< Ecclesiastes 11 >

1 Fún àkàrà rẹ sórí omi, nítorí lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ìwọ yóò rí i padà.
Nanliringni sularƣa ǝwǝt; kɵp künlǝrdin keyin uni ⱪaytidin tapisǝn.
2 Fi ìpín fún méje, àní fún mẹ́jọ pẹ̀lú, nítorí ìwọ kò mọ ohun ìparun tí ó le è wá sórí ilẹ̀.
Bir ülüxni yǝttǝ kixigǝ, sǝkkizigimu bǝrgin; qünki yǝr yüzidǝ nemǝ yamanliⱪ bolidiƣanliⱪini bilmǝysǝn.
3 Bí àwọsánmọ̀ bá kún fún omi, ayé ni wọ́n ń rọ òjò sí. Bí igi wó sí ìhà gúúsù tàbí sí ìhà àríwá, níbi tí ó wó sí náà, ni yóò dùbúlẹ̀ sí.
Bulutlar yamƣurƣa tolƣan bolsa, ɵzlirini zemin üstigǝ boxitidu; dǝrǝh ximal tǝrǝpkǝ ɵrülsǝ, yaki jǝnub tǝrǝpkǝ ɵrülsǝ, ⱪaysi tǝrǝpkǝ qüxkǝn bolsa, xu yǝrdǝ ⱪalidu.
4 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo afẹ́fẹ́ kò ní fúnrúgbìn; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo àwọsánmọ̀ kò ní kórè.
Xamalni kɵzitidiƣanlar teriⱪqiliⱪ ⱪilmaydu; bulutlarƣa ⱪaraydiƣanlar orma ormaydu.
5 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ kò ti ṣe mọ ojú ọ̀nà afẹ́fẹ́ tàbí mọ bí ọmọ tí ń dàgbà nínú ikùn ìyáarẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ìwọ kò le è ní òye iṣẹ́ Ọlọ́run ẹlẹ́dàá ohun gbogbo.
Sǝn xamalning yolini bilmiginingdǝk yaki boyida barning ⱨamilisining ustihanlirining baliyatⱪuda ⱪandaⱪ ɵsidiƣanliⱪini bilmiginingdǝk, sǝn ⱨǝmmini yasiƣuqi Hudaning ⱪilƣinini bilmǝysǝn.
6 Fún irúgbìn rẹ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣọlẹ̀ ní àṣálẹ́, nítorí ìwọ kò mọ èyí tí yóò ṣe rere bóyá èyí tàbí ìyẹn tàbí àwọn méjèèjì ni yóò ṣe dáradára bákan náà.
Sǝⱨǝrdǝ uruⱪungni teriƣin, kǝqtimu ⱪolungni ixtin ⱪaldurma; qünki nemǝ ixning, u yaki bu ixning paydiliⱪ bolidiƣanliⱪini wǝ yaki ⱨǝr ikkisining ohxaxla yahxi bolidiƣanliⱪini bilmǝysǝn.
7 Ìmọ́lẹ̀ dùn; Ó sì dára fún ojú láti rí oòrùn.
Nur xerin bolidu, aptapni kɵrüxmu ⱨuzurluⱪ ixtur.
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn jẹ̀gbádùn gbogbo iye ọdún tí ó le è lò láyé ṣùgbọ́n jẹ́ kí ó rántí ọjọ́ òkùnkùn nítorí wọn ó pọ̀. Gbogbo ohun tí ó ń bọ̀ asán ni.
Xunga birsi kɵp yil yaxiƣan bolsa, bularning ⱨǝmmisidin ⱨuzur alsun. Ⱨalbuki, u yǝnǝ ⱪarangƣuluⱪ künlirini esidǝ tutsun, qünki ular kɵp bolidu; kǝlgüsidiki ixlarning ⱨǝmmisi bimǝniliktur!
9 Jẹ́ kí inú rẹ dùn, ìwọ ọ̀dọ́mọdé ní ìgbà tí o wà ní èwe kí o sì jẹ́ kí ọkàn rẹ fún ọ ní ayọ̀ ní ìgbà èwe rẹ. Tẹ̀lé ọ̀nà ọkàn rẹ àti ohunkóhun tí ojú rẹ rí ṣùgbọ́n mọ̀ dájú pé nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run yóò mú ọ wá sí ìdájọ́.
Yaxliⱪingdin ⱨuzur al, i yigit; yaxliⱪing künliridǝ kɵnglüng ɵzünggǝ huxalliⱪni yǝtküzgǝy; kɵnglüng haliƣini boyiqǝ wǝ kɵzliring kɵrgini boyiqǝ yürgin; biraⱪ xuni bilginki, bularning ⱨǝmmisi üqün Huda seni soraⱪⱪa tartidu.
10 Nítorí náà, mú ìjayà kúrò ní ọkàn rẹ kí o sì lé ìbànújẹ́ ara rẹ kúrò nítorí èwe àti kékeré kò ní ìtumọ̀.
Əmdi kɵnglüngdin ƣǝxlikni elip taxla, teningdin yamanliⱪni neri ⱪil; qünki baliliⱪ wǝ yaxliⱪmu bimǝniliktur.

< Ecclesiastes 11 >