< Deuteronomy 8 >

1 Ẹ kíyèsi i láti máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ tí mo fún un yín lónìí, kí ẹ bá à le yè, kí ẹ sì pọ̀ sí i wọ ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le gba ilẹ̀ náà, tí Olúwa fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
Внимавайте да вършите всичките заповеди, които днес ви заповядвам, за да живеете, да се умножите и да влезете да завладеете земята, за която се е клел Господ на бащите ви.
2 Ẹ rántí bí Olúwa Ọlọ́run yín ti tọ́ ọ yín ṣọ́nà ní gbogbo ọ̀nà ní aginjù fún ogójì ọdún wọ̀nyí láti tẹ orí yín ba àti láti dán an yín wò kí ó ba à le mọ bí ọkàn yín ti rí, bóyá ẹ ó pa òfin rẹ̀ mọ́ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
И да помниш целия път, по който Господ твоят Бог те е водил през тия четиридесет години из пустинята, за да те смири и да те изпита, за да узнае що има в сърцето ти, дали ще пазиш заповедите Му, или не.
3 Ó rẹ̀ yín sílẹ̀ nípa fífi ebi pa yín, Ó sì fi manna bọ́ ọ yín, èyí tí ẹ kò mọ̀, tí àwọn baba yín kò mọ̀, kí ó ba à lè kọ́ ọ yín pé, ènìyàn kò ti ipa oúnjẹ nìkan wà láààyè, bí kò ṣe ohun gbogbo tí ó jáde láti ẹnu Olúwa wá.
И те смири, и като те остави да огладнееш, храни те с манна, (която беше храна непозната на тебе и непозната на бащите ти), за да те научи, че човек не живее само с хляб, но че човек живее с всяко слово, което излиза из Господната уста.
4 Aṣọ yín kò gbó mọ́ ọn yín lọ́rùn bẹ́ẹ̀ ní ẹsẹ̀ yín kò sì wú, ní ogójì ọdún náà.
Облеклото ти не овехтя на тебе нито ногата ти отече през тия четиридесет години.
5 Ẹ mọ̀ ní ọkàn an yín pé, bí baba ti ń kọ́ ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín ń kọ́ ọ yín.
Да вземеш, прочее, в съображение в сърцето си, че както човек наказва сина си, така и Господ твоят Бог наказва тебе.
6 Nítorí èyí, ẹ gbọdọ̀ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́, nípa rínrìn ní ọ̀nà rẹ̀, àti bíbẹ̀rù rẹ̀.
За това, да пазиш заповедите на Господа твоя Бог, да ходиш в пътищата Му и да се боиш от Него.
7 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ń mú un yín bọ̀ wá sí ilẹ̀ rere ilẹ̀ tí ó kún fún odò àti ibú omi, pẹ̀lú àwọn ìsun tí ń sàn jáde láti orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Защото Господ твоят Бог те завежда в добра земя, в земя богата с водни потоци, които извират в долини и планини;
8 Ilẹ̀ tí ó kún fún jéró àti ọkà barle, tí ó sì kún fún àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́, igi pomegiranate, òróró olifi àti oyin.
в земя богата с жито, ечемик, лозя, смокини и нарове; в земя богата с маслини и мед;
9 Ilẹ̀ tí oúnjẹ kò ti wọ́n, kò sí ohun tí ẹ̀yin yóò ṣe aláìní, ilẹ̀ tí irin ti pọ̀ bí òkúta, ẹ̀yin sì lè wa idẹ jáde láti inú òkè rẹ̀ wá.
в земя гдето не ще ядеш хляб оскъдно и в който не ще си в нужда от нищо; в земя чиито камъни са желязо, и от чиито планини ще копаеш мед.
10 Nígbà tí ẹ bá ti jẹ tí ẹ sì yó tán ẹ yin Olúwa Ọlọ́run yín fún pípèsè ilẹ̀ rere fún un yín.
Ще ядеш и ще се наситиш, и ще благословиш Господа твоя Бог за добрата земя, която ти е дал.
11 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, nípa kíkùnà láti pa àṣẹ rẹ̀, àwọn òfin rẹ̀, àti àwọn ìlànà rẹ̀ tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
Внимавай да не забравиш Господа твоя Бог и да не престъпваш заповедите Му, съдбите Му и повеленията Му, които днес ти заповядвам,
12 Kí ó má ba à jẹ́ pé, nígbà tí ẹ bá jẹun yó tán, tí ẹ bá kọ́ ilé tí ó dára tán, tí ẹ sí ń gbé inú rẹ̀,
да не би, като ядеш и се наситиш и построиш добри къщи и живееш в тях,
13 nígbà tí àwọn agbo màlúù yín àti tí ewúrẹ́ ẹ yín bá pọ̀ sí i tán, tí fàdákà àti wúrà yín sì ń peléke sí i, tí ohun gbogbo tí ẹ ní sì ń pọ̀ sí i,
и като се умножат говедата и овците ти и се умножат среброто ти и златото ти, и се умножи всичко що имаш,
14 nígbà náà ni ọkàn yín yóò gbéga, tí ẹ̀yin yóò sì gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá, nínú oko ẹrú.
тогава да се надигне сърцето ти и да забравиш Господа твоя Бог, Който те е извел из Египетската земя, из дома на робството;
15 Òun ni ó mú un yín la aginjù ẹlẹ́rù ńlá já, ilẹ̀ tí kò sí omi tí ó sì kún fún òǹgbẹ, pẹ̀lú àwọn ejò olóró ńlá ńlá àti àkéekèe. Ó mú omi jáde fún un yín láti inú àpáta.
Който те преведе през голямата и страшна пустиня, гдето имаше горителни змии, скорпии и сухи безводни змии; Който ти извади вода из кременливия камък;
16 Ó fún yín ní manna láti jẹ nínú aginjù, ohun tí àwọn baba yín kò mọ̀ rí, kí Òun bá à le tẹ orí yín ba kí ó sì lè dán an yín wò, kí ó bá à lè dára fún un yín.
Който те храни в пустинята с манна, храна която не знаеха бащите ти, за да те смири и да те изпита, да ти направи добро в сетнините ти;
17 Ẹ lè rò nínú ara yín pé, “Agbára mi àti iṣẹ́ ọwọ́ mi ni ó mú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá fún mi.”
и да не би да речеш в сърцето си: Моята мощ и силата на моята ръка ми спечелиха това богатство.
18 Ṣùgbọ́n ẹ rántí Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fún un yín ní agbára àti lè ní àwọn ọrọ̀ wọ̀nyí, tí ó sì fi mú májẹ̀mú rẹ̀ ṣẹ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín bí ó ti rí lónìí.
Но да помниш Господа твоя Бог, защото Той е, Който ти дава сила да придобиваш богатство; за да утвърди завета, за който се е клел на бащите ти, както прави днес.
19 Bí ẹ bá wá gbàgbé Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn, tí ẹ sì sìn wọ́n, tí ẹ sì foríbalẹ̀ fún wọn, Mo kìlọ̀ fún un yín pé rírun ni ẹ̀yin yóò run.
Но ако забравиш Господа твоя Бог и отидеш след други богове, служиш им и им се поклониш, заявявам ви днес, че съвсем ще бъдете изтребени.
20 Bí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa parun níwájú u yín, bákan náà ni ẹ ó parun, torí pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín lẹ́nu.
Ще бъдете изтребени както народите, които Господ изтребва от пред вас, защото не послушахте гласа на Господа вашия Бог.

< Deuteronomy 8 >