< Deuteronomy 8 >
1 Ẹ kíyèsi i láti máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ tí mo fún un yín lónìí, kí ẹ bá à le yè, kí ẹ sì pọ̀ sí i wọ ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le gba ilẹ̀ náà, tí Olúwa fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
'All the command which I am commanding thee to-day ye observe to do, so that ye live, and have multiplied, and gone in, and possessed the land which Jehovah hath sworn to your fathers;
2 Ẹ rántí bí Olúwa Ọlọ́run yín ti tọ́ ọ yín ṣọ́nà ní gbogbo ọ̀nà ní aginjù fún ogójì ọdún wọ̀nyí láti tẹ orí yín ba àti láti dán an yín wò kí ó ba à le mọ bí ọkàn yín ti rí, bóyá ẹ ó pa òfin rẹ̀ mọ́ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
and thou hast remembered all the way which Jehovah thy God hath caused thee to go these forty years in the wilderness, in order to humble thee to try thee, to know that which [is] in thy heart, whether thou dost keep His commands or not.
3 Ó rẹ̀ yín sílẹ̀ nípa fífi ebi pa yín, Ó sì fi manna bọ́ ọ yín, èyí tí ẹ kò mọ̀, tí àwọn baba yín kò mọ̀, kí ó ba à lè kọ́ ọ yín pé, ènìyàn kò ti ipa oúnjẹ nìkan wà láààyè, bí kò ṣe ohun gbogbo tí ó jáde láti ẹnu Olúwa wá.
'And He doth humble thee, and cause thee to hunger and doth cause thee to eat the manna (which thou hast not known, even thy fathers have not known), in order to cause thee to know that not by bread alone doth man live, but by every produce of the mouth of Jehovah man doth live.
4 Aṣọ yín kò gbó mọ́ ọn yín lọ́rùn bẹ́ẹ̀ ní ẹsẹ̀ yín kò sì wú, ní ogójì ọdún náà.
'Thy raiment hath not worn out from off thee, and thy foot hath not swelled these forty years,
5 Ẹ mọ̀ ní ọkàn an yín pé, bí baba ti ń kọ́ ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín ń kọ́ ọ yín.
and thou hast known, with thy heart, that as a man chastiseth his son Jehovah thy God is chastising thee,
6 Nítorí èyí, ẹ gbọdọ̀ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́, nípa rínrìn ní ọ̀nà rẹ̀, àti bíbẹ̀rù rẹ̀.
and thou hast kept the commands of Jehovah thy God, to walk in His ways, and to fear Him.
7 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ń mú un yín bọ̀ wá sí ilẹ̀ rere ilẹ̀ tí ó kún fún odò àti ibú omi, pẹ̀lú àwọn ìsun tí ń sàn jáde láti orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.
'For Jehovah thy God is bringing thee in unto a good land, a land of brooks of waters, of fountains, and of depths coming out in valley and in mountain:
8 Ilẹ̀ tí ó kún fún jéró àti ọkà barle, tí ó sì kún fún àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́, igi pomegiranate, òróró olifi àti oyin.
a land of wheat, and barley, and vine, and fig, and pomegranate; a land of oil olive and honey;
9 Ilẹ̀ tí oúnjẹ kò ti wọ́n, kò sí ohun tí ẹ̀yin yóò ṣe aláìní, ilẹ̀ tí irin ti pọ̀ bí òkúta, ẹ̀yin sì lè wa idẹ jáde láti inú òkè rẹ̀ wá.
a land in which without scarcity thou dost eat bread, thou dost not lack anything in it; a land whose stones [are] iron, and out of its mountains thou dost dig brass;
10 Nígbà tí ẹ bá ti jẹ tí ẹ sì yó tán ẹ yin Olúwa Ọlọ́run yín fún pípèsè ilẹ̀ rere fún un yín.
and thou hast eaten, and been satisfied, and hast blessed Jehovah thy God, on the good land which he hath given to thee.
11 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, nípa kíkùnà láti pa àṣẹ rẹ̀, àwọn òfin rẹ̀, àti àwọn ìlànà rẹ̀ tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
'Take heed to thyself, lest thou forget Jehovah thy God so as not to keep His commands, and His judgments, and His statutes which I am commanding thee to-day;
12 Kí ó má ba à jẹ́ pé, nígbà tí ẹ bá jẹun yó tán, tí ẹ bá kọ́ ilé tí ó dára tán, tí ẹ sí ń gbé inú rẹ̀,
lest thou eat, and hast been satisfied, and good houses dost build, and hast inhabited;
13 nígbà tí àwọn agbo màlúù yín àti tí ewúrẹ́ ẹ yín bá pọ̀ sí i tán, tí fàdákà àti wúrà yín sì ń peléke sí i, tí ohun gbogbo tí ẹ ní sì ń pọ̀ sí i,
and thy herd and thy flock be multiplied, and silver and gold be multiplied to thee; and all that is thine be multiplied:
14 nígbà náà ni ọkàn yín yóò gbéga, tí ẹ̀yin yóò sì gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá, nínú oko ẹrú.
'And thy heart hath been high, and thou hast forgotten Jehovah thy God (who is bringing thee out of the land of Egypt, out of a house of servants;
15 Òun ni ó mú un yín la aginjù ẹlẹ́rù ńlá já, ilẹ̀ tí kò sí omi tí ó sì kún fún òǹgbẹ, pẹ̀lú àwọn ejò olóró ńlá ńlá àti àkéekèe. Ó mú omi jáde fún un yín láti inú àpáta.
who is causing thee to go in the great and the terrible wilderness — burning serpent, and scorpion, and thirst — where there is no water; who is bringing out to thee waters from the flinty rock;
16 Ó fún yín ní manna láti jẹ nínú aginjù, ohun tí àwọn baba yín kò mọ̀ rí, kí Òun bá à le tẹ orí yín ba kí ó sì lè dán an yín wò, kí ó bá à lè dára fún un yín.
who is causing thee to eat manna in the wilderness, which thy fathers have not known, in order to humble thee, and in order to try thee, to do thee good in thy latter end),
17 Ẹ lè rò nínú ara yín pé, “Agbára mi àti iṣẹ́ ọwọ́ mi ni ó mú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá fún mi.”
and thou hast said in thy heart, My power, and the might of my hand, hath made for me this wealth:
18 Ṣùgbọ́n ẹ rántí Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fún un yín ní agbára àti lè ní àwọn ọrọ̀ wọ̀nyí, tí ó sì fi mú májẹ̀mú rẹ̀ ṣẹ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín bí ó ti rí lónìí.
'And thou hast remembered Jehovah thy God, for He it [is] who is giving to thee power to make wealth, in order to establish His covenant which He hath sworn to thy fathers as [at] this day.
19 Bí ẹ bá wá gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn, tí ẹ sì sìn wọ́n, tí ẹ sì foríbalẹ̀ fún wọn, Mo kìlọ̀ fún un yín pé rírun ni ẹ̀yin yóò run.
'And it hath been — if thou really forget Jehovah thy God, and hast gone after other gods, and served them, and bowed thyself to them, I have testified against you to-day that ye do utterly perish;
20 Bí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa parun níwájú u yín, bákan náà ni ẹ ó parun, torí pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín lẹ́nu.
as the nations whom Jehovah is destroying from your presence, so ye perish; because ye hearken not to the voice of Jehovah your God.