< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
La ngamazwi akhulunywa nguMosi kubo bonke abako-Israyeli enkangala, empumalanga yeJodani, lokhu kuyikuthi, e-Arabha, maqondana leSufi, phakathi kwePharani leThofeli, eLabhani, eHazerothi kanye laseDizahabi.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
(Loluhambo luthatha insuku ezilitshumi lanye ukusuka eHorebhi kusiya eKhadeshi Bhaneya ngomgwaqo odlula eNtabeni yaseSeyiri.)
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Ngomnyaka wamatshumi amane, ngosuku lwakuqala lwenyanga yetshumi lanye, uMosi wamemezela kwabako-Israyeli konke lokho uThixo ayemlaye ngakho ngabo.
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Lokhu kwakungemva kokuba esenqobe uSihoni inkosi yama-Amori, owayebusa eHeshibhoni, njalo wayesenqobe e-Edreyi u-Ogi inkosi yaseBhashani, owayebusa e-Ashitharothi.
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Empumalanga kweJodani elizweni laseMowabi, uMosi waqalisa ukufundisa ngalo umthetho, esithi:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
“UThixo uNkulunkulu wethu wakhuluma lathi siseHorebhi wathi, ‘Selihlale isikhathi eseneleyo kule intaba.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Dilizani izihonqo zenu ledlulele elizweni lamaqaqa lama-Amori; yanini kubo bonke abangomakhelwane e-Arabha, ezintabeni, emawatheni angentshonalanga, eNegebi lilandelele ukhumbi, liye ezweni lamaKhenani kanye laseLebhanoni, lidabule lize liyefika emfuleni omkhulu, iYufrathe.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Khangelani, sengiliphile lelilizwe. Ngenani lilithumbe lelilizwe uThixo afunga wathi uzalipha okhokho benu, u-Abhrahama, u-Isaka, uJakhobe kanye lezizukulwane zabo emva kwabo.’”
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
“Ngalesosikhathi ngathi kini, ‘Lina lingumthwalo omkhulu kakhulu onzima ukuthi ngiwuthwale ngingedwa.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
UThixo uNkulunkulu wenu usengezelele amanani enu okokuthi lamuhla selilingana lezinkanyezi zemkhathini.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Sengathi uThixo, uNkulunkulu wabokhokho benu, angalibusisa njalo alandise ngokuphindwe kankulungwane njengokuthembisa kwakhe!
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Kodwa ngingazithwala njani inhlupho zenu lemithwalo yenu kanye lezingxabano zenu ngingedwa na?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Khethani amadoda akhaliphileyo, azwisisayo lahloniphekayo phakathi kwezizwana zakini zonke, mina ngizawabeka alikhokhele.’
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Langiphendula lathi, ‘Lokho ofisa ukukwenza kulungile.’
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Ngakho ngathatha abakhokheli bezizwana zenu, amadoda akhaliphileyo njalo ahloniphekayo, ngabanika amandla phezu kwenu ukuze babe ngabalawuli bezinkulungwane, bamakhulu, bamatshumi amahlanu, betshumi kanye lokuba yizikhulu zezizwana zenu.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
Njalo ngapha isiqondiso kubahluleli ngalesosikhathi ngathi: ‘Hluzani ingxabano phakathi kwabafowenu njalo lahlulele ngokufaneleyo, kungakhathalekile ukuthi yingxabano phakathi kwabako-Israyeli bodwa loba kungowako-Israyeli oxabana lowezizweni.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Lingathathi hlangothi ekwahluleleni; hluzani amacala abancinyane labakhulu ngokufananayo. Lingesabi loba ngubani, ngoba ukwahlulela ngokukaNkulunkulu. Kuthi icala elinzima lililethe kimi, ngizalihluza ngilahlulele.’
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
Njalo ngalesosikhathi ngalitshela konke okwakumele likwenze.”
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
“Kwathi-ke, njengoba uThixo wethu wayesilayile, sasuka eHorebhi saqonda ezweni lama-Amori elilamaqaqa sadabula inkangala enkulu eyesabekayo eseliyibonile, saze sayafika eKhadeshi Bhaneya.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
Ngakho ngathi kini, ‘Selifikile elizweni lama-Amori elamaqaqa, ilizwe uThixo uNkulunkulu wethu asinika lona.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Khangelani, uThixo uNkulunkulu wenu uselinike lelilizwe. Hambani lilithumbe njengoba uThixo, uNkulunkulu wabokhokho benu alitshela. Lingesabi; lingadangali.’
