< Deuteronomy 7 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
Quando Yahweh seu Deus o traz à terra onde você vai para possuí-la, e expulsa muitas nações diante de você - o hitita, o girgasita, o amorreu, o cananeu, o perizeu, o hivita e o jebusita - sete nações maiores e mais poderosas do que você;
2 nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
e quando Yahweh seu Deus as entregar diante de você, e você as atingir, então você as destruirá totalmente. Não fareis nenhum pacto com eles, nem tereis misericórdia deles.
3 Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
Não fareis matrimônios com eles. Não darás tua filha a seu filho, nem tomarás sua filha por teu filho.
4 torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
Pois isso afastará seus filhos de me seguirem, para que possam servir a outros deuses. Assim, a ira de Javé seria acesa contra você, e ele o destruiria rapidamente.
5 Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
Mas você lidará com eles assim: derrubará seus altares, quebrará seus pilares em pedaços, cortará seus bastões de Asherah e queimará suas imagens gravadas com fogo.
6 Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
Pois vós sois um povo santo para Yahweh vosso Deus. Javé, vosso Deus, vos escolheu para serdes um povo para sua própria posse, sobretudo povos que estão sobre a face da terra.
7 Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
Yahweh não colocou seu amor em vocês nem os escolheu, porque vocês eram em maior número que qualquer povo; pois vocês eram o menor de todos os povos;
8 Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
mas porque Yahweh os ama, e porque deseja cumprir o juramento que fez a seus pais, Yahweh vos tirou com uma mão poderosa e vos redimiu da casa da servidão, da mão do faraó rei do Egito.
9 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Saiba portanto que o próprio Javé, vosso Deus, é Deus, o Deus fiel, que mantém aliança e bondade amorosa com mil gerações com aqueles que o amam e guardam seus mandamentos,
10 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
e que repaga aqueles que o odeiam diante deles, para destruí-los. Ele não será frouxo para com aquele que o odeia. Ele o retribuirá na cara dele.
11 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
Guardareis, portanto, os mandamentos, os estatutos e as ordenanças que eu vos ordeno hoje, para cumpri-los.
12 Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
Acontecerá, porque ouvis estas ordenanças e as cumprireis e cumprireis, que Javé, vosso Deus, guardará convosco o pacto e a bondade amorosa que ele jurou a vossos pais.
13 Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
Ele vos amará, vos abençoará e vos multiplicará. Ele também abençoará o fruto de vosso corpo e o fruto de vossa terra, vosso grão e vosso novo vinho e vosso azeite, o aumento de vosso gado e das crias de vosso rebanho, na terra que Ele jurou a vossos pais que vos daria.
14 A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
Você será abençoado acima de todos os povos. Não haverá entre vós machos ou fêmeas estéreis, nem entre vosso gado.
15 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
Javé vos tirará todas as enfermidades; e não porá sobre vós nenhuma das doenças malignas do Egito, que vós conheceis, mas as colocará sobre todos aqueles que vos odeiam.
16 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
Consumireis todos os povos que Yavé vosso Deus vos entregará. Vosso olho não terá piedade deles. Não servireis aos seus deuses, pois isso seria uma armadilha para vós.
17 Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
Se você disser em seu coração: “Estas nações são mais do que eu; como posso despojá-las”?
18 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
não tereis medo deles. Recordareis bem o que Javé vosso Deus fez ao Faraó e a todo o Egito:
19 Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
as grandes provações que vossos olhos viram, os sinais, as maravilhas, a mão poderosa e o braço estendido, pelo qual Javé vosso Deus vos fez sair. Assim fará Javé, vosso Deus, a todos os povos dos quais temeis.
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
Além disso, Javé, seu Deus, enviará o vespeiro entre eles, até que aqueles que restam, e se escondem, pereçam diante de você.
21 Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Não tereis medo deles, pois Yavé vosso Deus está entre vós, um grande e impressionante Deus.
22 Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
Javé, vosso Deus, expulsará pouco a pouco essas nações diante de vós. Você não poderá consumi-las imediatamente, para que os animais do campo não aumentem sobre você.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
Mas Javé, vosso Deus, os entregará diante de vós, e os confundirá com uma grande confusão, até que sejam destruídos.
24 Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
Ele entregará seus reis em suas mãos, e você fará perecer seu nome de debaixo do céu. Ninguém poderá estar diante de você até que você os tenha destruído.
25 Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Você queimará com fogo as imagens gravadas de seus deuses. Não cobiçarás a prata ou o ouro que está sobre eles, nem a tomarás para ti, para que não sejas enganado nela; pois é uma abominação para Javé teu Deus.
26 Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.
Você não trará uma abominação para sua casa e não se tornará uma coisa dedicada como ela. Você a detestará totalmente. Abominá-la-eis totalmente, pois é uma coisa devota.

< Deuteronomy 7 >