⱪ dana boluxumning zadi nemǝ paydisi?!» — dedim. Andin mǝn kɵnglümdǝ: «Bu ixmu ohxaxla bimǝniliktur!» — dedim.
16 Nítorí pé ọlọ́gbọ́n ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí i òmùgọ̀, a kì yóò rántí rẹ̀ fún ìgbà pípẹ́; gbogbo wọn ni yóò di ohun ìgbàgbé ní ọjọ́ tó ń bọ̀. Ikú tí ó pa aṣiwèrè náà ni yóò pa ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
Qünki mǝnggügǝ dana kixi ǝhmǝⱪkǝ nisbǝtǝn ⱨeq artuⱪ ǝslǝnmǝydu; qünki kǝlgüsidiki künlǝrdǝ ⱨǝmmǝ ix alliⱪaqan untulup ketidu; ǝmdi dana kixi ⱪandaⱪ ɵlidu? — Əhmǝⱪ kixi bilǝn billǝ!
17 Nítorí náà, mo kórìíra ìwàláàyè, nítorí pé iṣẹ́ tí wọn ń ṣe ní abẹ́ oòrùn ti mú ìdààmú bá mi. Gbogbo rẹ̀ asán ni, ó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
Xunga mǝn ⱨayatⱪa ɵq boldum; qünki ⱪuyax astida ⱪilinƣan ixlar manga eƣir kelǝtti; ⱨǝmmisi bimǝnilik wǝ xamalni ⱪoƣliƣandǝk ix idi.
18 Mo kórìíra gbogbo ohun tí mo ti ṣiṣẹ́ fún ní abẹ́ oòrùn, nítorí pé mo ní láti fi wọ́n sílẹ̀ fún ẹni tí ó wà lẹ́yìn mi ni.
Xuningdǝk mǝn ⱪuyax astidiki barliⱪ ǝjrimgǝ ɵq boldum; qünki buni mǝndin keyin kǝlgǝn kixigǝ ⱪaldurmasliⱪⱪa amalim yoⱪ idi.
19 Ta ni ó wá mọ̀ bóyá ọlọ́gbọ́n ènìyàn ni yóò jẹ́ tàbí aṣiwèrè? Síbẹ̀ yóò ní láti ṣe àkóso lórí gbogbo iṣẹ́ tí mo tí ṣe yìí pẹ̀lú.
Uning dana yaki ǝhmǝⱪ ikǝnlikini kim bilidu? U bǝribir mǝn japaliⱪ bilǝn singdürgǝn ⱨǝmdǝ danaliⱪ bilǝn ada ⱪilƣan ⱪuyax astidiki barliⱪ ǝjrim üstigǝ ⱨɵküm süridu. Bumu bimǝniliktur.
20 Nítorí náà, ọkàn mi bẹ̀rẹ̀ sí ní kábámọ̀ lórí gbogbo àìsimi iṣẹ́ ṣíṣe mi ní abẹ́ oòrùn.
Andin mǝn rayimdin yandim, kɵnglüm ⱪuyax astidiki japa tartⱪan barliⱪ ǝjrimdin ümidsizlinip kǝtti.
21 Nítorí pé ènìyàn le è ṣe iṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní abẹ́ oòrùn, tí ó sì ti kọ́ ṣe iṣẹ́ fúnra rẹ̀. Asán ni eléyìí pẹ̀lú àti àdánù ńlá.
Qünki ǝjrini danaliⱪ, bilim wǝ ǝp bilǝn ⱪilƣan bir adǝm bar; biraⱪ u ǝjrini uningƣa ⱨeq ixlimigǝn baxⱪa birsining nesiwisi boluxⱪa ⱪalduruxi kerǝk. Bumu bimǝnilik wǝ intayin aqqiⱪ külpǝttur.
22 Kí ni ohun tí ènìyàn rí gbà fún gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú tí ó fi ṣiṣẹ́ lábẹ́ oòrùn?
Qünki insan ⱪuyax astida ɵzini upritip, ɵzining barliⱪ ǝmgikidin wǝ kɵnglining intilixliridin nemigǝ igǝ bolidu?
23 Gbogbo ọjọ́ rẹ, iṣẹ́ rẹ kún fún ìrora, àti ìbànújẹ́, kódà ọkàn rẹ̀ kì í ní ìsinmi ní alẹ́. Asán ni eléyìí pẹ̀lú.
Qünki uning barliⱪ künliri azabliⱪtur, uning ǝjri ƣǝxliktur; ⱨǝtta keqidǝ uning kɵngli ⱨeq aram tapmaydu. Bumu bimǝniliktur.
24 Ènìyàn kò le è ṣe ohunkóhun tí ó dára jù pé kí ó jẹ kí ó sì mu, kí ó sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú iṣẹ́ rẹ̀. Mo rí wí pé eléyìí pẹ̀lú wá láti ọwọ́ Ọlọ́run.
Insan üqün xuningdin baxⱪa yahxi ix yoⱪki, u yeyixi, iqixi, ɵz jenini ɵz ǝjridin ⱨuzur alduruxidin ibarǝttur; buni Hudaning ⱪolidindur, dǝp kɵrüp yǝttim.
25 Nítorí wí pé láìsí òun, ta ni ó le jẹ tàbí kí ó mọ adùn?
Qünki uningsiz kim yeyǝlisun yaki besip ixliyǝlisun?
26 Fún ẹni tí ó bá tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn ni Ọlọ́run yóò fún ní ọgbọ́n, ìmọ̀ àti ìdùnnú, ṣùgbọ́n fún ẹni dẹ́ṣẹ̀, Ó fún un ní iṣẹ́ láti ṣà àti láti kó ohun ìní pamọ́ kí ó sì fi fún ẹni tí ó tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn. Eléyìí pẹ̀lú, asán ni, ó dàbí ẹni gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́.
Qünki u ɵz nǝzirigǝ yaⱪidiƣan adǝmgǝ danaliⱪ, bilim wǝ xadliⱪni ata ⱪilidu; biraⱪ gunaⱨkar adǝmgǝ u mal-mülük yiƣip-toplaxⱪa japaliⱪ ǝmgǝkni beridu, xuningdǝk u yiƣip-topliƣinini Hudaning nǝziridǝ yahxi bolƣanƣa tapxuridiƣan ⱪilidu. Bumu bimǝnilik wǝ xamalni ⱪoƣliƣandǝk ixtin ibarǝttur.

< Ecclesiastes 2 >