< Deuteronomy 8 >
1 Ẹ kíyèsi i láti máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ tí mo fún un yín lónìí, kí ẹ bá à le yè, kí ẹ sì pọ̀ sí i wọ ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le gba ilẹ̀ náà, tí Olúwa fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
Musa melanjutkan nasihatnya kepada umat Israel, “Kalian harus setia mematuhi semua perintah yang saya berikan kepada kalian hari ini. Bila kamu semua melakukannya, kamu boleh tetap hidup, keturunanmu akan bertambah banyak, dan kalian semua akan masuk serta menduduki negeri yang sudah dijanjikan TUHAN kepada nenek moyang kita.
2 Ẹ rántí bí Olúwa Ọlọ́run yín ti tọ́ ọ yín ṣọ́nà ní gbogbo ọ̀nà ní aginjù fún ogójì ọdún wọ̀nyí láti tẹ orí yín ba àti láti dán an yín wò kí ó ba à le mọ bí ọkàn yín ti rí, bóyá ẹ ó pa òfin rẹ̀ mọ́ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Ingatlah bagaimana TUHAN Allahmu memimpin kalian sepanjang perjalanan di padang belantara selama empat puluh tahun. Melalui semua itu, Dia bermaksud merendahkan hatimu dan menguji kamu semua untuk mengetahui isi hatimu. Dia ingin tahu apakah kamu akan tetap taat kepada perintah-perintah-Nya atau tidak.
3 Ó rẹ̀ yín sílẹ̀ nípa fífi ebi pa yín, Ó sì fi manna bọ́ ọ yín, èyí tí ẹ kò mọ̀, tí àwọn baba yín kò mọ̀, kí ó ba à lè kọ́ ọ yín pé, ènìyàn kò ti ipa oúnjẹ nìkan wà láààyè, bí kò ṣe ohun gbogbo tí ó jáde láti ẹnu Olúwa wá.
Maka TUHAN merendahkan hatimu dengan cara membiarkan kalian kelaparan, kemudian memberimu manna, roti yang belum pernah dimakan, baik oleh kita maupun nenek moyang kita. Dia melakukan hal itu untuk mengajarimu bahwa manusia hidup bukan hanya dengan mengandalkan makanan, tetapi juga mengandalkan setiap perkataan TUHAN.
4 Aṣọ yín kò gbó mọ́ ọn yín lọ́rùn bẹ́ẹ̀ ní ẹsẹ̀ yín kò sì wú, ní ogójì ọdún náà.
Biarpun mengembara selama empat puluh tahun di padang belantara, pakaianmu tidak usang dan kakimu tidak bengkak.
5 Ẹ mọ̀ ní ọkàn an yín pé, bí baba ti ń kọ́ ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín ń kọ́ ọ yín.
Jadi, sadarilah betapa TUHAN sudah mendidik kalian, seperti seorang ayah mendidik anaknya.
6 Nítorí èyí, ẹ gbọdọ̀ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́, nípa rínrìn ní ọ̀nà rẹ̀, àti bíbẹ̀rù rẹ̀.
“Oleh karena itu, taatilah perintah-perintah TUHAN! Hiduplah menurut kehendak-Nya. Takut dan hormatlah kepada-Nya.
7 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ń mú un yín bọ̀ wá sí ilẹ̀ rere ilẹ̀ tí ó kún fún odò àti ibú omi, pẹ̀lú àwọn ìsun tí ń sàn jáde láti orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Dia sedang membawa kalian ke suatu negeri yang subur, di mana sungai, kolam, dan mata air berlimpah, dan airnya mengalir dari bukit-bukit sampai ke lembah-lembah.
8 Ilẹ̀ tí ó kún fún jéró àti ọkà barle, tí ó sì kún fún àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́, igi pomegiranate, òróró olifi àti oyin.
Negeri itu berlimpah juga dengan pohon-pohon ara dan delima, serta menghasilkan gandum, jelai, anggur, buah zaitun, dan madu.
9 Ilẹ̀ tí oúnjẹ kò ti wọ́n, kò sí ohun tí ẹ̀yin yóò ṣe aláìní, ilẹ̀ tí irin ti pọ̀ bí òkúta, ẹ̀yin sì lè wa idẹ jáde láti inú òkè rẹ̀ wá.
Negeri itu berlimpah dengan makanan. Semua kebutuhanmu akan terpenuhi. Tanah di sana mengandung bijih besi, dan kalian dapat menambang tembaga dari perbukitannya.
