< Deuteronomy 1 >
1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Acestea sunt cuvintele pe care le-a rostit Moise, întregului Israel, de partea aceasta a Iordanului în pustiu, în câmpia din dreptul Mării Roşii, între Paran şi Tofel şi Laban şi Haţerot şi Di-Zahab.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
(Sunt unsprezece zile de călătorie de la Horeb pe calea Muntelui Seir până la Cades-Barnea).
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Şi s-a întâmplat în al patruzecilea an, în a unsprezecea lună, în prima zi a lunii, că Moise a vorbit copiilor lui Israel, conform cu tot ceea ce DOMNUL i-a dat ca poruncă pentru ei;
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
După ce ucisese pe Sihon, împăratul amoriţilor, care locuia în Hesbon; şi pe Og, împăratul Basanului, care locuia la Aştarot, în Edrei,
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
De partea aceasta a Iordanului, în ţara Moabului, Moise a început să vestească această lege, spunând:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
DOMNUL Dumnezeul nostru ne-a vorbit la Horeb, spunând: Aţi locuit destul de mult pe muntele acesta;
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Întoarceţi-vă şi călătoriţi şi mergeţi la muntele amoriţilor şi la toate locurile apropiate de el, în câmpie, la dealuri şi la vale şi în sud şi pe ţărmul mării, în ţara canaaniţilor şi la Liban până la râul cel mare, râul Eufrat.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Iată, v-am pus ţara înainte, intraţi şi stăpâniţi ţara pe care DOMNUL a jurat-o părinţilor voştri, Avraam, Isaac şi Iacob, că le-o va da lor şi seminţei lor, după ei.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
Şi v-am vorbit în timpul acela, spunând: Nu vă pot purta singur,
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
DOMNUL Dumnezeul vostru v-a înmulţit şi, iată, astăzi sunteţi o mulţime ca stelele cerului.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
(DOMNUL Dumnezeul părinţilor voştri să vă facă de o mie de ori mai mulţi decât sunteţi şi să vă binecuvânteze, precum v-a promis!)
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Cum să pot purta eu singur necazul vostru şi povara voastră şi cearta voastră?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Luaţi-vă bărbaţi înţelepţi şi înţelegători şi cunoscuţi printre triburile voastre şi îi voi face conducători peste voi.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Şi mi-aţi răspuns şi aţi zis: Lucrul pe care l-ai spus să îl facem este bun.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Astfel că am luat pe mai marii triburilor voastre, bărbaţi înţelepţi şi cunoscuţi, şi i-am făcut capi peste voi, căpetenii peste mii şi căpetenii peste sute şi căpetenii peste cincizeci şi căpetenii peste zeci şi administratori printre triburile voastre,
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
Şi am poruncit judecătorilor voştri în timpul acela, spunând: Ascultaţi cauzele dintre fraţii voştri şi judecaţi cu dreptate între fiecare om şi fratele său şi străinul care este cu el.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Să nu fiţi părtinitori în judecată, ci să ascultaţi atât pe cel mic cât şi pe cel mare; să nu vă temeţi de faţa omului, pentru că judecata este a lui Dumnezeu şi cauza care este prea grea pentru voi să o aduceţi la mine şi o voi asculta.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
Şi v-am poruncit în timpul acela toate lucrurile pe care trebuie să le împliniţi.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Şi când am plecat de la Horeb, am mers prin tot pustiul acela mare şi înfricoşător, pe care l-aţi văzut pe calea spre muntele amoriţilor, precum ne-a poruncit DOMNUL Dumnezeul nostru; şi am venit la Cades-Barnea.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
Şi v-am spus: Aţi ajuns la muntele amoriţilor, pe care ni-l dă DOMNUL Dumnezeul nostru.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Iată, DOMNUL Dumnezeul tău a pus ţara înaintea ta, urcă-te şi stăpâneşte-o, precum ţi-a spus DOMNUL Dumnezeul părinţilor tăi; nu te teme nici nu te descuraja.
