< Deuteronomy 6 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí Olúwa Ọlọ́run yín pàṣẹ fún mi láti kọ́ ọ yín kí ẹ lè kíyèsi i, ní ilẹ̀ náà tí ẹ ó ni lẹ́yìn tí ẹ bá kọjá a Jordani.
Hae loknawk loe Jordan vapui nang kat o moe, na toep o ih prae thungah na oh o naah na sak o hanah, nihcae patuk han koi, na Angraeng Sithaw mah paek ih kaalok, lokcaekhaih hoi zaehhoihaih daan lok ah oh.
2 Kí ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn, lẹ́yìn wọn bá à lè bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá wà láyé, nípa pípa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ tí mo fún un yín mọ́, kí ẹ bá à lè pẹ́ lórí ilẹ̀.
To tiah ni nangmah hoi na caanawk, na caanawk ih caa patoengnawk mah, kang paek ih lokcaekhaih hoi zaehhoihaih daan loknawk to hing thung pazui o tih, na Angraeng Sithaw to zii o ueloe, hinglung doeh sawk o tih.
3 Gbọ́ ìwọ Israẹli, kí o sì ṣọ́ra láti gbọ́rọ̀, kí ó bá à lè dára fún ọ, kí o bá à lè gbilẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ní ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ ti ṣèlérí fún ọ.
Aw Israel kaminawk, tahngai oh; nam panawk ih Angraeng Sithaw mah nangcae khaeah thuih ih lok baktih toengah, nangcae loe tahnutui hoi khoitui longhaih prae ah, khosak na hoih o tih, pop parai ah nang pung o thaih hanah, acoehaih hoiah pazui oh.
4 Gbọ́ ìwọ Israẹli, Olúwa Ọlọ́run wa, Olúwa kan ni.
Aw Israel kaminawk, tahngai oh; aicae Angraeng Sithaw loe, maeto khue kaom Angraeng ah oh.
5 Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ.
Na Angraeng Sithaw to na palungthin boih, na hinghaih boih, na thacakhaih boih hoiah palung ah.
6 Àwọn àṣẹ tí mo fún un yín lónìí gbọdọ̀ máa wà lóókan àyà yín.
Vaihniah kang thuih o ih hae loknawk hae na palungthin thungah pakuem oh;
7 Ẹ fi kọ́ àwọn ọmọ yín gidigidi. Bí ẹ bá jókòó nínú ilé, ẹ jíròrò nípa wọn, àti nígbà tí ẹ bá ń rìn ní ojú ọ̀nà, bí ẹ bá dùbúlẹ̀ àti nígbà tí ẹ bá dìde.
na caanawk ih caa patoeng khaeah doeh kahoih ah patuk oh; imthung ah nang hnut o naah maw, loklam na caeh o naah maw, na iih o moe, nang thawk o naah maw doeh thui pae oh.
8 Ẹ so wọ́n sí ọwọ́ yín fún àmì, ẹ so ó mọ́ iwájú orí yín.
Na ban pongah to loknawk to angmathaih ah pathlet oh loe, na mik salak ih lu pataeh nuiah doeh zaeng oh.
9 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
Na khongkha hoi na imthung ih tung pongah doeh tarik oh.
10 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá mú yín dé ilẹ̀ náà tí ó ti búra fún àwọn baba yín, fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu láti fi fún un yín, ilẹ̀ tí ó kún fún àwọn ìlú ńlá ńlá tí kì í ṣe ẹ̀yin ló kọ́ ọ,
Na Angraeng Sithaw mah na sah o ai ih kalen parai, kahoih phi vangpuinawk nangcaeh khaeah paek hanah, nam pa Abraham, Isak hoi Jakob khaeah lokkam ih prae thungah ang caeh haih naah loe,
11 àwọn ilé tí ó kún fún gbogbo ohun mèremère tí kì í ṣe ẹ̀yin ló rà wọ́n, àwọn kànga tí ẹ kò gbẹ́, àti àwọn ọgbà àjàrà àti èso olifi tí kì í ṣe ẹ̀yin ló gbìn wọ́n. Nígbà tí ẹ bá jẹ tí ẹ sì yó,
na sah o ai ih kahoih hmuennawk hoiah kakoi imnawk, na takaeh o ai ih tuikhawnawk, na patit o ai ih misur takhanawk hoi olive kungnawk to caak moe, zok nam hah o haih atue om tih.
12 ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé Olúwa, tí o mú un yín jáde láti Ejibiti wá, kúrò ní oko ẹrú.
Misong ah na oh o haih, Izip prae thung hoiah zaehoikung, Angraeng to na pahnet o han ai ah acoe oh.
