< Deuteronomy 7 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
Pǝrwǝrdigar Hudaying seni ⱨazir igilǝxkǝ ketiwatⱪan zeminƣa baxlap kirgüzgǝndin keyin, aldingdin kɵp yat ǝl-millǝtlǝrni, yǝni Ⱨittiylar, Girgaxiylar, Amoriylar, Ⱪanaaniylar, Pǝrizziylar, Ⱨiwiylar, Yǝbusiylarni — sǝndin küqlük ǝl-millǝtlǝrni ⱨǝydiwetidu.
2 nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
Əmdi Pǝrwǝrdigar Hudaying aldingda ularni ⱪolungƣa tapxuruxi bilǝn sǝn ularƣa ⱨujum ⱪilƣiningda, sǝn ularni tǝltɵküs yoⱪitixing kerǝk; ular bilǝn ⱨeq ǝⱨdǝ tüzixinggǝ wǝ ularƣa ⱨeq rǝⱨim ⱪilixingƣa bolmaydu.
3 Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
Sening ular bilǝn nikaⱨlixixingƣa bolmaydu; sǝn ⱪizingni ularning oƣulliriƣa berixinggimu wǝ ularning ⱪizini oƣlungƣa elip berixinggimu bolmaydu;
4 torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
qünki ular oƣlungni Manga ǝgixixtin eziⱪturidu wǝ xuning bilǝn oƣulliring baxⱪa ilaⱨlarƣa qoⱪunidu; u qaƣda Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi silǝrgǝ ⱪozƣilip, silǝrni tezla yoⱪitidu.
5 Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
Sǝn ularƣa xundaⱪ muamilǝ ⱪilƣinki, ularning ⱪurbangaⱨlirini buzuwetinglar, but tüwrüklirini qeⱪiwetinglar, axǝraⱨ butlirini kesiwetinglar wǝ oyma butlirini ot bilǝn kɵydürüwetinglar;
6 Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
qünki silǝr Pǝrwǝrdigar Hudayinglarƣa pak-muⱪǝddǝs bir hǝlⱪtursilǝr; Pǝrwǝrdigar Hudayinglar silǝrni yǝr yüzidiki barliⱪ baxⱪa hǝlⱪlǝrdin üstün ⱪilip, Ɵzigǝ has bir hǝlⱪ boluxⱪa talliwalƣan.
7 Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
Pǝrwǝrdigarning silǝrgǝ meⱨir qüxüp silǝrni talliwalƣini silǝrning baxⱪa hǝlⱪlǝrdin kɵp bolƣanliⱪinglar üqün ǝmǝs, ǝmǝliyǝttǝ silǝr barliⱪ hǝlⱪlǝr arisida ǝng az idinglar,
8 Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
Pǝrwǝrdigarning silǝrni sɵygini sǝwǝbidin wǝ ata-bowiliringlar aldida bǝrgǝn ⱪǝsimigǝ sadiⱪ bolƣanliⱪi üqün Pǝrwǝrdigar silǝrni küqlük ⱪol bilǝn ⱪutⱪuzup, ⱨɵrlük bǝdili tɵlǝp «ⱪulluⱪ makani»din, yǝni Misir padixaⱨi Pirǝwnning ⱪolidin qiⱪarƣan.
9 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Xunga silǝr Pǝrwǝrdigar Hudayinglarning bǝrⱨǝⱪ Huda, wǝdisidǝ turƣuqi Tǝngri ikǝnlikini bilixinglar kerǝk; U Ɵzini sɵyüp, ǝmrlirini tutⱪanlarƣa ming dǝwrgiqǝ ɵzgǝrmǝs meⱨir kɵrsitip ǝⱨdisidǝ turƣuqidur;
10 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
lekin Ɵzigǝ ɵqmǝnlǝrning ixlirini ɵz bexiƣa oquⱪ-axkarǝ qüxürüp, ularni yoⱪitidu; Ɵzigǝ ɵqmǝnlǝrning ⱨǝrbirigǝ ɵzi ⱪilƣan ixlirini ularning bexiƣa oquⱪ-axkarǝ ⱪayturuxⱪa ⱨayal ⱪilmaydu.
11 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
Silǝr Mǝn bügün silǝrgǝ tapiliƣan ǝmr, bǝlgilimilǝr ⱨǝm ⱨɵkümlǝrgǝ ǝmǝl ⱪilix üqün ularni qing tutunglar.
12 Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
Qoⱪum xundaⱪ boliduki, bu bǝlgilimilǝrgǝ ⱪulaⱪ selip, kɵngül ⱪoyup ǝmǝl ⱪilisanglar, Pǝrwǝrdigar Hudayinglar ata-bowiliringlarƣa ⱪǝsǝm bilǝn wǝdǝ ⱪilƣan ǝⱨdǝ wǝ meⱨirni silǝrgǝ kɵrsitip turidu;
13 Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
Seni sɵyüp bǝrikǝtlǝp, ata-bowiliringƣa ⱪǝsǝm bilǝn sanga berixkǝ wǝdǝ ⱪilƣan zeminda turƣuzup kɵpǝytidu; xu yǝrdǝ pǝrzǝntliringni, yǝr-tupriⱪingdiki mǝⱨsulatlarni, buƣdiyingni, yengi xarabingni, zǝytun meyingni, kaliliringning nǝslini wǝ ⱪoyliringning ⱪozilirini bǝrikǝtlǝp kɵpǝytidu.
