< Deuteronomy 7 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
Mikor bevisz téged az Úr, a te Istened a földre, a melyre te bemenendő vagy, hogy bírjad azt; és sok népet kiűz te előled a Khitteust, a Girgazeust, az Emoreust, a Kananeust, a Perizeust, a Khivveust, és a Jebuzeust: hétféle népet, náladnál nagyobbakat és erősebbeket;
2 nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
És adja őket az Úr, a te Istened a te hatalmadba, és megvered őket: mindenestől veszítsd ki őket; ne köss velök szövetséget, és ne könyörülj rajtok.
3 Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
Sógorságot se szerezz ő velök, a leányodat se adjad az ő fioknak, és az ő leányukat se vegyed a te fiadnak;
4 torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
Mert elpártoltatja a te fiadat én tőlem, és idegen isteneknek szolgálnak; és felgerjed az Úrnak haragja reátok, és hamar kipusztít titeket.
5 Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
Hanem így cselekedjetek velök: Oltáraikat rontsátok le, oszlopaikat törjétek össze, berkeiket vágjátok ki, faragott képeiket pedig tűzzel égessétek meg.
6 Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
Mert az Úrnak, a te Istenednek szent népe vagy te; téged választott az Úr, a te Istened, hogy saját népe légy néki, minden nép közül e föld színén.
7 Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
Nem azért szeretett titeket az Úr, sem nem azért választott titeket, hogy minden népnél többen volnátok; mert ti minden népnél kevesebben vagytok;
8 Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
Hanem mivel szeretett titeket az Úr, és hogy megtartsa az esküt, a melylyel megesküdt volt a ti atyáitoknak; azért hozott ki titeket az Úr hatalmas kézzel, és szabadított meg téged a szolgaságnak házából, az égyiptombeli Faraó királynak kezéből.
9 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
És hogy megtudjad, hogy az Úr, a te Istened, ő az Isten, a hívséges Isten, a ki megtartja a szövetséget és az irgalmasságot ezeríziglen azok iránt, a kik őt szeretik, és az ő parancsolatait megtartják.
10 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
De megfizet azoknak személy szerint, a kik őt gyűlölik, elvesztvén őket; nem késlekedik az ellen, a ki gyűlöli őt, megfizet annak személy szerint.
11 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
Tartsd meg azért a parancsolatot, a rendeléseket és végzéseket, a melyeket én e mai napon parancsolok néked, hogy azokat cselekedjed.
12 Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
Ha pedig engedelmeskedtek e végzéseknek, és megtartjátok, és teljesítitek azokat: az Úr, a te Istened is megtartja néked a szövetséget és irgalmasságot, a mely felől megesküdött a te atyáidnak.
13 Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
És szeretni fog téged, és megáld téged, és megsokasít téged; és megáldja a te méhednek gyümölcsét, a te földednek gyümölcsét: gabonádat, mustodat és olajodat; teheneid fajzását és juhaidnak ellését azon a földön, a mely felől megesküdt a te atyáidnak, hogy néked adja azt.
14 A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
Áldottabb lészesz minden népnél; nem lészen közötted magtalan férfi és asszony, sem barmaid között meddő.
15 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
És távol tart az Úr te tőled minden betegséget, és Égyiptomnak minden gonosz nyavalyáját, a melyeket ismersz; nem veti azokat te reád, hanem mind azokra, a kik gyűlölnek téged.
16 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
És megemészted mind a népeket, a melyeket néked ád az Úr, a te Istened; ne kedvezzen a te szemed nékik, és ne tiszteld az ő isteneit; mert tőr gyanánt volna az néked.
17 Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
Ha azt mondod a te szívedben: Többen vannak e népek, mint én, miképen űzhetem én ki őket?
18 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
Ne félj tőlök; emlékezzél meg csak azokról, a miket cselekedett az Úr, a te Istened a Faraóval és mind az égyiptombeliekkel:
19 Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
A nagy kisértésekről, a melyeket láttak a te szemeid, és a jelekről és csudákról; az erős kézről, és a kinyujtott karról, a melylyel kihozott téged az Úr, a te Istened! Így cselekeszik az Úr, a te Istened minden néppel, a melytől te félsz.
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
Sőt még a darázsokat is rájok bocsátja az Úr, a te Istened mind addig, míglen elvesznek azok is, a kik megmaradtak, és a kik elrejtőztek te előled.
21 Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Ne rettenj meg azok előtt, mert közötted van az Úr, a te Istened, nagy és rettenetes Isten!
22 Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
És lassan-lassan kiűzi az Úr, a te Istened e népeket te előled. Nem lehet őket hirtelen kipusztítanod, hogy a mezei vadak meg ne sokasodjanak ellened!
23 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
De az Úr, a te Istened elődbe veti őket, és nagy romlással rontja meg őket, míglen elvesznek.
24 Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
Az ő királyaikat is kezedbe adja, hogy eltöröljed az ő nevöket az ég alól; senki ellened nem állhat, míglen elveszted őket.
25 Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Az ő isteneiknek faragott képeit tűzzel égesd meg; az azokon lévő ezüstöt és aranyat meg ne kívánd, és magadnak el ne vedd, hogy tőrbe ne essél miatta; mert útálatosság az az Úr előtt, a te Istened előtt.
26 Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.
Útálatosságot pedig ne vígy be a te házadba, hogy átokká ne légy, mint az, hanem megvetvén vesd meg azt, és útálván útáld meg azt, mert átkozott.

< Deuteronomy 7 >