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Şi v-aţi apropiat toţi de mine şi aţi spus: Să trimitem oameni înaintea noastră, să cerceteze ţara pentru noi şi să ne aducă ştire din nou despre calea pe care să ne urcăm şi despre cetăţile la care vom ajunge.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Şi spusa aceasta mi-a plăcut mult; şi am luat doisprezece bărbaţi dintre voi, un bărbat din fiecare trib,
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Şi s-au întors şi s-au urcat la munte şi au venit până la Valea Eşcol şi au cercetat-o.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Şi au luat în mâinile lor din rodul ţării şi ni l-au adus jos; şi ne-au adus ştire din nou şi au spus: Este o ţară bună pe care ne-a dat-o DOMNUL Dumnezeul nostru.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
Totuşi nu aţi voit să vă urcaţi, ci v-aţi răzvrătit împotriva poruncii DOMNULUI Dumnezeul vostru.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Şi aţi cârtit în corturile voastre şi aţi spus: Pentru că DOMNUL ne urăşte, ne-a scos din ţara Egiptului, ca să ne dea în mâna amoriţilor, să ne nimicească.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Unde să ne urcăm? Fraţii noştri ne-au descurajat inima, spunând: Poporul este mai mare şi mai înalt decât noi; cetăţile sunt mari şi cu ziduri până la cer; şi mai mult, am văzut acolo pe copiii anachimilor.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Atunci v-am spus: Nu vă îngroziţi, nici nu vă temeţi de ei.
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
DOMNUL Dumnezeul vostru care merge înaintea voastră, el se va lupta pentru voi, conform cu tot ce a făcut pentru voi în Egipt, înaintea ochilor voştri;
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
Şi în pustiu, unde ai văzut cum DOMNUL Dumnezeul tău te-a purtat, precum poartă un om pe fiul său, pe tot drumul pe care aţi umblat, până aţi ajuns în acest loc.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Totuşi în acest lucru nu aţi crezut pe DOMNUL Dumnezeul vostru,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
Care a mers pe cale înaintea voastră, să cerceteze pentru voi un loc unde să vă înălţaţi corturile, noaptea în foc, să vă arate calea pe care să mergeţi şi ziua într-un nor.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Şi DOMNUL a auzit vocea cuvintelor voastre şi s-a înfuriat şi a jurat, spunând:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
Negreşit niciunul dintre aceşti oameni din această generaţie rea nu va vedea ţara aceea bună, pe care am jurat să o dau părinţilor voştri,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
În afară de Caleb, fiul lui Iefune, el o va vedea; şi îi voi da pământul pe care a călcat, lui şi fiilor lui, deoarece a urmat pe deplin pe DOMNUL.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Şi DOMNUL s-a mâniat şi pe mine, din cauza voastră, spunând: De asemenea nici tu nu vei intra acolo.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Ci Iosua, fiul lui Nun, care stă în picioare înaintea ta, el va intra acolo; încurajează-l, pentru că el va face pe Israel să o moştenească.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Mai mult, micuţii voştri, despre care aţi spus că vor fi o pradă şi copiii voştri, care în acea zi nu au cunoscut între bine şi rău, ei vor intra acolo şi lor le-o voi da şi o vor stăpâni.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Dar cât despre voi, întoarceţi-vă şi călătoriţi în pustiu pe calea Mării Roşii.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Şi aţi răspuns şi mi-aţi zis: Am păcătuit împotriva DOMNULUI; ne vom urca şi vom lupta, conform cu tot ceea ce ne-a poruncit DOMNUL Dumnezeul nostru. Şi când v-aţi încins fiecare cu armele sale de război, aţi fost gata să vă urcaţi pe deal.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Şi DOMNUL mi-a zis: Spune-le: Să nu vă urcaţi nici să nu luptaţi, ca să nu fiţi loviţi înaintea duşmanilor voştri, fiindcă eu nu sunt printre voi.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Astfel v-am vorbit, dar aţi refuzat să ascultaţi şi v-aţi răzvrătit împotriva poruncii DOMNULUI şi v-aţi urcat înfumurați pe deal.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Şi amoriţii, care au locuit pe acel munte, au ieşit împotriva voastră şi v-au urmărit, precum fac albinele, şi v-au nimicit în Seir, până la Horma.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Şi v-aţi întors şi aţi plâns înaintea DOMNULUI, dar DOMNUL nu a dat ascultare vocii voastre, nici nu şi-a plecat urechea spre voi.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
Astfel că aţi locuit în Cades multe zile, conform cu zilele cât aţi stat acolo.