< Ecclesiastes 12 >

1 Rántí Ẹlẹ́dàá rẹ ní ọjọ́ èwe rẹ, nígbà tí ọjọ́ ibi kò tí ì dé àti tí ọdún kò tí ì ní súnmọ́ etílé, nígbà tí ìwọ yóò wí pé, “Èmi kò ní ìdùnnú nínú wọn,”
Lembre-se também de seu Criador nos dias de sua juventude, antes que os dias maus cheguem, e os anos se aproximem, quando você dirá: “Eu não tenho prazer neles”.
2 kí oòrùn àti ìmọ́lẹ̀ àti òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ tó ṣókùnkùn, àti kí àwọsánmọ̀ tó padà lẹ́yìn òjò;
Antes do sol, a luz, a lua e as estrelas são escurecidas, e as nuvens retornam após a chuva;
3 nígbà tí olùṣọ́ ilé yóò wárìrì tí àwọn ọkùnrin alágbára yóò tẹríba, nígbà tí àwọn tí ó ń lọ dákẹ́ nítorí pé wọn kò pọ̀, tí àwọn tí ń wo òde láti ojú fèrèsé yóò ṣókùnkùn;
no dia em que os zeladores da casa tremerão, e os homens fortes devem se curvar, e os moinhos param porque são poucos, e aqueles que olham para fora das janelas ficam escuros,
4 nígbà tí ìlẹ̀kùn sí ìgboro yóò tì tí ariwo ọlọ yóò dákẹ́; nígbà tí àwọn ènìyàn yóò dìde sí ariwo àwọn ẹyẹ ṣùgbọ́n gbogbo orin wọn yóò máa lọ ilẹ̀.
e as portas devem ser fechadas na rua; quando o som da trituração é baixo, e se levantará à voz de um pássaro, e todas as filhas da música devem ser trazidas para baixo;
5 Nígbà tí ènìyàn yóò bẹ̀rù ibi gíga àti ti ìfarapa ní ìgboro; nígbà tí igi almondi yóò tanná àti tí ẹlẹ́ǹgà yóò wọ́ ara rẹ̀ lọ tí ìfẹ́ kò sì ní ru sókè mọ́ nígbà náà ni ènìyàn yóò lọ ilé rẹ́ ayérayé tí àwọn aṣọ̀fọ̀ yóò máa rìn kiri ìgboro.
sim, eles devem ter medo das alturas, e terrores estarão a caminho; e a amendoeira deve florescer, e o gafanhoto deve ser um fardo, e o desejo deve falhar; porque o homem vai para sua casa eterna, e as carpideiras andam pelas ruas;
6 Rántí rẹ̀ kí okùn fàdákà tó já, tàbí kí ọpọ́n wúrà tó fọ́; kí iṣà tó fọ́ níbi ìsun, tàbí kí àyíká kẹ̀kẹ́ kí ó tó kán níbi kànga.
antes que o cordão prateado seja cortado, ou a tigela dourada está quebrada, ou o jarro está quebrado na primavera, ou a roda quebrada na cisterna,
7 Tí erùpẹ̀ yóò sì padà sí ilẹ̀ ibi tí ó ti wà, tí ẹ̀mí yóò sì padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run tí ó fi í fún ni.
e a poeira retorna à terra como estava, e o espírito retorna a Deus que o deu.
8 “Asán! Asán!” ni Oniwaasu wí. “Gbogbo rẹ̀ asán ni!”
“Vaidade das vaidades”, diz o pregador. “Tudo é vaidade!”
9 Kì í ṣe wí pé Oniwaasu jẹ́ ọlọ́gbọ́n nìkan, ṣùgbọ́n ó tún kọ́ àwọn ènìyàn ní ìmọ̀. Ó rò ó dáradára ó sì ṣe àwárí, ó sì gbé ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe kalẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ.
Além disso, porque o Pregador era sábio, ele ainda ensinava o conhecimento do povo. Sim, ele ponderou, procurou e pôs em ordem muitos provérbios.
10 Oniwaasu wádìí láti rí àwọn ọ̀rọ̀ tí ó tọ̀nà, ohun tí ó kọ sì dúró ṣinṣin ó sì jẹ́ òtítọ́.
O Pregador procurou encontrar palavras aceitáveis, e o que foi escrito sem culpa, palavras de verdade.
11 Ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹ̀gún, àkójọpọ̀ ọ̀rọ̀ wọn sì dàbí ìṣó tí a kàn pọ̀ dáradára, tí olùṣọ́-àgùntàn kan fi fún ni.
As palavras dos sábios são como goads; e como pregos bem apertados são palavras dos mestres das assembléias, que são dadas por um só pastor.
12 Àti síwájú láti inú èyí, ọmọ mi, gba ìmọ̀ràn. Nínú ìwé púpọ̀, òpin kò sí, ìwé kíkà púpọ̀ a máa mú ara ṣàárẹ̀.
Furthermore, meu filho, seja admoestado: de fazer muitos livros não há fim; e muito estudo é um cansaço da carne.
13 Nísinsin yìí, òpin gbogbo ọ̀rọ̀ tí a gbọ́ ni pé, bẹ̀rù Ọlọ́run, kí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́, nítorí èyí ni ojúṣe gbogbo ènìyàn.
Este é o fim da questão. Tudo já foi ouvido. Temam a Deus e guardam seus mandamentos; pois este é todo o dever do homem.
14 Nítorí Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olúkúlùkù iṣẹ́ àti ohun ìkọ̀kọ̀, kì bá à ṣe rere kì bá à ṣe búburú.
Pois Deus levará cada obra a julgamento, com cada coisa oculta, seja ela boa, seja má.

< Ecclesiastes 12 >