< Deuteronomy 8 >
1 Ẹ kíyèsi i láti máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ tí mo fún un yín lónìí, kí ẹ bá à le yè, kí ẹ sì pọ̀ sí i wọ ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le gba ilẹ̀ náà, tí Olúwa fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
Вся заповеди, яже аз заповедаю вам днесь, снабдите творити, да живете, и умножитеся, и внидете, и наследите землю благую, еюже клятся Господь Бог отцем вашым.
2 Ẹ rántí bí Olúwa Ọlọ́run yín ti tọ́ ọ yín ṣọ́nà ní gbogbo ọ̀nà ní aginjù fún ogójì ọdún wọ̀nyí láti tẹ orí yín ba àti láti dán an yín wò kí ó ba à le mọ bí ọkàn yín ti rí, bóyá ẹ ó pa òfin rẹ̀ mọ́ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
И да помянеши весь путь, имже проведе тебе Господь Бог твой, сие четыредесятое лето в пустыни, да искусит тя и озлобит тя, и уразумеются яже в сердцы твоем, аще сохраниши заповеди Его или ни.
3 Ó rẹ̀ yín sílẹ̀ nípa fífi ebi pa yín, Ó sì fi manna bọ́ ọ yín, èyí tí ẹ kò mọ̀, tí àwọn baba yín kò mọ̀, kí ó ba à lè kọ́ ọ yín pé, ènìyàn kò ti ipa oúnjẹ nìkan wà láààyè, bí kò ṣe ohun gbogbo tí ó jáde láti ẹnu Olúwa wá.
И озлоби тя, и гладом замори тя, и напита тя манною, еяже ты не уведел еси, ни отцы твои: да возвестит тебе, яко не от хлебе единем жив будет человек, но о всяком словеси исходящем из уст Божиих жив будет человек.
4 Aṣọ yín kò gbó mọ́ ọn yín lọ́rùn bẹ́ẹ̀ ní ẹsẹ̀ yín kò sì wú, ní ogójì ọdún náà.
Ризы твоя не обетшаша на тебе: нозе твои не язвишася, се, четыредесять лет.
5 Ẹ mọ̀ ní ọkàn an yín pé, bí baba ti ń kọ́ ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín ń kọ́ ọ yín.
И уразумееши сердцем твоим, яко имже образом аще кий человек накажет сына своего, тако Господь Бог твой накажет тя.
6 Nítorí èyí, ẹ gbọdọ̀ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́, nípa rínrìn ní ọ̀nà rẹ̀, àti bíbẹ̀rù rẹ̀.
И сохраниши заповеди Господа Бога твоего ходити в путех Его и боятися Его.
7 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ń mú un yín bọ̀ wá sí ilẹ̀ rere ilẹ̀ tí ó kún fún odò àti ibú omi, pẹ̀lú àwọn ìsun tí ń sàn jáde láti orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Господь бо Бог твой введет тя в землю благую и многу, идеже водотечи водныя и источники бездны исходящыя по полям и горам,
8 Ilẹ̀ tí ó kún fún jéró àti ọkà barle, tí ó sì kún fún àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́, igi pomegiranate, òróró olifi àti oyin.
в землю пшеницы и ячменя, (идеже) виногради, смокви и щипцы, в землю масличия елеа и меда:
9 Ilẹ̀ tí oúnjẹ kò ti wọ́n, kò sí ohun tí ẹ̀yin yóò ṣe aláìní, ilẹ̀ tí irin ti pọ̀ bí òkúta, ẹ̀yin sì lè wa idẹ jáde láti inú òkè rẹ̀ wá.
в землю на нейже не с нищетою снеси хлеб твой, и ничесого востребуеши на ней: в землю в нейже камение железно, и от гор ея ископаеши медь:
10 Nígbà tí ẹ bá ti jẹ tí ẹ sì yó tán ẹ yin Olúwa Ọlọ́run yín fún pípèsè ilẹ̀ rere fún un yín.
и ясти будеши, и насытишися, и благословиши Господа Бога твоего на земли блазей, юже даде тебе.