10 Nígbà tí ẹ bá ti jẹ tí ẹ sì yó tán ẹ yin Olúwa Ọlọ́run yín fún pípèsè ilẹ̀ rere fún un yín.
Nanti di sana, saat kalian makan sampai kenyang, hendaklah kalian memuji TUHAN karena segala kemakmuran yang kalian nikmati di negeri subur yang diberikan kepadamu itu!
11 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, nípa kíkùnà láti pa àṣẹ rẹ̀, àwọn òfin rẹ̀, àti àwọn ìlànà rẹ̀ tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
“Berjaga-jagalah supaya kamu semua tidak melupakan TUHAN Allahmu dengan melanggar perintah, peraturan, dan ketetapan-Nya yang saya sampaikan kepadamu hari ini.
12 Kí ó má ba à jẹ́ pé, nígbà tí ẹ bá jẹun yó tán, tí ẹ bá kọ́ ilé tí ó dára tán, tí ẹ sí ń gbé inú rẹ̀,
Di negeri Kanaan kamu akan makan dengan puas dan membangun serta menempati rumah yang bagus.
13 nígbà tí àwọn agbo màlúù yín àti tí ewúrẹ́ ẹ yín bá pọ̀ sí i tán, tí fàdákà àti wúrà yín sì ń peléke sí i, tí ohun gbogbo tí ẹ ní sì ń pọ̀ sí i,
Jumlah ternakmu akan bertambah banyak. Kamu juga akan mengumpulkan banyak emas, perak, dan harta kekayaan lainnya.
14 nígbà náà ni ọkàn yín yóò gbéga, tí ẹ̀yin yóò sì gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá, nínú oko ẹrú.
Saat itu terjadi, berhati-hatilah agar kamu tidak menjadi sombong dan melupakan TUHAN Allah yang sudah membawa kamu keluar dari perbudakan di Mesir!
15 Òun ni ó mú un yín la aginjù ẹlẹ́rù ńlá já, ilẹ̀ tí kò sí omi tí ó sì kún fún òǹgbẹ, pẹ̀lú àwọn ejò olóró ńlá ńlá àti àkéekèe. Ó mú omi jáde fún un yín láti inú àpáta.
Jangan lupa bahwa Dia menuntunmu menempuh perjalanan melalui padang belantara yang sangat luas dan mengerikan. Di sana ada banyak kalajengking dan ular berbisa. Tanahnya sangat kering dan tidak ada air untuk diminum, tetapi Dia membuat air mengalir dari batu yang sangat keras.
16 Ó fún yín ní manna láti jẹ nínú aginjù, ohun tí àwọn baba yín kò mọ̀ rí, kí Òun bá à le tẹ orí yín ba kí ó sì lè dán an yín wò, kí ó bá à lè dára fún un yín.
Jangan lupa bahwa di padang belantara, Dia memberi manna kepada kalian, makanan yang belum pernah dimakan oleh kita maupun nenek moyang kita. Dengan begitu, Dia menguji kalian demi kebaikanmu, karena Dia ingin kamu semua menjadi rendah hati.
17 Ẹ lè rò nínú ara yín pé, “Agbára mi àti iṣẹ́ ọwọ́ mi ni ó mú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá fún mi.”
Oleh sebab itu, berjaga-jagalah supaya kamu tidak pernah berpikir, “Aku memperoleh semua harta ini dengan kekuatan dan kemampuanku sendiri.”
18 Ṣùgbọ́n ẹ rántí Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fún un yín ní agbára àti lè ní àwọn ọrọ̀ wọ̀nyí, tí ó sì fi mú májẹ̀mú rẹ̀ ṣẹ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín bí ó ti rí lónìí.
Ingatlah selalu bahwa kemampuanmu untuk menjadi kaya berasal dari TUHAN saja! Dia memberikan itu untuk memenuhi perjanjian-Nya yang Dia sahkan dengan nenek moyang kita.
19 Bí ẹ bá wá gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn, tí ẹ sì sìn wọ́n, tí ẹ sì foríbalẹ̀ fún wọn, Mo kìlọ̀ fún un yín pé rírun ni ẹ̀yin yóò run.
“Jadi, sekarang saya memberi peringatan keras kepada kamu sekalian: Jika kamu melupakan TUHAN Allahmu dengan berpaling kepada dewa-dewa dan sujud menyembah mereka, kamu pasti binasa!
20 Bí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa parun níwájú u yín, bákan náà ni ẹ ó parun, torí pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín lẹ́nu.
Sama seperti bangsa-bangsa lain yang sudah dimusnahkan TUHAN, begitu jugalah kalian akan dibinasakan bila kalian tidak mau menaati Dia!”