< Ecclesiastes 2 >

1 Mo rò nínú ọkàn mi, “Wá nísinsin yìí, èmi yóò sì dán ọ wò pẹ̀lú ìgbádùn láti ṣe àwárí ohun tí ó dára.” Ṣùgbọ́n eléyìí náà jásí asán.
Am spus în inima mea: Du-te acum, te voi încerca cu veselie, de aceea bucură-te de plăcere; și, iată, aceasta de asemenea este deșertăciune.
2 “Mo wí fún ẹ̀rín pé òmùgọ̀ ni. Àti fún ìre-ayọ̀ pé kí ni ó ń ṣe?”
Am spus despre râs: Este nebun; și despre veselie: Ce face aceasta?
3 Mo tiraka láti dun ara mi nínú pẹ̀lú ọtí wáìnì, àti láti fi ọwọ́ lé òmùgọ̀—ọkàn mi sì ń tọ́ mi pẹ̀lú ọgbọ́n. Mo fẹ́ wo ohun tí ó yẹ ní ṣíṣe fún ènìyàn ní abẹ́ ọ̀run ní ìwọ̀nba ọjọ́ ayé rẹ̀.
Am căutat în inima mea să mă dedau vinului, totuși deprinzându-mi inima cu înțelepciune; și să apuc prostia, până voi vedea ce este acel bine pe care fiii oamenilor ar trebui să îl facă sub cer toate zilele vieții lor.
4 Mo ṣe àwọn iṣẹ́ ńlá ńlá. Mo kọ́ ilé púpọ̀ fún ara mi, mo sì gbin ọgbà àjàrà púpọ̀.
Mi-am făcut lucrări mari, mi-am construit case, mi-am sădit vii,
5 Mo ṣe ọgbà àti àgbàlá, mo sì gbin onírúurú igi eléso sí inú wọn.
Mi-am făcut grădini și livezi și am sădit în ele pomi de toate felurile [de] fructe;
6 Mo gbẹ́ adágún láti máa bu omi rin àwọn igi tí ó ń hù jáde nínú ọgbà.
Mi-am făcut iazuri de apă, ca să ud cu ele pădurea ce aduce pomi;
7 Mo ra àwọn ẹrú ọkùnrin àti àwọn ẹrú obìnrin, mo sì tún ní àwọn ẹrú mìíràn tí a bí sí ilé mi. Mo sì tún ní ẹran ọ̀sìn ju ẹnikẹ́ni ní Jerusalẹmu lọ.
Am dobândit servitori și servitoare și mi s-au născut servitori în casă; de asemenea am avut mari turme de vite mari și mici mai mult decât toți cei ce au fost în Ierusalim înainte de mine;
8 Mo kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara mi àti àwọn ohun ìṣúra ti ọba àti ìgbèríko. Mo ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin, àti dídùn inú ọmọ ènìyàn, aya àti obìnrin púpọ̀.
Mi-am adunat de asemenea argint și aur și tezaurul deosebit al împăraților și al provinciilor; mi-am dobândit cântăreți și cântărețe și desfătările fiilor oamenilor, instrumente muzicale și acelea de toate felurile.
9 Mo di ẹni ńlá ju ẹnikẹ́ni tí ó wà ní Jerusalẹmu ṣáájú mi. Nínú gbogbo èyí, ọgbọ́n mi kò fi mí sílẹ̀.
Astfel am fost mare și i-am întrecut pe toți cei ce au fost înainte de mine în Ierusalim; de asemenea înțelepciunea mea a rămas cu mine.
10 Èmi kò jẹ́ kí ojú mi ṣe aláìrí ohun tí ó bá ń fẹ́. N kò sì jẹ́ kí ọkàn mi ó ṣe aláìní ìgbádùn. Ọkàn mi yọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ mi, èyí sì ni èrè fún gbogbo wàhálà mi.
Și orice au dorit ochii mei nu le-am refuzat, nu mi-am oprit inima de la nicio bucurie; fiindcă inima mi s-a bucurat în toată munca mea; și aceasta mi-a fost partea mea din toată munca.
11 Síbẹ̀, nígbà tí mo wo gbogbo ohun tí ọwọ́ mi ti ṣe àti ohun tí mo ti ṣe wàhálà láti ní: gbogbo rẹ̀, asán ni. Ó dàbí ẹni gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́, kò sí èrè kan ní abẹ́ oòrùn; ọgbọ́n àti òmùgọ̀, asán ni.
Atunci m-am uitat la toate lucrările pe care mâinile mele le-au lucrat și la osteneala cu care m-am ostenit ca să o fac, și iată, totul era deșertăciune și chinuire a duhului și nu era niciun folos sub soare.
12 Nígbà náà ni mo tún bẹ̀rẹ̀ sí ọgbọ́n, àti ìsínwín àti àìgbọ́n kí ni ọba tí ó jẹ lẹ́yìn tí ọba kan kú le è ṣe ju èyí tí ọba ìṣáájú ti ṣe lọ.
Și m-am întors să privesc înțelepciunea și nebunia și prostia; căci ce poate face omul care vine după împărat? Chiar ceea ce s-a făcut deja.
13 Mo sì ri wí pé ọgbọ́n dára ju òmùgọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ ti dára ju òkùnkùn lọ.
Atunci am văzut că înțelepciunea întrece prostia, precum lumina întrece întunericul.
14 Ojú ọlọ́gbọ́n ń bẹ lágbárí rẹ̀, nígbà tí aṣiwèrè ń rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n mo wá padà mọ̀ wí pé ìpín kan náà ni ó ń dúró de ìsọ̀rí àwọn ènìyàn méjèèjì.