14 A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
Sǝn barliⱪ ǝllǝrdin ziyadǝ bǝht-bǝrikǝt kɵrisǝn; arangda, ǝr-ayal yaki mal-qarwang arisida ⱨeq tuƣmasliⱪ bolmaydu;
15 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
Pǝrwǝrdigar sǝndin barliⱪ kesǝllǝrni neri ⱪilidu wǝ sǝn ɵzüng kɵrgǝn Misirdiki dǝⱨxǝtlik wabalardin ⱨeqⱪaysisini üstünggǝ salmaydu, bǝlki sanga ɵq bolƣanlarƣa salidu.
16 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
Sǝn Pǝrwǝrdigar sanga tapxurƣan barliⱪ hǝlⱪlǝrni yoⱪitixing kerǝk; sǝn ularni kɵrgǝndǝ, ularƣa ⱨeq rǝⱨim ⱪilmasliⱪing kerǝk, sǝn ularning ilaⱨlirining ⱪulluⱪiƣa kirmǝsliking kerǝk; ǝgǝr xundaⱪ ⱪilsang, bu ix sanga ⱪiltaⱪ bolidu.
17 Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
Əgǝr sǝn kɵnglüngdǝ: «Bu ǝllǝr mǝndin küqlük; mǝn ⱪandaⱪ ⱪilip ularni zeminidin ⱪoƣliwetǝlǝymǝn?» — desǝng,
18 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
ulardin ⱪorⱪma; Pǝrwǝrdigar Hudayingning Pirǝwn ⱨǝm barliⱪ Misirliⱪlarni ⱪandaⱪ ⱪilƣanliⱪini ǝsligin,
19 Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
— yǝni Pǝrwǝrdigar Hudaying seni xu yǝrdin qiⱪirix üqün wasitǝ ⱪilƣan, ɵz kɵzüng bilǝn kɵrgǝn dǝⱨxǝtlik ⱨɵküm-sinaⱪlar, mɵjizilik alamǝtlǝr wǝ karamǝtlǝr, küqlük ⱪol wǝ sozulƣan bilǝkni mǝⱨkǝm esingdǝ tut; Pǝrwǝrdigar sǝn ⱪorⱪuwatⱪan barliⱪ hǝlⱪnimu xundaⱪ ⱪilidu.
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
Uning üstigǝ Pǝrwǝrdigar Hudaying taki ularning sǝndin yoxurunƣan ⱪalduⱪliri yoⱪitilƣuqǝ ularning arisiƣa seriⱪ ⱨǝrilǝrni ǝwǝtidu;
21 Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Sǝn ulardin ⱪorⱪmasliⱪing kerǝk; qünki Pǝrwǝrdigar Hudaying arangdidur; U uluƣ wǝ dǝⱨxǝtlik bir Ilaⱨdur.
22 Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
Pǝrwǝrdigar Hudaying xu ǝllǝrni aldingdin pǝydinpǝy ⱨǝydǝydu; sǝn ularni biraⱪla yoⱪitiwetǝlmǝysǝn; biraⱪla yoⱪitiwǝtkǝn tǝⱪdirdimu, daladiki ⱨaywanlar kɵpiyip, üstünggǝ basturup kelixi mumkin.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
Lekin aldingƣa ilgirilǝp mangƣiningda Pǝrwǝrdigar Hudaying ularni ⱪolungƣa tapxuridu wǝ ularni parakǝndǝ ⱪilip, yoⱪitilƣuqǝ dǝkkǝ-dükkigǝ salidu.
24 Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
U ularning padixaⱨlirini ⱪolungƣa tapxuridu, sǝn ularning namlirinimu asman astidin yoⱪ ⱪilisǝn; ularni yoⱪatⱪuqǝ ⱨeqbir adǝm aldingda turalmaydu.
25 Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Silǝr ularning oyma butini ot bilǝn kɵydürüwetinglar; kɵz ⱪiringlarni xularning üstidiki altun-kümüxkǝ salmanglar, ularni almanglar; bolmisa u silǝrgǝ ⱪiltaⱪ bolidu; qünki u Pǝrwǝrdigar Hudaying aldida yirginqlik bir nǝrsidur.
26 Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.
Sǝn ⱨeqⱪandaⱪ yirginqlik nǝrsini ɵyünggǝ elip kǝlmǝ; bolmisa sǝn uningƣa ohxax lǝnǝtlik nǝrsǝ bolup ⱪalisǝn; sǝn uningdin ⱪattiⱪ yirgǝn, uningƣa mutlǝⱪ nǝprǝtlǝn; qünki u lǝnǝtlik bir nǝrsidur.

< Deuteronomy 7 >