< Deuteronomy 6 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí Olúwa Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani.
و این است اوامر و فرایض و احکامی که یهوه، خدای شما، امر فرمود که به شماتعلیم داده شود، تا آنها را در زمینی که شما بسوی آن برای تصرفش عبور می‌کنید، بجا آورید.۱
2 Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀.
و تااز یهوه خدای خود ترسان شده، جمیع فرایض واوامر او را که من به شما امر می‌فرمایم نگاه داری، تو و پسرت و پسر پسرت، در تمامی ایام عمرت و تا عمر تو دراز شود.۲
3 Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ.
پس‌ای اسرائیل بشنو، و به عمل نمودن آن متوجه باش، تا برای تو نیکوباشد، و بسیار افزوده شوی در زمینی که به شیر وشهد جاری است، چنانکه یهوه خدای پدرانت تورا وعده داده است.۳
4 Gbọ́ ìwọ Israẹli, Olúwa Ọlọ́run wa, Olúwa kan ni.
‌ای اسرائیل بشنو، یهوه، خدای ما، یهوه واحد است.۴
5 Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ.
پس یهوه خدای خود را به تمامی جان و تمامی قوت خود محبت نما.۵
6 Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín.
و این سخنانی که من امروز تو را امر می‌فرمایم، بر دل توباشد.۶
7 Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde.
و آنها را به پسرانت به دقت تعلیم نما، وحین نشستنت در خانه، و رفتنت به راه، و وقت خوابیدن و برخاستنت از آنها گفتگو نما.۷
8 Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín.
و آنهارا بردست خود برای علامت ببند، و در میان چشمانت عصابه باشد.۸
9 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
و آنها را بر باهوهای درخانه ات و بر دروازه هایت بنویس.۹
10 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ,
و چون یهوه، خدایت، تو را به زمینی که برای پدرانت ابراهیم و اسحاق و یعقوب قسم خورد که به تو بدهد، درآورد، به شهرهای بزرگ وخوشنمایی که تو بنا نکرده‌ای،۱۰
11 àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó,
و به خانه های پر از هر چیز نیکو که پر نکرده‌ای، و حوضهای کنده شده‌ای که نکنده‌ای، و تاکستانها و باغهای زیتونی که غرس ننموده‌ای، و از آنها خورده، سیرشدی.۱۱
12 ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé Olúwa, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú.
آنگاه با حذر باش مبادا خداوند را که تورا از زمین مصر، از خانه بندگی بیرون آورد، فراموش کنی.۱۲
13 Bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan.
از یهوه خدای خود بترس و اورا عبادت نما و به نام او قسم بخور.۱۳
14 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká;
خدایان دیگر را از خدایان طوایفی که به اطراف تومی باشند، پیروی منمایید.۱۴
15 torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà.
زیرا یهوه خدای تودر میان تو خدای غیور است، مبادا غضب یهوه، خدایت، برتو افروخته شود، و تو را از روی زمین هلاک سازد.۱۵
16 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa.
یهوه خدای خود را میازمایید، چنانکه او رادر مسا آزمودید.۱۶
17 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín.
توجه نمایید تا اوامر یهوه خدای خود را و شهادات و فرایض او را که به شما امر فرموده است، نگاه دارید.۱۷
18 Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú Olúwa, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
و آنچه درنظر خداوند راست و نیکوست، به عمل آور تابرای تو نیکو شود، و داخل شده آن زمین نیکو راکه خداوند برای پدرانت قسم خورد به تصرف آوری.۱۸
19 Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí Olúwa ti ṣèlérí.
و تا جمیع دشمنانت را از حضورت اخراج نماید، چنانکه خداوند گفته است.۱۹
20 Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?”
چون پسر تو در ایام آینده از تو سوال نموده، گوید که مراد از این شهادات و فرایض واحکامی که یهوه خدای ما به شما امر فرموده است، چیست؟۲۰
21 Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti.
پس به پسر خود بگو: ما درمصر غلام فرعون بودیم، و خداوند ما را از مصر بادست قوی بیرون آورد.۲۱
22 Lójú wa ni Olúwa tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀.
و خداوند آیات ومعجزات عظیم و ردی‌ای بر مصر و فرعون وتمامی اهل خانه او در نظر ما ظاهر ساخت.۲۲
23 Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa.
وما را از آنجا بیرون آورد تا ما را به زمینی که برای پدران ما قسم خورد که به ما بدهد، درآورد.۲۳
24 Olúwa pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní.
وخداوند ما را مامور داشت که تمام این فرایض رابجا آورده، از یهوه خدای خود بترسیم، تا برای ماهمیشه نیکو باشد و ما را زنده نگاه دارد، چنانکه تاامروز شده است.۲۴
25 Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”
و برای ما عدالت خواهد بودکه متوجه شویم که جمیع این اوامر را به حضوریهوه خدای خود بجا آوریم، چنانکه ما را امرفرموده است.۲۵

< Deuteronomy 6 >