Ochii înțeleptului sunt în capul său, dar prostul umblă în întuneric; și tot eu am priceput că aceeași întâmplare se întâmplă tuturor.
15 Nígbà náà ni mo rò nínú ọkàn wí pé, “Irú ìpín tí òmùgọ̀ ní yóò bá èmi náà pẹ̀lú kí wá ni ohun tí mo jẹ ní èrè nípa ọgbọ́n?” Mo sọ nínú ọkàn mi wí pé, “Asán ni eléyìí pẹ̀lú.”
Atunci am spus în inima mea: Așa cum se întâmplă prostului, la fel mi se întâmplă și mie; și de ce am fost atunci mai înțelept? Apoi am spus în inima mea că și aceasta este deșertăciune.
16 Nítorí pé ọlọ́gbọ́n ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí i òmùgọ̀, a kì yóò rántí rẹ̀ fún ìgbà pípẹ́; gbogbo wọn ni yóò di ohun ìgbàgbé ní ọjọ́ tó ń bọ̀. Ikú tí ó pa aṣiwèrè náà ni yóò pa ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
Căci nu este amintire pentru totdeauna a înțeleptului mai mult decât a prostului; văzând că ceea ce este acum, în zilele ce vin vor fi toate uitate. Și cum moare înțeleptul? Ca și prostul.
17 Nítorí náà, mo kórìíra ìwàláàyè, nítorí pé iṣẹ́ tí wọn ń ṣe ní abẹ́ oòrùn ti mú ìdààmú bá mi. Gbogbo rẹ̀ asán ni, ó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
De aceea am urât viața, pentru că lucrarea ce se face sub soare este apăsătoare pentru mine, căci totul este deșertăciune și chinuire a duhului.
18 Mo kórìíra gbogbo ohun tí mo ti ṣiṣẹ́ fún ní abẹ́ oòrùn, nítorí pé mo ní láti fi wọ́n sílẹ̀ fún ẹni tí ó wà lẹ́yìn mi ni.
Da, am urât toată munca mea pe care am făcut-o sub soare, pentru că o voi lăsa omului ce va fi după mine.
19 Ta ni ó wá mọ̀ bóyá ọlọ́gbọ́n ènìyàn ni yóò jẹ́ tàbí aṣiwèrè? Síbẹ̀ yóò ní láti ṣe àkóso lórí gbogbo iṣẹ́ tí mo tí ṣe yìí pẹ̀lú.
Și cine știe dacă el va fi înțelept, sau prost? Totuși va avea stăpânire peste toată munca mea în care am muncit și în care m-am arătat înțelept sub soare. Și aceasta este deșertăciune.
20 Nítorí náà, ọkàn mi bẹ̀rẹ̀ sí ní kábámọ̀ lórí gbogbo àìsimi iṣẹ́ ṣíṣe mi ní abẹ́ oòrùn.
De aceea am ajuns să îmi fac inima să dispere de toată munca pe care am făcut-o sub soare.
21 Nítorí pé ènìyàn le è ṣe iṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní abẹ́ oòrùn, tí ó sì ti kọ́ ṣe iṣẹ́ fúnra rẹ̀. Asán ni eléyìí pẹ̀lú àti àdánù ńlá.
Pentru că este un om a cărui muncă este în înțelepciune și în cunoaștere și în echitate; totuși unui om care nu a muncit în acestea va lăsa el aceasta ca partea lui. Și aceasta este deșertăciune și un mare rău.
22 Kí ni ohun tí ènìyàn rí gbà fún gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú tí ó fi ṣiṣẹ́ lábẹ́ oòrùn?
Căci ce are omul din toată munca sa și din chinuirea inimii sale, în care el a muncit sub soare?
23 Gbogbo ọjọ́ rẹ, iṣẹ́ rẹ kún fún ìrora, àti ìbànújẹ́, kódà ọkàn rẹ̀ kì í ní ìsinmi ní alẹ́. Asán ni eléyìí pẹ̀lú.
Căci toate zilele sale sunt întristări, iar osteneala lui, mâhnire; da, inima lui nu își ia odihnă noaptea. Și aceasta este deșertăciune.
24 Ènìyàn kò le è ṣe ohunkóhun tí ó dára jù pé kí ó jẹ kí ó sì mu, kí ó sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú iṣẹ́ rẹ̀. Mo rí wí pé eléyìí pẹ̀lú wá láti ọwọ́ Ọlọ́run.
Nu este nimic mai bun pentru un om, decât să mănânce și să bea și să își facă sufletul să se bucure de binele din munca lui. Și aceasta am văzut că era din mâna lui Dumnezeu.
25 Nítorí wí pé láìsí òun, ta ni ó le jẹ tàbí kí ó mọ adùn?
Pentru că cine poate mânca, sau cine altul se poate grăbi mai mult decât mine?
26 Fún ẹni tí ó bá tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn ni Ọlọ́run yóò fún ní ọgbọ́n, ìmọ̀ àti ìdùnnú, ṣùgbọ́n fún ẹni dẹ́ṣẹ̀, Ó fún un ní iṣẹ́ láti ṣà àti láti kó ohun ìní pamọ́ kí ó sì fi fún ẹni tí ó tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn. Eléyìí pẹ̀lú, asán ni, ó dàbí ẹni gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́.
Pentru că Dumnezeu dă unui om ce este bun în ochii săi, înțelepciune și cunoaștere și bucurie; dar celui păcătos îi dă osteneala să adune și să îngrămădească, pentru ca el să dea celui ce este bun înaintea lui Dumnezeu. Și aceasta este deșertăciune și chinuire a duhului.

< Ecclesiastes 2 >