11 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, nípa kíkùnà láti pa àṣẹ rẹ̀, àwọn òfin rẹ̀, àti àwọn ìlànà rẹ̀ tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
Вонми себе, не забуди Господа Бога твоего, еже не сохранити заповеди Его и судбы и оправдания Его, елика аз заповедаю тебе днесь:
12 Kí ó má ba à jẹ́ pé, nígbà tí ẹ bá jẹun yó tán, tí ẹ bá kọ́ ilé tí ó dára tán, tí ẹ sí ń gbé inú rẹ̀,
да не когда ядый и насытився, и домы добры соградив и вселився в ня,
13 nígbà tí àwọn agbo màlúù yín àti tí ewúrẹ́ ẹ yín bá pọ̀ sí i tán, tí fàdákà àti wúrà yín sì ń peléke sí i, tí ohun gbogbo tí ẹ ní sì ń pọ̀ sí i,
и волом твоим и овцам твоим умножившымся тебе, сребру и злату умножившымся тебе, и всем, елика тебе будут, умножившымся тебе,
14 nígbà náà ni ọkàn yín yóò gbéga, tí ẹ̀yin yóò sì gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá, nínú oko ẹrú.
вознесешися сердцем твоим, и забудеши Господа Бога твоего, изведшаго тя из земли Египетския, из дому работы:
15 Òun ni ó mú un yín la aginjù ẹlẹ́rù ńlá já, ilẹ̀ tí kò sí omi tí ó sì kún fún òǹgbẹ, pẹ̀lú àwọn ejò olóró ńlá ńlá àti àkéekèe. Ó mú omi jáde fún un yín láti inú àpáta.
проведшаго тя сквозе пустыню великую и страшную ону, в нейже змии угрызающыя, и скорпии, и жажда, в нейже не бяше воды: изведшаго тебе из камене несекома источник водный:
16 Ó fún yín ní manna láti jẹ nínú aginjù, ohun tí àwọn baba yín kò mọ̀ rí, kí Òun bá à le tẹ orí yín ba kí ó sì lè dán an yín wò, kí ó bá à lè dára fún un yín.
питавшаго тя манною в пустыни, еяже не ведел еси ты, ниже ведяху отцы твои, да озлобит тя и да искусит тя, и благо тебе сотворит на последок твой:
17 Ẹ lè rò nínú ara yín pé, “Agbára mi àti iṣẹ́ ọwọ́ mi ni ó mú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá fún mi.”
да не речеши в сердцы твоем: крепость моя и сила руки моея сотвори мне силу великую сию,
18 Ṣùgbọ́n ẹ rántí Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fún un yín ní agbára àti lè ní àwọn ọrọ̀ wọ̀nyí, tí ó sì fi mú májẹ̀mú rẹ̀ ṣẹ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín bí ó ti rí lónìí.
и помянеши Господа Бога твоего, яко Той даде тебе крепость, еже сотворити силу, и да уставит завет Свой, имже клятся отцем твоим, якоже днесь.
19 Bí ẹ bá wá gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn, tí ẹ sì sìn wọ́n, tí ẹ sì foríbalẹ̀ fún wọn, Mo kìlọ̀ fún un yín pé rírun ni ẹ̀yin yóò run.
И будет аще забвением забудеши Господа Бога твоего, и пойдеши вслед богов иных, и послужиши им, и поклонишися им, засвидетелствую вам днесь небесем и землею, яко пагубою погибнете:
20 Bí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa parun níwájú u yín, bákan náà ni ẹ ó parun, torí pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín lẹ́nu.
якоже и прочии языцы, яже Господь Бог погубляет от лица вашего, тако погибнете, занеже не послушасте гласа Господа Бога вашего.