< Ecclesiastes 12 >

1 Rántí Ẹlẹ́dàá rẹ ní ọjọ́ èwe rẹ, nígbà tí ọjọ́ ibi kò tí ì dé àti tí ọdún kò tí ì ní súnmọ́ etílé, nígbà tí ìwọ yóò wí pé, “Èmi kò ní ìdùnnú nínú wọn,”
Pamiętaj więc o swoim Stwórcy w dniach swojej młodości, zanim nastaną złe dni i przyjdą lata, o których powiesz: Nie podobają mi się.
2 kí oòrùn àti ìmọ́lẹ̀ àti òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ tó ṣókùnkùn, àti kí àwọsánmọ̀ tó padà lẹ́yìn òjò;
Zanim zaćmią się słońce, światło, księżyc i gwiazdy, a chmury powrócą po deszczu.
3 nígbà tí olùṣọ́ ilé yóò wárìrì tí àwọn ọkùnrin alágbára yóò tẹríba, nígbà tí àwọn tí ó ń lọ dákẹ́ nítorí pé wọn kò pọ̀, tí àwọn tí ń wo òde láti ojú fèrèsé yóò ṣókùnkùn;
W dzień, w którym trząść się będą stróże domu i pochylą się silni mężczyźni, ustaną mielący, gdyż będzie ich mało, i zaćmią się patrzące przez okna;
4 nígbà tí ìlẹ̀kùn sí ìgboro yóò tì tí ariwo ọlọ yóò dákẹ́; nígbà tí àwọn ènìyàn yóò dìde sí ariwo àwọn ẹyẹ ṣùgbọ́n gbogbo orin wọn yóò máa lọ ilẹ̀.
I zamkną się drzwi na ulicę, gdy odgłos mielenia osłabnie, gdy będzie się wstawać na głos ptaków i przycichną wszystkie córki śpiewające.
5 Nígbà tí ènìyàn yóò bẹ̀rù ibi gíga àti ti ìfarapa ní ìgboro; nígbà tí igi almondi yóò tanná àti tí ẹlẹ́ǹgà yóò wọ́ ara rẹ̀ lọ tí ìfẹ́ kò sì ní ru sókè mọ́ nígbà náà ni ènìyàn yóò lọ ilé rẹ́ ayérayé tí àwọn aṣọ̀fọ̀ yóò máa rìn kiri ìgboro.
Gdy też będą się bać wysokich miejsc i lękać na drodze, [gdy] zakwitnie drzewo migdałowe i szarańcza będzie ciężka i pragnienie ustanie, bo człowiek idzie do [swego] wiecznego domu, a płaczący będą chodzić po ulicach;
6 Rántí rẹ̀ kí okùn fàdákà tó já, tàbí kí ọpọ́n wúrà tó fọ́; kí iṣà tó fọ́ níbi ìsun, tàbí kí àyíká kẹ̀kẹ́ kí ó tó kán níbi kànga.
Zanim się zerwie srebrny sznur i stłucze złota czasza, nim rozbije się dzban u źródła i złamie się koło przy studni.
7 Tí erùpẹ̀ yóò sì padà sí ilẹ̀ ibi tí ó ti wà, tí ẹ̀mí yóò sì padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run tí ó fi í fún ni.
Wtedy proch powróci do ziemi, jak nią był, a duch powróci do Boga, który go dał.
8 “Asán! Asán!” ni Oniwaasu wí. “Gbogbo rẹ̀ asán ni!”
Marność nad marnościami – mówi Kaznodzieja – wszystko to marność.
9 Kì í ṣe wí pé Oniwaasu jẹ́ ọlọ́gbọ́n nìkan, ṣùgbọ́n ó tún kọ́ àwọn ènìyàn ní ìmọ̀. Ó rò ó dáradára ó sì ṣe àwárí, ó sì gbé ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe kalẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ.
A poza tym, że Kaznodzieja był mądry, uczył lud wiedzy; rozważał, badał i ułożył wiele przysłów.
10 Oniwaasu wádìí láti rí àwọn ọ̀rọ̀ tí ó tọ̀nà, ohun tí ó kọ sì dúró ṣinṣin ó sì jẹ́ òtítọ́.
Kaznodzieja starał się znaleźć słowa przyjemne i napisał to, co jest dobre – słowa prawdy.
11 Ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹ̀gún, àkójọpọ̀ ọ̀rọ̀ wọn sì dàbí ìṣó tí a kàn pọ̀ dáradára, tí olùṣọ́-àgùntàn kan fi fún ni.
Słowa mądrych są jak ościenie i jak gwoździe wbite przez tych, którzy je złożyli, i pochodzą od jednego pasterza.
12 Àti síwájú láti inú èyí, ọmọ mi, gba ìmọ̀ràn. Nínú ìwé púpọ̀, òpin kò sí, ìwé kíkà púpọ̀ a máa mú ara ṣàárẹ̀.
Ponadto, mój synu, przyjmij przestrogę z tych [słów]: Pisaniu wielu ksiąg nie ma końca, a wiele nauki męczy ciało.
13 Nísinsin yìí, òpin gbogbo ọ̀rọ̀ tí a gbọ́ ni pé, bẹ̀rù Ọlọ́run, kí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́, nítorí èyí ni ojúṣe gbogbo ènìyàn.
Wysłuchaj podsumowania wszystkiego: Bój się Boga i przestrzegaj jego przykazań. Ponieważ to jest cały [obowiązek] człowieka.
14 Nítorí Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olúkúlùkù iṣẹ́ àti ohun ìkọ̀kọ̀, kì bá à ṣe rere kì bá à ṣe búburú.
Bóg przywiedzie bowiem każdy uczynek na sąd, nawet każdą rzecz utajoną, czy dobrą, czy złą.

< Ecclesiastes 12 >