< Ecclesiastes 11 >
1 Fún àkàrà rẹ sórí omi, nítorí lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ìwọ yóò rí i padà.
Rzucaj swój chleb na wody, bo po wielu dniach odnajdziesz go.
2 Fi ìpín fún méje, àní fún mẹ́jọ pẹ̀lú, nítorí ìwọ kò mọ ohun ìparun tí ó le è wá sórí ilẹ̀.
Rozdaj dział siedmiu lub ośmiu, bo nie wiesz, co złego wydarzy się na ziemi.
3 Bí àwọsánmọ̀ bá kún fún omi, ayé ni wọ́n ń rọ òjò sí. Bí igi wó sí ìhà gúúsù tàbí sí ìhà àríwá, níbi tí ó wó sí náà, ni yóò dùbúlẹ̀ sí.
Gdy chmury napełniają się deszczem, spuszczają go na ziemię. Gdy drzewo upada na południe lub na północ, w miejscu, gdzie upadnie to drzewo, tam zostanie.
4 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo afẹ́fẹ́ kò ní fúnrúgbìn; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo àwọsánmọ̀ kò ní kórè.
Kto zważa na wiatr, [nigdy] nie będzie siał, a kto patrzy na chmury, nie będzie żąć.
5 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ kò ti ṣe mọ ojú ọ̀nà afẹ́fẹ́ tàbí mọ bí ọmọ tí ń dàgbà nínú ikùn ìyáarẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ìwọ kò le è ní òye iṣẹ́ Ọlọ́run ẹlẹ́dàá ohun gbogbo.
Jak nie wiesz, jaka jest droga ducha, [i] jak [się kształtują] kości w łonie brzemiennej, tak nie znasz spraw Boga, który wszystko czyni.
6 Fún irúgbìn rẹ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣọlẹ̀ ní àṣálẹ́, nítorí ìwọ kò mọ èyí tí yóò ṣe rere bóyá èyí tàbí ìyẹn tàbí àwọn méjèèjì ni yóò ṣe dáradára bákan náà.
Rano siej swoje ziarno, a wieczorem nie pozwól spocząć swojej ręce, gdyż nie wiesz, co się uda, czy to, czy tamto, czy też oboje będą równie dobre.
7 Ìmọ́lẹ̀ dùn; Ó sì dára fún ojú láti rí oòrùn.
Doprawdy, światło jest słodkie i miła to rzecz dla oczu widzieć słońce.
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn jẹ̀gbádùn gbogbo iye ọdún tí ó le è lò láyé ṣùgbọ́n jẹ́ kí ó rántí ọjọ́ òkùnkùn nítorí wọn ó pọ̀. Gbogbo ohun tí ó ń bọ̀ asán ni.
A choćby człowiek żył przez wiele lat i radował się nimi wszystkimi, to niech pamięta o dniach ciemności, bo będzie ich wiele. Wszystko, co nastąpi, to tylko marność.
9 Jẹ́ kí inú rẹ dùn, ìwọ ọ̀dọ́mọdé ní ìgbà tí o wà ní èwe kí o sì jẹ́ kí ọkàn rẹ fún ọ ní ayọ̀ ní ìgbà èwe rẹ. Tẹ̀lé ọ̀nà ọkàn rẹ àti ohunkóhun tí ojú rẹ rí ṣùgbọ́n mọ̀ dájú pé nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run yóò mú ọ wá sí ìdájọ́.
[Dlatego] raduj się, młodzieńcze, w swojej młodości, niech twoje serce cieszy cię za dni twojej młodości i krocz drogami swego serca oraz według zdania swoich oczu, ale wiedz, że za to wszystko Bóg przyprowadzi cię na sąd.
10 Nítorí náà, mú ìjayà kúrò ní ọkàn rẹ kí o sì lé ìbànújẹ́ ara rẹ kúrò nítorí èwe àti kékeré kò ní ìtumọ̀.
Usuń więc gniew ze swojego serca i odrzuć zło od swego ciała, gdyż dzieciństwo i młodość są marnością.