< Ecclesiastes 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:
Słowa kaznodziei, syna Dawidowego, króla w Jeruzalemie.
2 “Asán inú asán!” Oníwàásù náà wí pé, “Asán inú asán! Gbogbo rẹ̀ asán ni.”
Marność nad marnościami, powiedział kaznodzieja; marność nad marnościami, i wszystko marność.
3 Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?
Cóż za pożytek ma człowiek ze wszystkiej pracy swej, którą prowadzi pod słońcem?
4 Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ, síbẹ̀ ayé dúró títí láé.
Jeden rodzaj przemija, a drugi rodzaj nastaje; lecz ziemia na wieki stoi.
5 Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀, ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.
Słońce wschodzi i słońce zachodzi, a spieszy się do miejsca swego, kędy wschodzi;
6 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù, Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá, a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.
Idzie na południe, a obraca się na północy; wiatr ustawicznie krążąc idzie, a po okręgach swoich wraca się wiatr.
7 Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun, síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún. Níbi tí àwọn odò ti wá, níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.
Wszystkie rzeki idą do morza, wszakże morze nie wylewa; do miejsca, z którego rzeki płyną, wracają się, aby zaś stamtąd wychodziły.
8 Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá, ju èyí tí ẹnu le è sọ. Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn, bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.
Wszystkie rzeczy są pełne zabaw, a człowiek nie może ich wymówić; oko nie nasyci się widzeniem, a ucho nie napełni się słyszeniem.
9 Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn òun ni a ó tún máa ṣe padà kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.
Co było, jest to, co być ma; a co się teraz dzieje, jest to, co się dziać będzie, a niemasz nic nowego pod słońcem.
10 Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé, “Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”? Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́, o ti wà ṣáájú tiwa.
Jestże jaka rzecz, o którejby kto rzec mógł: Wej! to coś nowego? I toć już było za onych wieków, które były przed nami.
11 Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀ lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.
Niemasz pamiątki pierwszych rzeczy; także też i potomnych, które będą, nie będzie pamiątki u tych, którzy potem nastaną.
12 Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí.
Ja kaznodzieja byłem królem Izraelskim w Jeruzalemie;
13 Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn.
I przyłożyłem do tego serce swe, abym szukał, i doszedł mądrością swoją wszystkiego, co się dzieje pod niebem.(Tę zabawę trudną dał Bóg synom ludzkim, aby się nią trapili.)
14 Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
Widziałem wszystkie sprawy, które się dzieją pod słońcem, a oto wszystko jest marnością i utrapieniem ducha.
15 Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́, ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.
Co jest krzywego, nie może być wyprostowane, a niedostatki nie mogą być policzone.
16 Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.”
Przetoż takiem myślał w sercu swem, mówiąc: Otom ja uwielbił i rozszerzył mądrość nad wszystkich, którzy byli przedemną w Jeruzalemie, a serce moje dostąpiło wielkiej mądrości i umiejętności.
17 Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
I przyłożyłem do tego serce moje, abym poznał mądrość i umiejętność, szaleństwo i głupstwo; alem doznał, iż to jest utrapieniem ducha.
18 Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá, bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.
Bo gdzie wiele mądrości, tam jest wiele gniewu; a kto przyczynia umiejętności, przyczynia boleści.

< Ecclesiastes 1 >