< Deuteronomy 8 >

1 Ẹ kíyèsi i láti máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ tí mo fún un yín lónìí, kí ẹ bá à le yè, kí ẹ sì pọ̀ sí i wọ ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le gba ilẹ̀ náà, tí Olúwa fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
Vse zapovedi, ki sem ti jih ta dan zapovedal, boste obeleževali, da jih izvršujete, da boste lahko živeli, se množili in vstopili in vzeli v last deželo, ki jo je Gospod prisegel vašim očetom.
2 Ẹ rántí bí Olúwa Ọlọ́run yín ti tọ́ ọ yín ṣọ́nà ní gbogbo ọ̀nà ní aginjù fún ogójì ọdún wọ̀nyí láti tẹ orí yín ba àti láti dán an yín wò kí ó ba à le mọ bí ọkàn yín ti rí, bóyá ẹ ó pa òfin rẹ̀ mọ́ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Spomnil se boš celotne poti, po kateri te je Gospod, tvoj Bog, teh štirideset let vodil po divjini, da te poniža in te preizkusi, da spozna kaj je bilo v tvojem srcu, bodisi se boš držal njegovih zapovedi ali ne.
3 Ó rẹ̀ yín sílẹ̀ nípa fífi ebi pa yín, Ó sì fi manna bọ́ ọ yín, èyí tí ẹ kò mọ̀, tí àwọn baba yín kò mọ̀, kí ó ba à lè kọ́ ọ yín pé, ènìyàn kò ti ipa oúnjẹ nìkan wà láààyè, bí kò ṣe ohun gbogbo tí ó jáde láti ẹnu Olúwa wá.
Ponižal te je in ti dopustil, da si bil lačen in te hranil z mano, ki je nisi poznal niti je niso poznali tvoji očetje, da bi ti on lahko dal spoznati, da človek ne živi samo od kruha, temveč človek živi od vsake besede, ki izhaja iz Gospodovih ust.
4 Aṣọ yín kò gbó mọ́ ọn yín lọ́rùn bẹ́ẹ̀ ní ẹsẹ̀ yín kò sì wú, ní ogójì ọdún náà.
Teh štirideset let se tvoja obleka na tebi ni postarala niti tvoje stopalo ni oteklo.
5 Ẹ mọ̀ ní ọkàn an yín pé, bí baba ti ń kọ́ ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín ń kọ́ ọ yín.
V svojem srcu boš tudi preudaril, da kakor mož kara svojega sina, tako Gospod, tvoj Bog, kara tebe.
6 Nítorí èyí, ẹ gbọdọ̀ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́, nípa rínrìn ní ọ̀nà rẹ̀, àti bíbẹ̀rù rẹ̀.
Zatorej boš varoval zapovedi Gospoda, svojega Boga, da hodiš po njegovih poteh in da se ga bojiš.
7 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ń mú un yín bọ̀ wá sí ilẹ̀ rere ilẹ̀ tí ó kún fún odò àti ibú omi, pẹ̀lú àwọn ìsun tí ń sàn jáde láti orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Kajti Gospod, tvoj Bog, te vodi v dobro deželo, deželo vodnih potokov, studencev in globin, ki privrejo iz dolin in hribov;
8 Ilẹ̀ tí ó kún fún jéró àti ọkà barle, tí ó sì kún fún àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́, igi pomegiranate, òróró olifi àti oyin.
deželo pšenice, ječmena, trt, figovih dreves in granatnih jabolk; deželo olivnega olja in medu;
9 Ilẹ̀ tí oúnjẹ kò ti wọ́n, kò sí ohun tí ẹ̀yin yóò ṣe aláìní, ilẹ̀ tí irin ti pọ̀ bí òkúta, ẹ̀yin sì lè wa idẹ jáde láti inú òkè rẹ̀ wá.
deželo, v kateri boš jedel kruh brez pomanjkanja, v njej ti ne bo primanjkovalo nobene stvari; deželo, katere kamni so železo in iz katerih hribov lahko koplješ bron.
10 Nígbà tí ẹ bá ti jẹ tí ẹ sì yó tán ẹ yin Olúwa Ọlọ́run yín fún pípèsè ilẹ̀ rere fún un yín.
Ko se naješ in si sit, potem boš blagoslovil Gospoda, svojega Boga, zaradi dobre dežele, ki ti jo je dal.