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Kusenjalo lina lonke leza kimi lathi, ‘Asithumeni amadoda ahambe phambili ayehlola lelolizwe abuye azositshengisa indlela esizangena ngayo kanye leyokuthumba amadolobho esizafikela kuwo.’
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Lokho kwakhanya kungumbono omuhle kimi; lakanye ngakhetha abalitshumi lababili phakathi kwenu, indoda eyodwa esizwaneni ngasinye.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Basuka baya ezweni lamaqaqa njalo bafika bahlola isihotsha sase-Eshikholi.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Bathatha ezinye izithelo zelizwe babuya lazo kithi, njalo bethula umbiko othi, ‘Yilizwe elihle uThixo uNkulunkulu wethu asipha lona.’”
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
“Kodwa lina lalingazimiselanga ukuhamba; lahlamukela uThixo uNkulunkulu wenu ngokungalaleli umlayo wakhe.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Lina lakhonona lisemathenteni enu lathi, ‘UThixo uyasizonda; kutsho ukuthi wasikhipha eGibhithe ukuze asinikele ezandleni zama-Amori ukuthi asibhubhise.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Singaya ngaphi na? Abafowethu sebesithelele ubuthakathaka. Bathi bona, “Abantu bakhona balamandla njalo bade kulathi; amadolobho akhona makhulu, alemiduli etshaya emkhathini. Size sabona lama-Anakhi khonale.”’
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Mina ngasengisithi kini, ‘Lingethuki; lingabesabi.
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
UThixo uNkulunkulu wenu ohamba phambi kwenu uzalilwela, njengalokho alenzela khona eGibhithe lizibonela ngamehlo enu,
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
njalo lasenkangala. Khonale lazibonela ukuthi uThixo uNkulunkulu wenu walithwala, njengobaba ethwala indodana yakhe, uhambo lwenu lonke laze lafika lapha.’
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Lanxa kunjalo, kalizange limethembe uThixo uNkulunkulu wenu,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
yena owahamba phambi kwenu kuloluhambo, elikhokhela ngomlilo ebusuku kanti kusiba leyezi emini, elidingela izindawo zokumisa izihonqo zenu lokulitshengisa lapho okumele liye khona.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Kwathi uThixo esezwile elalikutsho, wathukuthela, wafunga wathi:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
‘Kakho loyedwa kulesisizukulwane esingalunganga ozalibona lelolizwe engafungela ukulipha okhokho benu,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
ngaphandle kukaKhalebi indodana kaJefune. Yena uzalibona, njalo ngizamupha yena lesizukulwane sakhe lelolizwe azafikela kilo, ngoba walalela uThixo ngenhliziyo yakhe yonke.’
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Ngenxa yenu uThixo wangithukuthelela lami njalo wathi, ‘Wena lawe awuyikungena khona.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Kodwa umsekeli wakho, uJoshuwa indodana kaNuni, uzangena kulelolizwe. Umkhuthaze yena, ngoba uzakhokhela abako-Israyeli kulo ukuba libe yilifa labo.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Kanti njalo lalabo abancane elalisithi bazathunjwa, abantwabenu abangakehlukanisi phakathi kokubi lokuhle, bazangena kulelolizwe. Ngizabapha lona njalo bazalithatha libe ngelabo.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Kodwa lina, phendukani njalo lisuke liqonde enkangala lilandele indlela eya oLwandle oluBomvu.’
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Lina laphendula lathi, ‘Sonile kuThixo. Sizahamba siyekulwa, njengokulaywa kwethu nguThixo uNkulunkulu wethu.’ Ngalokho lonke lahloma ngezikhali linakana ukuthi kulula ukungena elizweni lamaqaqa.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Kodwa uThixo wathi kimi, ‘Wothi kubo, “Lingayi ukuyakulwa, ngoba kangiyikuba lani. Lizakwehlulwa yizitha zenu.”’
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Ngakho ngalitshela, kodwa kalizange lilalele. Lahlamukela umlayo kaThixo kwathi ngobuqholo benu layangena elizweni lamaqaqa.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Kwathi ama-Amori ayehlala kulawomaqaqa alihlangabeza alihlasela; alixotsha njengomtshitshi wenyosi, alibhuqa kusukela eSeyiri indlela yonke kusiya eHoma.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Laphenduka lafika lakhala phambi kukaThixo kodwa kazange alalele ukukhala kwenu walifulathela.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
Ngakho lahlala eKhadeshi okwensuku ezinengi, okwesikhathi sonke elasichitha likhonale.”

< Deuteronomy 1 >