< Deuteronomy 6 >
1 Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí Olúwa Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani.
EIA na kauoha, na kanawai, a me na olelo kupaa, a Iehova ko oukou Akua i kauoha mai ai e ao aku ia oukou, i malama aku ai oukou ma ka aina e hele aku nei oukou e noho:
2 Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀.
I mea e makau aku ai oe ia Iehova i kou Akua, e malama i kona mau kanawai a pau, a me kana mau kauoha a'u e kauoha aku nei ia oe; o oe, a me kau keiki, a me kau moopuna, i na la a pau o kou ola'na, i hooloihiia'i kou mau la.
3 Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ.
E hoolohe hoi oe, e ka Iseraela, a hoomanao e malama hoi, i pomaikai ai oe, i mahuahua loa ai noi oukou, ma ka aina e kahe ana o ka waiu a me ka meli, e like me ka Iehova ke Akua o kou poe kupuna i olelo mai ai ia oe.
4 Gbọ́ ìwọ Israẹli, Olúwa Ọlọ́run wa, Olúwa kan ni.
E hoolohe mai, e ka Iseraela; O Iehova ko kakou Akua, hookahi no Iehova.
5 Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ.
E aloha aku oe ia Iehova i kou Akua me kou naau a pau, me kou uhane a pau, a me kou ikaika a pau.
6 Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín.
O keia mau olelo a'u e kauoha aku nei ia oe i keia la, e waiho no ia maloko o kou naau;
7 Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde.
A e ao pono aku oe ia mau mea i au mau keiki, a e kamailio aku ia mau mea i kou noho ana ma kou hale, a i kou hele ana ma ke ala, i kou moe ana ilalo, a me kou ala ana iluna.
8 Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín.
A e nakii oe ia mau mea i hoailona ma kou lima, a e lilo ia i mea e hoomanao ai mawaena o kou mau maka.
9 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
A e kakau oe ia mau mea ma na lapauila o kou puka hale, a me na puka pa ou.
10 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ,
A i ka manawa a Iehova kou Akua i kai aku ai ia oe i ka aina ana i hoohiki mai ai i kou mau kupuna, ia Aberahama, ia Isaaka, a me Iakoba, e haawi mai ia oe i na kulanakauhale nui a maikai, aole nau i kukulu,
11 àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó,
A me na hale piha i ka waiwai, aole nau i hoolako, a me na luawai i eliia, aole nau i eil, i na pawaina a me na laau oliva, aole nau i kanu; aia ai iho oe a maona;
12 ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé Olúwa, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú.
Alaila e malama ia oe iho, o hoopoina oe ia Iehova, nana oe i lawe mai ka aina o Aigupita mai, mailoko mai hoi o ka hale hooluhi.
13 Bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan.
E makau oe ia Iehova i kou Akua, e malama ia ia, a e hoohiki oe ma kona inoa.
14 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká;
Mai hele aku oukou mamuli o na akua e, o na akua o na kanaka e noho ana a puni o oukou;
15 torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà.
O hoaaia mai auanei ka inaina o Iehova kou Akua ia oe, a lukuia mai oe mai ke alo aku o ka honua: (no ka mea, o Iehova kou Akua, he Akua lili ia iwaena o oukou.)
16 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa.
Mai aa aku oukou ia Iehova i ko oukou Akua, e like me ko oukou aa ana ma Masa.
17 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín.
E malama pono oukou i na kauoha a Iehova ko oukou Akua, me kana mau oihana, a me kona mau kanawai, ana i kauoha mai ai ia oe.
18 Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú Olúwa, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
E hana oe i ka pono a me ka maikai imua i ke alo o Iehova; i pomaikai ai oe, i komo ai hoi oe a noho ma ka aina maikai a Iehova i hoohiki mai ai i ou mau kupuna;
19 Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí Olúwa ti ṣèlérí.
I hookuke aku ai i kou poe enemi a pau mai kou alo aku, e like me ka Iehova i olelo mai ai.
20 Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?”
Aia ninau mai kau keiki ia oe ma ia hope aku, i ka i ana mai, Heaha na oihana, na kanawai, a me na olelo kupaa a Iehova ko kakou Akua i kauoha mai ai ia oukou?
21 Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti.
Alaila oe e olelo aku ai i kau keiki, He poe kauwa hooluhi makou a Parao i Aigupita, na Iehova makou i kai ae mai Aigupita mai me ka lima ikaika.
22 Lójú wa ni Olúwa tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀.
Ua hoike mai o Iehova i na hoailona, a me na mea kupanaha, he nui a he ino maluna o Aigupita, maluna o Parao, a maluna hoi o kona mau ohua a pau, imua o ko makou maka;
23 Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa.
A kai mai la oia ia makou mai ia wahi mai, i hookomo mai ai ia ia makou iloko, e haawi ia makou i ka aina ana i hoohiki ai i ko makou poe kupuna.
24 Olúwa pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní.
Kauoha mai la o Iehova ia makou e malama i keia mau kanawai a pau, e makau ia Iehova ko makou Akua, i pomaikai mau ai makou, i malama mai ai hoi oia ia makou e ola ana, e like me ia i keia la.
25 Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”
A e lilo ia i pono no kakou, ke hoomanao kakou e malama i neia mau kauoha imua o Iehova ko kakou Akua, e like me ia i kauoha mai ai ia kakou.