< Deuteronomy 9 >
1 Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
Oe Isarelnaw thai awh haw. Nangmouh hlak a thakasai e miphun hai thoseh, kalvan kadeng e rapan hoi ka kawi e khopuinaw hai thoseh,
2 Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
Anakim miphun hmalah bangtelah vai kangdue thai tie lawk na thai teh, na panue e Anakim miphun tie kalenpounge miphun hai thoseh, tuk nateh lawp hanelah atu Jordan tui raka tawmlei toe.
3 Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
Hatdawkvah, na BAWIPA Cathut ni na hmalah a cei teh, ka kang e hmai patetlah ao teh, ahnimouh a raphoe vaiteh, na hmaitung vah, a tabo han tie hah na lungkuep awh. Cathut ni a dei e patetlah nang ni ahnimouh na pâlei awh vaiteh karang poung lah na raphoe awh han.
4 Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
BAWIPA na Cathut ni ahnimouh nang koehoi a pâlei hnukkhu, nang ni kaie lannae dawk doeh BAWIPA ni hete ram ka kut dawk na poe telah na pouk payon vaih. Hote miphunnaw hawihoeh e dawk BAWIPA ni ka hmaitung hoi a pâlei telah pouk awh.
5 Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Na sak awh e hnokahawi dawk hai thoseh, lannae dawk hoi hai thoseh, hote ram a coe awh hane nahoeh. Hete miphunnaw hawihoeh dawk hoi thoseh, BAWIPA ni na pa Abraham, Isak, Jakop koe lawkkam e lawk hah, a caksak nahan na Cathut ni ahnimouh na hmalah hoi a pâlei e doeh.
6 Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
Hatdawkvah, na BAWIPA ni nama e na hawinae dawk hoi, kahawipoung e ram na poe e nahoeh, nang teh na lahuen ka cak e miphun doeh.
7 Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
Nang ni kahrawngum vah BAWIPA lung na khuek sak e hah, pahnim hanh. Izip ram hoi na tâco pasuek nah, hete hmuen koe na pha a totouh, BAWIPA koe taran lah na thaw awh.
8 Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
Horeb vah BAWIPA a lung na khuek sak awh teh, nangmouh raphoe hane totouh, BAWIPA hah a lungkhuek.
9 Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
BAWIPA hoi lawkkamnae thutnae talung, lungphen la hanelah, mon lah ka luen navah, hnin 40 touh thung vaiyei hoi tui ka catnet laipalah, mon vah ka o.
10 Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
BAWIPA Cathut ni lungphen kahni touh Cathut e kut hoi thut e na poe. Na kamkhueng hnin vah, mon som hmai dawk hoi a dei e lawknaw ao.
11 Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
Ahnin 40 arum 40 akuep navah hote lawkkam lungphen kahni touh e teh, BAWIPA Cathut ni kai koe na poe.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
Hahoi BAWIPA ni Thaw nateh karang cathuk leih. Izip ram hoi na tâcokhai e taminaw a rawk awh toe, tarawi hane ka poe e lamthung a phen awh toe. Kutsak meikapawk doeh a bawk awh toe.
13 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
BAWIPA ni, hete miphunnaw ka khet nah, a lahuen mangkhak e miphunnaw doeh.
14 Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
Ka madueng na awm sak awh. Ahnimouh kai ni ka raphoe han. A min hai kalvan rahim vah ka raphoe han. Nang teh ahnimouh hlak tha na sai sak vaiteh, miphun ka pungdaw sak han telah a ti.
15 Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
Hatnavah lawkkam talung kahni touh ka sin teh, ka kamlang teh hmai ka kang e mon dawk hoi ka kum.
16 Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
Nangmouh ni, BAWIPA Cathut koe na yon awh teh, maito meikaphawk hlun awh teh, Cathut ni lawk na poe e lamthung karang poung lah, na phen awh toe tie ka hmu navah,
17 Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
Kut roi hoi ka patuep e lungphen, kahni touh e hah nangmae hmaitung vah ka raphei.
18 Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
Nangmouh ni, BAWIPA lung na khuek sak nahanelah, a hmalah yonnae na sak awh e yon pueng dawkvah, yampa e patetlah BAWIPA hmalah ka tabo teh, hnin 40 rum 40 touh vaiyei hoi tui catnet laipalah ka o.
19 Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
Bangkongtetpawiteh, BAWIPA ni nangmouh na raphoe hanlah, puenghoi lungkhueknae a tâco sak e kai ni ka taki. Hatnavah BAWIPA ni kaie ka lawk bout na thai pouh.
20 Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
BAWIPA ni Aron raphoe hanelah a lung puenghoi a khuek dawkvah, Aron hane lahai ka ratoum.
21 Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
Yonnae tie na sak awh e maitoca hah ka la teh, a tui lah kalawng sak. A kanuikapin lah rekrek ka kanawi teh, mon dawk hoi ka lawng e palang dawk ka tâkhawng.
22 Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
Taberah, Messah hmuen, Kiborthhattaavah hmuen koe hai, nangmouh ni BAWIPA hah a lungkhuek nahanlah na sak awh.
23 Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
Kadeshbarnea hoi BAWIPA ni cet awh nateh, kai ni na poe e ram hah lat awh. Nangmouh na patoun awh navah, nangmouh ni nangmae BAWIPA e kâ poe e na kangek awh. BAWIPA na yuem awh hoeh, lawk hai ngâi laipalah na o awh.
24 Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
Ka panue hnin hoi nangmouh teh BAWIPA hah na taran awh toe.
25 Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
BAWIPA ni nangmouh na raphoe han telah a dei dawkvah, kai teh yampa e patetlah hnin 40 rum 40 touh ka tabo.
26 Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
BAWIPA koe, Oe Bawipa Jehovah, lentoenae hoi na ratang teh, thaonae kut hoi Izip hoi na tâcokhai e, nange râw lah kaawm e hete taminaw hah raphoe hanh loe.
27 Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Nange san Abraham, Isak, Jakop hah pahnim hanh. Hete miphunnaw teh a lungpatanae, a yonnae hoi a hawihoehnae pâkuem pouh hanh.
28 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
Hottelah hoeh pawiteh, tâconae ram dawk e taminaw ni, Cathut ni a kam pouh e ram dawk, a thokhai thai hoeh dawkvah, a hmu ngaihoeh dawk na ou, kahrawngum thei hanelah a ngai dawk na ou ati han nahoehmaw.
29 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”
Hetnaw teh lentoenae hoi, na kut na dâw teh, na tâcokhai e nange râwnaw doeh telah kai ni ka ratoum.