11 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, nípa kíkùnà láti pa àṣẹ rẹ̀, àwọn òfin rẹ̀, àti àwọn ìlànà rẹ̀ tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
Pazi se, da ne pozabiš Gospoda, svojega boga, da se ne bi držal njegovih zapovedi, njegovih sodb in njegovih zakonov, ki sem ti jih zapovedal ta dan,
12 Kí ó má ba à jẹ́ pé, nígbà tí ẹ bá jẹun yó tán, tí ẹ bá kọ́ ilé tí ó dára tán, tí ẹ sí ń gbé inú rẹ̀,
da se ne bi, ko se naješ in si sit in si si zgradil ljubke hiše in prebival v njih;
13 nígbà tí àwọn agbo màlúù yín àti tí ewúrẹ́ ẹ yín bá pọ̀ sí i tán, tí fàdákà àti wúrà yín sì ń peléke sí i, tí ohun gbogbo tí ẹ ní sì ń pọ̀ sí i,
in ko se tvoji tropi in tvoje črede pomnožijo in je pomnoženo tvoje srebro in tvoje zlato in je pomnoženo vse, kar imaš;
14 nígbà náà ni ọkàn yín yóò gbéga, tí ẹ̀yin yóò sì gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá, nínú oko ẹrú.
tvoje srce ne povzdigne in pozabiš na Gospoda, svojega Boga, ki te je privedel iz egiptovske dežele, iz hiše sužnosti,
15 Òun ni ó mú un yín la aginjù ẹlẹ́rù ńlá já, ilẹ̀ tí kò sí omi tí ó sì kún fún òǹgbẹ, pẹ̀lú àwọn ejò olóró ńlá ńlá àti àkéekèe. Ó mú omi jáde fún un yín láti inú àpáta.
ki te je vodil skozi to veliko in strašno divjino, v kateri so bile ognjene kače, škorpijoni in suša, kjer ni bilo vode; ki ti je vodo privedel iz kremenčeve skale;
16 Ó fún yín ní manna láti jẹ nínú aginjù, ohun tí àwọn baba yín kò mọ̀ rí, kí Òun bá à le tẹ orí yín ba kí ó sì lè dán an yín wò, kí ó bá à lè dára fún un yín.
ki te je v divjini hranil z mano, ki je tvoji očetje niso poznali, da bi te lahko ponižal in da bi te lahko preizkusil, da ti v tvojem zadnjem koncu stori dobro.
17 Ẹ lè rò nínú ara yín pé, “Agbára mi àti iṣẹ́ ọwọ́ mi ni ó mú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá fún mi.”
In ti bi rekel v svojem srcu: ›Moja moč in mogočnost moje roke mi je pridobila to premoženje.‹
18 Ṣùgbọ́n ẹ rántí Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fún un yín ní agbára àti lè ní àwọn ọrọ̀ wọ̀nyí, tí ó sì fi mú májẹ̀mú rẹ̀ ṣẹ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín bí ó ti rí lónìí.
Ampak se boš spominjal Gospoda, svojega Boga, kajti on je ta, ki ti daje moč, da pridobiš premoženje, da lahko on vzpostavi svojo zavezo, ki jo je prisegel tvojim očetom, kakor je to ta dan.
19 Bí ẹ bá wá gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn, tí ẹ sì sìn wọ́n, tí ẹ sì foríbalẹ̀ fún wọn, Mo kìlọ̀ fún un yín pé rírun ni ẹ̀yin yóò run.
Zgodilo pa se bo, če pozabite Gospoda, svojega Boga in hodite za drugimi bogovi in jim služite in jih obožujete, ta dan pričujem zoper vas, se boste zagotovo pogubili.
20 Bí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa parun níwájú u yín, bákan náà ni ẹ ó parun, torí pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín lẹ́nu.
Kakor narodi, ki jih Gospod uničuje pred vašim obrazom, tako se boste pogubili, ker niste hoteli biti poslušni glasu Gospoda, svojega Boga.

< Deuteronomy 8 >