< Deuteronomy 7 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
Selanjutnya, Musa mengajarkan kepada umat Israel, “Ketika TUHAN Allah membawa kalian ke negeri yang akan segera kalian masuki dan duduki, Dia akan mengusir tujuh bangsa yang lebih kuat dan yang lebih banyak jumlahnya daripada kalian, yaitu bangsa Het, Girgasi, Amori, Kanaan, Feris, Hewi, dan Yebus.
2 nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
Sewaktu TUHAN menyerahkan bangsa-bangsa itu kepada kalian, musnahkanlah mereka semua! Jangan membuat perjanjian damai dengan satu kelompok pun dari mereka, dan jangan mengasihani mereka.
3 Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
Jangan melakukan pernikahan campur dengan mereka. Jangan menyerahkan anak-anak perempuanmu untuk menikah dengan anak-anak laki-laki mereka. Dan jangan membiarkan anak-anak laki-lakimu menikahi anak-anak perempuan mereka,
4 torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
karena para perempuan itu akan mempengaruhi anak-anak laki-lakimu untuk menyembah dewa-dewa mereka sehingga TUHAN akan sangat marah kepada kalian dan segera membinasakan kalian.
5 Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
Inilah yang harus kalian lakukan terhadap bangsa-bangsa itu: Hancurkanlah mezbah-mezbah tempat mereka mengurbankan hewan. Hancurkan juga tugu-tugu berhala dari batu, tebanglah tiang-tiang kayu lambang dewi Asyera, dan bakarlah semua patung dewa mereka.
6 Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
Kalian harus melakukan itu karena kalian adalah umat yang dikhususkan oleh TUHAN bagi-Nya. Dari antara segala bangsa lain di muka bumi, kalian sudah dipilih oleh TUHAN Allah kita untuk menjadi milik-Nya sendiri yang khusus.
7 Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
“TUHAN mengasihi dan memilih kalian bukan karena jumlah kalian lebih banyak daripada bangsa-bangsa yang lain. Nyatanya, jumlah kalian paling sedikit dibandingkan semua bangsa lain.
8 Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
Tetapi TUHAN memilih kalian karena Dia mengasihi kalian, dan karena Dia menepati janji-Nya kepada nenek moyang kita. Itulah sebabnya Dia menggunakan kuasa-Nya yang hebat untuk membawa keluar dan membebaskan kalian dari perbudakan di bawah kuasa raja Mesir.
9 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Jadi, jangan lupa bahwa TUHAN Allahmu adalah satu-satunya Allah. Dia adalah Allah yang layak dipercaya, dan Dia akan setia menepati perjanjian yang Dia buat dengan kalian, bahkan sampai ribuan generasi, asalkan kalian tetap mengasihi Dia dan mematuhi perintah-perintah-Nya.
10 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
Sebaliknya, Dia akan menghukum orang-orang yang membenci Dia dengan cara membinasakan mereka. Dia tidak menunda-nunda untuk membalas mereka.
11 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
Karena itu, kamu sekalian harus menjaga diri untuk tetap mematuhi semua perintah, peraturan, dan ketetapan yang saya berikan kepada kalian hari ini.
12 Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
“Kalau kalian selalu setia menaati peraturan-peraturan ini, maka TUHAN Allahmu akan menepati perjanjian-Nya denganmu sesuai janji-Nya kepada nenek moyangmu.
13 Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
Dia akan mengasihi dan memberkati kalian serta membuat jumlahmu berlipat ganda. Dia akan memberkatimu dengan banyak anak, juga memberkati kebun dan ladangmu sehingga menghasilkan gandum-ganduman, anggur, dan minyak zaitun yang berlimpah. Dia juga akan memperbanyak sapi dan kambing dombamu. TUHAN akan memberikan semua itu kepada kalian di negeri yang Dia janjikan dengan bersumpah kepada nenek moyangmu.
14 A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
Dia akan memberkati kamu semua lebih daripada bangsa-bangsa lain. Kamu dan keturunanmu tidak akan ada yang mandul. Demikian juga ternak-ternakmu.
15 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
TUHAN juga akan melindungi kalian dari segala penyakit, supaya kalian tidak menderita penyakit mengerikan seperti yang pernah ditimpakan kepada orang-orang Mesir. Namun, Dia akan menghukum musuh-musuhmu dengan penyakit-penyakit itu!
16 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
“Sewaktu merebut negeri Kanaan, kalian harus membinasakan semua penduduk yang TUHAN serahkan kepada kalian. Jangan mengasihani mereka, dan jangan menyembah dewa-dewa mereka. Kalau berbuat demikian, kalian sudah masuk perangkap yang akan membinasakanmu.
17 Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
Jangan pernah berpikir, “Bangsa-bangsa di negeri ini lebih kuat daripada kita, bagaimana mungkin kita bisa mengusir mereka?”
18 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
Jangan takut kepada mereka! Ingatlah yang pernah TUHAN lakukan kepada raja Mesir dan semua rakyatnya.
19 Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
Kalian sudah melihat sendiri bagaimana TUHAN menggunakan kuasa-Nya yang hebat untuk mendatangkan bencana-bencana dan berbagai macam keajaiban ke atas mereka untuk membawa kalian keluar dari negeri itu. Dia akan melakukan hal yang sama kepada bangsa yang sekarang kalian takuti.
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
Bahkan TUHAN akan membuat mereka begitu ketakutan sehingga banyak yang melarikan diri dari hadapan kalian. Ada yang akan bersembunyi, tetapi pada akhirnya kalian akan membinasakan mereka.
21 Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
“Janganlah takut kepada bangsa-bangsa di negeri Kanaan, karena TUHAN Allahmu akan menyertai kalian. Dia adalah Allah yang hebat dan dahsyat!
22 Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
TUHAN akan mengusir bangsa-bangsa itu sedikit demi sedikit. Kalian tidak akan diizinkan menghabisi mereka sekaligus, karena kalau hal itu terjadi, maka binatang-binatang buas di sana akan berkembang terlalu banyak sehingga membahayakan kalian.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
Begitulah caranya TUHAN Allah akan menolong kalian mengalahkan musuh-musuh dengan membuat mereka panik sampai mereka binasa.
24 Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
Dia akan menyerahkan raja-raja mereka ke dalam kuasa kalian. Kalian akan memusnahkan mereka, bahkan nama-nama mereka tidak akan diingat lagi di dunia. Tidak akan ada bangsa yang sanggup melawan kalian, dan kalian akan membinasakan mereka semua.
25 Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
“Kalian harus membakar ukiran-ukiran berhala mereka yang terbuat dari kayu. Jangan mengingini hiasan perak atau emas dari patung-patung itu. Jangan mengambil apa pun! Benda-benda itu merupakan perangkap yang dapat membinasakanmu. Kalau mengambil barang-barang itu, berarti kalian mengambil barang yang dibenci oleh TUHAN Allahmu.
26 Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.
Barang seperti itu sudah ditetapkan oleh TUHAN untuk dimusnahkan. Jadi, kalau kalian membawa barang yang dibenci TUHAN ke dalam rumahmu, nanti kalian juga akan dimusnahkan! Kalian harus membenci barang seperti itu.”

< Deuteronomy 7 >