< Deuteronomy 9 >

1 Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
Ascultă, Israele: Astăzi treci Iordanul, ca să intri să stăpâneşti naţiuni mai mari şi mai tari decât tine, cetăţi mari şi întărite până la cer,
2 Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
Un popor mare şi înalt, copiii anachimilor, pe care îi cunoşti şi despre care ai auzit spunându-se: Cine poate sta înaintea fiilor lui Anac?
3 Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
Înţelege de aceea astăzi, că DOMNUL Dumnezeul tău este cel care trece înaintea ta; ca un foc mistuitor îi va nimici el şi îi va supune înaintea ta; astfel îi vei alunga şi îi vei nimici repede, precum ţi-a spus DOMNUL.
4 Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
Să nu vorbeşti în inima ta, după ce DOMNUL Dumnezeul tău îi va fi alungat dinaintea ta, spunând: Pentru dreptatea mea m-a adus DOMNUL să stăpânesc această ţară, căci pentru stricăciunea acestor naţiuni le alungă DOMNUL dinaintea ta.
5 Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Nu pentru dreptatea ta sau pentru integritatea inimii tale intri tu să stăpâneşti ţara lor, ci pentru stricăciunea acestor naţiuni le alungă DOMNUL Dumnezeul tău dinaintea ta şi pentru a împlini cuvântul, pe care l-a jurat DOMNUL către părinţii tăi: Avraam, Isaac şi Iacob.
6 Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
Să înţelegi de aceea, că nu pentru dreptatea ta îţi dă DOMNUL Dumnezeul tău această ţară bună ca să o stăpâneşti, pentru că tu eşti un popor îndărătnic.
7 Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
Aminteşte-ţi şi nu uita cum l-ai provocat la furie pe DOMNUL Dumnezeul tău în pustiu, din ziua în care ai ieşit din ţara Egiptului, până aţi venit la locul acesta, aţi fost răzvrătiţi împotriva DOMNULUI.
8 Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
De asemenea la Horeb aţi provocat la furie pe DOMNUL, astfel încât DOMNUL s-a mâniat pe voi ca să vă nimicească.
9 Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
Când m-am urcat pe munte să primesc tablele de piatră, tablele legământului pe care l-a făcut DOMNUL cu voi, atunci am rămas pe munte patruzeci de zile şi patruzeci de nopţi, nu am mâncat pâine nici nu am băut apă;
10 Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
Şi DOMNUL mi-a dat două table de piatră, scrise cu degetul lui Dumnezeu; şi pe ele era scris conform cu toate cuvintele, pe care vi le-a vorbit DOMNUL pe munte, din mijlocul focului, în ziua adunării.
11 Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
Şi s-a întâmplat la sfârşitul celor patruzeci de zile şi patruzeci de nopţi, că DOMNUL mi-a dat cele două table de piatră, adică tablele legământului.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
Şi DOMNUL mi-a spus: Ridică-te, coboară-te repede de aici, pentru că poporul tău, pe care l-ai scos din Egipt, s-a stricat; repede s-au abătut de la calea, pe care le-am poruncit-o, şi-au făcut un chip turnat.
13 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
Mai mult, DOMNUL mi-a vorbit, spunând: Am văzut poporul acesta şi, iată, este un popor îndărătnic,
14 Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
Lasă-mă să îi nimicesc şi să le şterg numele de sub cer şi voi face din tine o naţiune mai puternică şi mai mare decât ei.
15 Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
Astfel m-am întors şi am coborât de pe munte şi muntele ardea cu foc; şi cele două table ale legământului erau în amândouă mâinile mele.
16 Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
Şi am privit şi, iată, aţi păcătuit împotriva DOMNULUI Dumnezeul vostru, v-aţi făcut un viţel turnat; repede v-aţi abătut de la calea pe care v-a poruncit-o DOMNUL.
17 Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
Şi am luat cele două table şi le-am aruncat din amândouă mâinile mele şi le-am spart înaintea ochilor voştri.
18 Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
Şi m-am prosternat înaintea DOMNULUI, ca întâia dată, patruzeci de zile şi patruzeci de nopţi, nici nu am mâncat pâine, nici nu am băut apă, din cauza tuturor păcatelor voastre pe care le-aţi păcătuit, făcând ce este stricat înaintea ochilor DOMNULUI, ca să îl provocaţi la mânie.
19 Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
Pentru că m-am temut de mânia şi de nemulțumirea încinsă cu care s-a înfuriat DOMNUL împotriva voastră să vă nimicească. Dar DOMNUL mi-a dat ascultare şi în timpul acela.
20 Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
Şi DOMNUL s-a mâniat pe Aaron, ca să îl nimicească, dar m-am rugat şi pentru Aaron în acelaşi timp.
21 Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
Şi am luat păcatul vostru, viţelul pe care l-aţi făcut, şi l-am ars în foc şi l-am zdrobit foarte mărunt, până a fost mărunt ca praful; şi i-am aruncat praful în pârâul care cobora din munte.
22 Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
Şi la Tabera şi la Masa şi la Chibrot-Hataava, aţi provocat la furie pe DOMNUL.
23 Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
De asemenea când v-a trimis DOMNUL de la Cades-Barnea, spunând: Urcaţi-vă şi stăpâniţi ţara pe care v-am dat-o, atunci v-aţi răzvrătit împotriva poruncii DOMNULUI Dumnezeul vostru şi nu l-aţi crezut şi nu aţi dat ascultare vocii lui.
24 Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
Aţi fost răzvrătiţi împotriva DOMNULUI din ziua în care v-am cunoscut.
25 Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
Astfel m-am prosternat înaintea DOMNULUI patruzeci de zile şi patruzeci de nopţi, cum m-am prosternat prima dată, pentru că DOMNUL a spus că voieşte să vă nimicească.
26 Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
M-am rugat de aceea DOMNULUI şi am spus: Doamne Dumnezeule, nu nimici poporul tău şi moştenirea ta, pe care ai răscumpărat-o prin măreţia ta, pe care l-ai scos din Egipt cu mână tare.
27 Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Aminteşte-ţi de servitorii tăi, Avraam, Isaac şi Iacob; nu privi la încăpăţânarea acestui popor, nici la stricăciunea lui, nici la păcatul lui;
28 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
Ca nu cumva ţara din care ne-ai scos să spună: Pentru că DOMNUL nu a fost în stare să îi ducă în ţara pe care le-a promis-o şi pentru că i-a urât, i-a scos ca să îi ucidă în pustiu.
29 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”
Totuşi ei sunt poporul tău şi moştenirea ta, pe care ai scos-o prin puterea ta cea mare şi prin braţul tău cel întins.

< Deuteronomy 9 >