13 Bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ, Òun nìkan ni kí o sì máa sìn, búra ní orúkọ rẹ̀ nìkan.
Na Angraeng Sithaw to zii oh loe, anih ih tok khue to sah oh; anih ih ahmin hoiah lokkamhaih to sah oh.
14 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run àwọn tí ó yí i yín ká;
Nangcae taengah kaom kaminawk ih, sithawnawk hoi kalah sithawnawk hnukah patom o hmah;
15 torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run owú ni, ìbínú rẹ̀ yóò sì run yín kúrò ní ilẹ̀ náà.
to tih ai nahaeloe nangcae salakah kaom, na Angraeng Sithaw loe ut panoek Sithaw ah oh pongah, nangcae nuiah na Angraeng Sithaw palungphuihaih hmai baktiah kangh ueloe, long nui hoiah na tamit o boih moeng tih.
16 Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run yín wò bí ẹ̀yin ti dán wò ní Massa.
Massah ah na sak o ih baktih toengah, na Angraeng Sithaw to tanoek o hmah.
17 Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń pa àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́ àti àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà tí ó ti fún un yín.
Na Angraeng Sithaw mah paek ih, pazui han koi a thuih ih loknawk hoi zaehhoihaih daannawk to nangcae mah kahoih ah pazui oh.
18 Ẹ ṣe èyí tí ó dára tí ó sì tọ́ lójú Olúwa, kí ó bá à lè dára fún un yín, kí ẹ̀yin bá à lè lọ láti gba ilẹ̀ dáradára náà tí Ọlọ́run ti fi ìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.
Angraeng hmaa ah katoeng hoi kahoih hmuen to sah oh; to tiah nahaeloe Angraeng mah nam panawk khaeah paek han lokkam ih, prae thungah na kun o thaih ueloe, khosak na hoih o tih,
19 Ẹ̀yin yóò sì ti àwọn ọ̀tá yín jáde níwájú u yín bí Olúwa ti ṣèlérí.
Angraeng mah thuih ih lok baktih toengah, na misanawk to nangmacae hma ah nam khueng o sak boih tih.
20 Ní ọjọ́ iwájú, bí ọmọ rẹ bá béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin wọ̀nyí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún ọ?”
Hmabang tue ah na caa mah, Aicae Angraeng Sithaw mah thuih ih pazui han koi loknawk hoi lokcaekhaihnawk loe tih thuih koehhaih ih aa? tiah dueng nahaeloe,
21 Sọ fún un pé: “Ẹrú Farao ní ilẹ̀ Ejibiti ni wá tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa fi ọwọ́ agbára ńlá yọ wá jáde lóko ẹrú Ejibiti.
na caa khaeah, Kaicae loe Izip prae ah Faro ih misong ah ka oh o; toe a ban thacakhaih hoiah Angraeng mah Izip prae thung hoiah tacawt haih;
22 Lójú wa ni Olúwa tí ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu: tí ó lágbára tí ó sì ba ni lẹ́rù: lórí Ejibiti àti Farao, àti gbogbo ènìyàn rẹ̀.
Angraeng mah kaicae mikhnuk ah, angmathaih, dawnrai hmuennawk, zit kathok, kalen parai hmuennawk to Izip prae, Faro hoi anih ih imthung takoh boih nuiah phaksak.
23 Ṣùgbọ́n ó mú wa jáde láti ibẹ̀ wá láti mú wa wọ inú àti láti fún wa ní ilẹ̀ tí ó ti fì búra fún àwọn baba ńlá wa.
Toe aicae ampanawk khaeah paek hanah sak ih lokkamhaih baktih toengah, to prae thungah akunsak hanah Izip prae thung hoiah kaicae hae ang tacawt haih.
24 Olúwa pàṣẹ fún wa láti ṣe ìgbọ́ràn sí gbogbo ìlànà wọ̀nyí, láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, kí ó ba à lè máa dára fún wa nígbà gbogbo, kí a sì lè wà láyé, bí a ṣe wà títí di òní.
Aicae Angraeng Sithaw to zit moe, hae zaehhoihaih daannawk pazui boih hanah, Angraeng mah lokthuih; vaihni khoek to anih mah tahmenhaih amtuengsak baktih toengah, aicae hinghaih doeh na pathlung pae tih.
25 Bí a bá ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin wọ̀nyí mọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, bí ó ti pàṣẹ fún wa, èyí ni yóò máa jẹ́ òdodo wa.”
Hae kaaloknawk hae aicae Angraeng Sithaw hmaa ah a pazui o thaih boih nahaeloe, aicae toenghaih ah om tih, tiah thui pae oh, tiah a naa.

< Deuteronomy 6 >