< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Šie ir tie vārdi, ko Mozus runāja uz visu Israēli viņpus Jardānes tuksnesī, tai klajumā pret Sūfu, starp Pāranu un Tovelu un Labanu un Hacerotu un Dizaābu,
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
Vienpadsmit dienu gājumus no Horeba, pa Seīra kalna ceļu līdz Kādeš-Barneai.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Un notikās četrdesmitā gadā, vienpadsmitā mēnesī, pirmā mēneša dienā, tad Mozus runāja uz Israēla bērniem, kā Tas Kungs viņam priekš tiem bija pavēlējis,
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Pēc tam, kad viņš bija sakāvis Sihonu, Amoriešu ķēniņu, kas dzīvoja Hešbonā, un Ogu, Basanas ķēniņu, kas dzīvoja Astarotā un Edrejā.
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Viņpus Jardānes, Moaba zemē, Mozus sāka šo bauslību izskaidrot sacīdams:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
Tas Kungs mūsu Dievs runāja uz mums Horeba kalnā un sacīja: jūs gan ilgi esat palikuši pie šā kalna.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Griežaties un ceļaties un ejat uz Amoriešu kalniem un pie visiem viņu kaimiņiem klajumā, kalnos un lejā un pret dienvidiem un jūras malā, uz Kanaāna zemi un uz Lībanu, līdz tai lielai upei, tai Eifrat upei.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Redzi, Es jums nododu šo zemi, ejat, uzņemat to zemi, ko Tas Kungs jūsu tēviem Ābrahāmam, Īzakam un Jēkabam ir zvērējis, dot viņiem un viņu dzimumam pēc viņiem.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
Un tanī laikā es uz jums runāju un sacīju: es viens pats jūs nevaru panest.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Tas Kungs, jūsu Dievs, jūs ir vairojis, un redzi, jūs šodien esat savā pulkā tā kā debess zvaigznes.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Tas Kungs, jūsu tēvu Dievs, lai vēl pie jums pieliek, ka esat tūkstoškārt vairāk, un lai jūs svētī, itin kā Viņš uz jums ir runājis.
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Kā man vienam būs panest jūsu grūtumu un nastu un strīdu?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Dabūjat sev gudrus, prātīgus un zināmus vīrus pēc savām ciltīm, lai tos jums ieceļu par virsniekiem.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Un jūs man atbildējāt sacīdami: tas ir labs vārds, ko tu runā, ka to gribi darīt.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Tad es ņēmu jūsu cilšu virsniekus, gudrus un zināmus vīrus, un tos iecēlu par virsniekiem pār jums, virsniekus pār tūkstošiem un virsniekus pār simtiem un virsniekus pār piecdesmitiem un virsniekus pār desmitiem un uzraugus pēc jūsu ciltīm.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
Un es jūsu soģiem tanī laikā pavēlēju un sacīju: pārklausinājiet tās lietas starp jūsu brāļiem un tiesājiet taisni starp ikvienu un viņa brāli un viņa piedzīvotāju.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Tiesā jums nebūs uzlūkot vaigu, tāpat mazo kā lielo jums būs klausīt, no neviena jums nebūs bīties, jo tas sods pieder Dievam; bet to lietu, kas priekš jums par grūtu, to jums būs nest pie manis, un es to klausīšu.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
Tā es jums tanī laikā pavēlēju visas lietas, kas jums bija jādara. -
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Tad mēs cēlāmies no Horeba un gājām caur visu to lielo un briesmīgo tuksnesi, ko jūs esat redzējuši, pa to ceļu uz Amoriešu kalniem, itin kā Tas Kungs, mūsu Dievs, mums bija pavēlējis, un mēs nācām uz Kādeš-Barneū.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
Tad es jums sacīju: jūs esat nākuši pie Amoriešu kalniem, ko Tas Kungs, mūsu Dievs, mums dos.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Redzi, Tas Kungs, tavs Dievs, tev ir devis to zemi, celies, uzņem to, kā Tas Kungs, tavu tēvu Dievs, uz tevi runājis; nebīsties un neiztrūcinājies.
