< Deuteronomy 1 >
1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Disse ere de Ord, som Mose har talet til al Israel paa hin Side Jordanen, i Ørken paa den slette Mark, over for Suf, imellem Paran og imellem Tofel og Laban og Hazeroth og Di-Sahab,
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
elleve Dages Rejse fra Horeb til Seirs Bjerge, indtil Kades-Barnea.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Og det skete i det fyrretyvende Aar, i den ellevte Maaned, paa den første Dag i Maaneden, da talede Mose til Israels Børn, efter alt det som Herren havde budet ham til dem,
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
efter at han havde slaaet Sihon, Amoriternes Konge, som boede i Hesbon, og Og, Kongen af Basan, som boede i Astharoth ved Edrei.
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Paa hin Side Jordanen i Moabiternes Land begyndte Mose at udlægge denne Lov og sagde:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
Herren vor Gud talede til os ved Horeb og sagde: I have længe nok været ved dette Bjerg.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Vender om og rejser, og drager til Amoriternes Bjerg, og til alle deres Naboer paa den slette Mark, paa Bjergene og i Lavlandet, og i Sønden og ved Havets Strand; til Kananiternes Land og til Libanon, indtil den store Flod, den Flod Frat.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Se, jeg har givet det Land for eders Ansigt; kommer og indtager det Land, som Herren har tilsvoret eders Fædre, Abraham, Isak og Jakob at give dem og deres Sæd efter dem.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
Da talede jeg til eder paa den samme Tid og sagde: Jeg kan ikke ene bære eder.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Herren eders Gud har gjort eder mangfoldige, og se, I ere i Dag som Stjernerne paa Himmelen i Mangfoldighed.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Herren eders Fædres Gud lægge tusinde Gange flere til eder, end I ere, og han velsigne eder, som han har sagt eder!
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Hvorledes kan jeg ene bære eders Besvær og eders Byrde og eders Trætte?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Forskaffer mig vise og forstandige og forsøgte Mænd af eders Stammer, og jeg vil sætte dem til Høvedsmænd over eder.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Da svarede I mig og sagde: Det er en god Ting, som du siger, at du vil gøre.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Saa tog jeg eders Stammers Høvedsmænd, vise og forsøgte Mænd, og satte dem til Høvedsmænd over eder: Til Øverster over Tusinder og Øverster over Hundreder og Øverster over halvtredssindstyve og Øverster over ti og til Fogeder for eders Stammer.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
Og jeg bød eders Dommere paa samme Tid og sagde: Hører Sagerne imellem eders Brødre og dømmer med Retfærdighed imellem en Mand og hans Broder og imellem den fremmede hos ham.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
I skulle i Dommen ikke anse Personen, I skulle høre den mindste med den største, I skulle ikke frygte for nogen, thi Dommen hører Gud til; men den Sag, som bliver eder for svar, lader den komme frem til mig, saa vil jeg høre den.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
Da bød jeg eder paa samme Tid alt, hvad I skulle gøre.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Saa rejste vi fra Horeb og gik igennem hele den store og forfærdelige Ørk, hvilken I saa, ad Vejen til Amoritens Bjerg, som Herren vor Gud befalede os; og vi kom til Kades-Barnea.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
Da sagde jeg til eder: I ere komne til Amoritens Bjerg, hvilket Herren vor Gud vil give os.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Se, Herren din Gud har givet det Land for dit Ansigt; drag op, indtag det, som Herren dine Fædres Gud har sagt dig, frygt ikke og ræddes ikke.
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Da kom I alle frem til mig og sagde: Lader os sende Mænd for vort Ansigt, som kunne udforske os Landet, og de skulle bringe os Svar om, ad hvilken Vej vi skulle drage op, og om de Stæder, som vi skulle komme til.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Og de Ord behagede mig, saa jeg tog tolv Mænd af eder, een Mand for hver Stamme.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Og de vendte sig og droge op paa Bjerget og kom til Eskols Bæk, og de bespejdede det.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Og de toge i deres Haand af Landets Frugt og førte ned til os, og de bragte os Svar og sagde: Det er et godt Land, som Herren vor Gud har givet os.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
Men I vilde ikke drage op, og I vare genstridige mod Herren eders Guds Mund.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Og I knurrede i eders Telte og sagde: Fordi Herren hader os, har han udført os af Ægyptens Land, for at give os i Amoriternes Haand til at ødelægge os.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Hvorhen skulle vi drage op? Vore Brødre have mistrøstet vort Hjerte og sagt: Det Folk er større og højere end vi, Stæderne ere store og befæstede op imod Himmelen, dertil med have vi ogsaa set Anakiternes Børn der.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Da sagde jeg til eder: Lader eder ikke forfærde og frygter ej for dem!
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Herren eders Gud, som gaar foran eders Ansigt, han skal stride for eder, ganske som han gjorde med eder i Ægypten for eders Øjne,
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
og i Ørken, som du har set, hvor Herren din Gud har baaret dig, ligesom en Mand bærer sin Søn; paa hele den Vej, som I have vandret, indtil I ere komne til dette Sted.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Men uagtet dette Ord troede I ikke paa Herren eders Gud,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
han, som gik for eders Ansigt paa Vejen at opsøge for eder Stedet, hvor I skulde lejre eder, i en Ild om Natten, for at vise eder Vejen, som I skulde gaa paa, og i en Sky om Dagen.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Der Herren hørte eders Ords Røst, da blev han vred og svor og sagde:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
Der skal ingen af disse Mænd, af denne onde Slægt, se det gode Land, som jeg svor at ville give eders Fædre,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
uden Kaleb, Jefunne Søn; han skal se det, og ham og hans Børn vil jeg give det Land, som han har traadt paa, fordi han har fuldkommeligen efterfulgt Herren.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Herren blev endog vred paa mig for eders Skyld, og sagde: Du skal ikke heller komme derind.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Josva, Nuns Søn, som staar for dit Ansigt, han skal komme derhen; styrk ham, thi han skal dele det til Arv iblandt Israel.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Og eders smaa Børn, om hvilke I sagde: De skulle blive til Rov, og eders Sønner, som ikke paa denne Dag forstaa godt eller ondt, de skulle komme derind, og jeg vil give dem det, og de skulle arve det.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Men I, vender eder og rejser til Ørken ad Vejen til det røde Hav.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Da svarede I og sagde til mig: Vi have syndet imod Herren, vi ville drage op og stride, ganske som Herren vor Gud befalede os; og I bandt om eder, hver sine Krigsvaaben, og vare letsindige til at drage op paa Bjerget.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Da sagde Herren til mig: Sig dem, I skulle ikke drage op, og I skulle ikke stride, thi jeg er ikke midt iblandt eder; at I ikke skulle blive slagne for eders Fjenders Ansigt.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Der jeg sagde eder det, da vilde I ikke høre mig; og I vare genstridige imod Herrens Mund, og formastede eder hovmodeligen og droge op paa Bjerget.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Da droge Amoriterne, som boede paa det samme Bjerg, ud imod eder, og de forfulgte eder, saaledes som Bier gøre, og de knusede eder i Seir, lige til Horma.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Der I kom tilbage og græd for Herrens Ansigt, da hørte Herren ikke paa eders Røst og bøjede ikke Øret til eder.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
Saa bleve I i Kades mange Dage, al den Tid, I bleve der.