< Deuteronomy 7 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
Ie asese’ Iehovà Andrianañahare’o mb’amy tane himoaha’o naho ho ta­vane’oy, naho asiotsio’e mb’ aolo’o mb’eo ty fifeheañe maro: o nte-Kiteo, o nte-Girgaseo, o nte-Amoreo, o nte-Kanàneo, o nte-Perizeo, o nte-Kiveo, vaho o nte-Iebosèo, fifeheañe fito maozatse naho maro te ama’o,
2 nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
naho atolo’ Iehovà Andrianañahare’o ama’o vaho giohe’o, le tsy mete tsy mongore’o. Ko ifañina’o naho ko itretreza’o.
3 Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
Ko ifangalam-baly, ko anolora’o anak’ ampela o ana-dahi’eo ndra andrambesan’ anak’ ampela i ana-dahi’oy,
4 torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
amy te hampiambohoe’e ty ana’o tsy haño­rik’ ahy hitoroñe ndrahare ila’e. Le hisolebotse ama’o ty haviñera’ Iehovà vaho harotsa’e aniany.
5 Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
Fe inao ty hanoa’o iareo; demoho o kitreli’ iareoo, kimokimoho o hazomanga’ iareoo, naho firao o Asere’ iareoo vaho ampiforototò an’ afo o vongan-draha sinokitseo.
6 Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
Ondaty miavake am’ Iehovà Andrianañahare’o irehe, ie jinobo’ Iehovà Andria­nañahare’o amy ze kila ondaty ambone’ ty tane toy ho vara’e.
7 Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
Tsy t’ie nimaro ta ondaty ila’eo te napite’ Iehovà ama’ areo ty fikokoañe ndra ty fijoboña’e, toe nitsiampe te amy ze hene ondaty;
8 Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
fa ty fikokoa’ Iehovà anahareo naho ty nañambena’e i fañina nifantà’e aman-droae’ areoiy, ty nampiengà’ Iehovà anahareo an-dela-pità’e maozatse vaho nijebaña’e boak’amy trañom-pañondevozañey, hirik’ am-pità’ i Parò mpanjaka’ i Mitsraimey.
9 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Mahafohina arè te toe Andrianañahare t’Iehovà Andrianañahare’o naho Andrianañahare migahiñe mpitam-pañina naho fiferenaiñañe amo mpikoko azeo vaho mañorike o lili’eo pak’an-tarira’e fah’arivo’,
10 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
fe avaha’e an-dahara’ o manjehatse azeo. Tsy malaon-dre fa valea’e an-tarehe’e eo ze malaiñe aze.
11 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
Aa le ambeno ty lily naho o fañè naho fepetse andiliako azo androanio, vaho oriho.
12 Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
Ie amy zao, naho haoñe’o o fañè rezao naho ambena’o naho orihe’o, le havotinti’ Iehovà Andria­nañahare’o ama’o i fañina naho fikokoa-migahiñe nifantà’e aman-droae’oy;
13 Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
ho kokoa’e irehe, ho tahie’e vaho hampi­bodo­bodoe’e; ho tahie’e ty vokan-kovi’o naho ty vokan-tane’o, ty ampemba’o, ty divai’o naho ty mena’o naho ty fitom­boa’ o añombe’oo naho ty famorohotan-dia-rai’o amy tane nifañinà’e aman-droae’o hatolo’e azoy.
14 A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
Ho soa-tahy amy ze kila ondaty irehe, tsy eo ty ho betsi­terak’ aman-dahilahy ndra ampela, vaho tsy ho pok’anake o añombe’oo.
15 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
Hafaha’ Iehovà ama’o ze hene hasilofañe naho tsy hafetsa’e ama’o o angorosy nifohi’o e Mitsraime añeo, fe hapo’e amo malaiñ’ azoo.
16 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
Fonga habotse’o ze ondaty atolo’ Iehovà Andrianañahare’o azo, ko iferenaiñam-pihaino’o vaho ko toroñe’o o ndrahare’ iareoo fa ho fandrik’ ama’o.
17 Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
Ie manao ty hoe an-troke ao: Maro te amako o rofoko zao, aia ty hanoako soike iareo.
18 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
Ko ihem­baña’o, tiahio avao ty nanoe’ Iehovà Andria­nañahare’o amy Parò naho amy Mitsraime iaby,
19 Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
o fitsohañe ra’elahy niisam-pihaino’oo, o viloñeo naho o raha tsitantaneo, i lela-pitàñe maoza­tsey naho i fitàñe natora-kitsi’e nañavota’ Iehovà Andria­nañahare’o boak’añey, ro mbe hanoe’ Iehovà Andrianañahare’o amy ze hene ondaty irevendreveña’o,
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
vaho hampisangitrife’ Iehovà Andria­nañahare’o am’ iareo ty fanenetse, ampara’ te fonga miantantiry ze sehanga’e mietake.
21 Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Ko miriatsandry am’ iareo, amy te añivo’o ao t’Iehovà An­drianañahare’o; Andrianañahare jabahinake naho mam­pa­ñeveñe.
22 Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
Hasiotsio’ Iehovà Andria­naña­hare’o aolo’o mb’eo erike o rofoko rezay; f’ie tsy ho fonga mongore’o aniany tsy mone ho losotse ama’o o bibin-kivokeo.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
Toe hatolo’ Iehovà Andria­na­ñahare’o ama’o iereo, vaho ho rotsahe’e am-pandrebahañe ra’elahy am-para’ te zama­ne’e iaby.
24 Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
Hatolo’e am-pità’o o mpanjaka’eo vaho ho fao­paohe’o ambanen-dikerañe atoy ty tahina’ iareo, tsy eo t’indaty hahafiatreatre azo, am-para’ te narotsa’o.
25 Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Ho forototoe’ areo ze saren-drahare’ iareo. Ko tsikirihe’o ty volafoty ndra volamena ama’e ndra mandrambe aze ho azo, fa ho fandrik’ ama’o, toe tiva amy Iehovà Andria­nañahare’o.
26 Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.
Ko minday raha tiva añ’an­jomba’o ao ke hindre hafàtse ama’e irehe. Vata’e hejeo naho apoho hoe mampangory, ie fa navike harotsake.

< Deuteronomy 7 >