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Tad jūs visi nācāt pie manis un sacījāt: sūtīsim vīrus savā priekšā, mums to zemi izlūkot un mums ziņu atnest, pa kuru ceļu lai ejam uz turieni, un par tām pilsētām, kurp nāksim.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Tad man šī lieta patika un es ņēmu no jums divpadsmit vīrus, no ikvienas cilts vienu vīru.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Un tie griezās un gāja uz tiem kalniem un nāca pie Eškoles upes un to izlūkoja.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Un tie ņēma no tiem zemes augļiem savā rokā un atnesa tos pie mums un stāstīja mums un sacīja: tā zeme, ko Tas Kungs, mūsu Dievs, mums dos, ir laba.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
Bet jūs negribējāt iet un bijāt nepaklausīgi Tā Kunga, sava Dieva, vārdam.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Un jūs kurnējāt savos dzīvokļos un sacījāt: tāpēc ka Tas Kungs mūs ienīst, Viņš mūs izvedis no Ēģiptes zemes, mūs nodot Amoriešu rokā un mūs izdeldēt.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Kurp mums iet? Mūsu brāļi mūsu sirdi darījuši bailīgu sacīdami: tur ir ļaudis lielāki un garāki nekā mēs, tās pilsētas ir lielas un stipras līdz pat debesīm, un mēs tur arī esam redzējuši Enaka bērnus.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Tad es uz jums sacīju: neiztrūcināties un nebīstaties no tiem.
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Tas Kungs, jūsu Dievs, kas iet jūsu priekšā, karos par jums, itin kā Viņš pie jums ir darījis Ēģiptes zemē priekš jūsu acīm,
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
Un tuksnesī, kur tu esi redzējis, kā Tas Kungs, tavs Dievs, tevi nesis, itin kā vīrs savu dēlu nes, uz visiem ceļiem, kur tu esi gājis, tiekams jūs esat nākuši līdz šai vietai.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Bet arī pie šī vārda jūs neticējāt uz To Kungu, savu Dievu,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
Kas jūsu priekšā gāja ceļā, jums izlūkodams to vietu, kur jums apmesties pa nakti, ugunī jums rādīdams to ceļu, kas jums bija jāstaigā, un pa dienu padebesī.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Kad nu Tas Kungs jūsu vārdu balsi dzirdēja, tad Viņš apskaitās un zvērēja sacīdams:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
Nevienam no šiem vīriem, no šā niknā auguma, nebūs redzēt to labo zemi, ko Es esmu zvērējis dot jūsu tēviem,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
Kā vien Kālebam, Jefunna dēlam, tam to būs redzēt, un tam Es došu to zemi, kur viņš staigājis, un viņa bērniem, tāpēc ka viņš pareizi klausījis Tam Kungam.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Tas Kungs arī par mani apskaitās jūsu dēļ un sacīja: arī tu tur nenonāksi.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Jozuas, Nuna dēls, kas stāv tavā priekšā, tas tur nonāks; stiprini viņu, jo tas Israēlim to zemi izdalīs.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Un jūsu bērniņi, par kuriem jūs sacījāt, ka būšot par laupījumu, un jūsu bērni, kas šodien nezin nedz laba nedz ļauna, tie tur nonāks, un tiem Es to došu, un tiem to būs iemantot.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Bet jūs griežaties un ejat uz tuksnesi pa niedru jūras ceļu.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Tad jūs man atbildējāt un sacījāt: mēs pret To Kungu esam grēkojuši, mēs celsimies un karosim, kā Tas Kungs, mūsu Dievs, mums ir pavēlējis. Kad nu jūs ikviens ar saviem rīkiem apbruņojaties un bijāt gatavi iet uz tiem kalniem,
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Tad Tas Kungs uz mani sacīja: saki viņiem, neceļaties un nekarojiet, jo Es neesmu jūsu vidū, ka netopat sakauti savu ienaidnieku priekšā.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Bet kad es uz jums runāju, tad jūs neklausījāt un turējaties Tā Kunga vārdam pretī un palikāt pārgalvīgi un gājāt uz tiem kalniem.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Tad tie Amorieši, kas tanīs kalnos dzīvoja, jums izgāja pretī un dzinās jums pakaļ, kā bites dara, un jūs sakāva Seīrā līdz Hormai.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Kad jūs nu atgriezušies Tā Kunga priekšā raudājāt, tad Tas Kungs neklausīja jūsu balsi un negrieza Savas ausis uz jums.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
Un jūs palikāt Kādešā ilgu laiku, tās dienas, ko tur esat dzīvojuši.

< Deuteronomy 1 >