< Ecclesiastes 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:
Slova kazatele syna Davidova, krále v Jeruzalémě.
2 “Asán inú asán!” Oníwàásù náà wí pé, “Asán inú asán! Gbogbo rẹ̀ asán ni.”
Marnost nad marnostmi, řekl kazatel, marnost nad marnostmi, a všecko marnost.
3 Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?
Jaký užitek má člověk ze všelijaké práce své, kterouž vede pod sluncem?
4 Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ, síbẹ̀ ayé dúró títí láé.
Věk pomíjí, a jiný věk nastává, ačkoli země na věky trvá.
5 Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀, ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.
Vychází slunce, i zapadá slunce, a k místu svému chvátá, kdež vychází.
6 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù, Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá, a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.
Jde ku poledni, a obrací se na půlnoci, sem i tam se toče, chodí vítr, a okolky svými navracuje se vítr.
7 Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun, síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún. Níbi tí àwọn odò ti wá, níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.
Všecky řeky jdou do moře, a však se moře nepřeplňuje; do místa, do něhož tekou řeky, navracují se, aby zase odtud vycházely.
8 Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá, ju èyí tí ẹnu le è sọ. Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn, bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.
Všecky věci jsou plné zaneprázdnění, aniž může člověk vymluviti; nenasytí se oko hleděním, aniž se naplní ucho slyšením.
9 Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn òun ni a ó tún máa ṣe padà kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.
Což bylo, jest to, což býti má; a což se nyní děje, jest to, což se díti bude; aniž jest co nového pod sluncem.
10 Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé, “Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”? Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́, o ti wà ṣáájú tiwa.
Jest-liž jaká věc, o níž by říci mohl: Pohleď, toť jest cosi nového? Ano již to bylo před věky, kteříž byli před námi.
11 Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀ lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.
Není paměti prvních věcí, aniž také potomních, kteréž budou, památka zůstane u těch, jenž potom nastanou.
12 Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí.
Já kazatel byl jsem králem nad Izraelem v Jeruzalémě,
13 Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn.
A přiložil jsem mysl svou k tomu, jak bych vyhledati a vystihnouti mohl rozumností svou všecko to, což se děje pod nebem. (Takové bídné zaměstknání dal Bůh synům lidským, aby se jím bědovali.)
14 Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
Viděl jsem všecky skutky, dějící se pod sluncem, a aj, všecko jest marnost a trápení ducha.
15 Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́, ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.
Což křivého jest, nemůže se zpřímiti, a nedostatkové nemohou sečteni býti.
16 Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.”
Protož tak jsem myslil v srdci svém, řka: Aj, já zvelebil jsem a rozšířil moudrost nade všecky, kteříž byli přede mnou v Jeruzalémě, a srdce mé dosáhlo množství moudrosti a umění.
17 Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
I přiložil jsem mysl svou, abych poznal moudrost a umění, nemoudrost i bláznovství, ale shledal jsem, že i to jest trápení ducha.
18 Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá, bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.
Nebo kde jest mnoho moudrosti, tu mnoho hněvu; a kdož rozmnožuje umění, rozmnožuje bolest.

< Ecclesiastes 1 >