< Deuteronomy 5 >

1 Mose sì pe gbogbo Israẹli jọ, ó sì wí pé, Gbọ́ ìwọ Israẹli, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etí ìgbọ́ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.
Then called Moses unto all Israel and said unto them—Hear, O Israel, the statutes and the regulations, which I am speaking in your ears to-day, —so shall ye learn them, and observe to do them.
2 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Horebu.
Yahweh our God, solemnised with us a covenant in Horeb:
3 Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láààyè níbí lónìí.
not with our fathers did Yahweh solemnise this covenant, —but with us, ourselves—these here to-day, all of us living.
4 Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrín iná lórí òkè.
Face to face, spake Yahweh with you in the mount out of the midst of the fire,
5 (Ní ìgbà yìí, mo wà láàrín ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè.) Ó sì wí pé,
(I was standing between Yahweh and you, at that time, to declare unto you the word of Yahweh, —for ye shrank with fear from the presence of the fire, and went not up in the mount) saying: —
6 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
I, am Yahweh thy God, who have brought thee forth out of the land of Egypt out of the house of servants: —
7 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
Thou shalt not have other gods, besides me:
8 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
Thou shalt not make unto thee an image, any form that is in the heavens above, or that is in the earth beneath or that is in the waters beneath the earth:
9 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
thou shalt not bow thyself down to them nor be led to serve them, —for, I Yahweh thy God, am a jealous GOD, visiting the iniquity of fathers upon sons even unto three generations and unto four, unto them that hate me;
10 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
but shewing lovingkindness unto a thousand generation—unto them who love me, and keep my commandments:
11 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
Thou shalt not utter the name of Yahweh thy God, for falsehood, —for Yahweh will not let him go unpunished who uttereth his name for falsehood:
12 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.
Observe the sabbath day, to hallow it, —as Yahweh thy God, hath commanded thee:
13 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ.
six days, shalt thou labour, and do all thy work;
14 Ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti akọ màlúù rẹ, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, àti ohun ọ̀sìn rẹ kan, àti àlejò tí ń bẹ nínú ibodè rẹ; kí ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin kí ó lè sinmi gẹ́gẹ́ bí ìwọ.
but, the seventh day, is a sabbath unto Yahweh thy God, —thou shalt do no work—thou nor thy son nor thy daughter nor thy servant nor thy handmaid nor thine ox nor thine ass nor any of thy cattle, nor thy sojourner who is within thy gates, that thy servant and thy handmaid may rest, as well as thou.
15 Sì rántí pé, ìwọ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yọ ọ́ kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe pàṣẹ fún ọ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
So shalt thou remember that a servant, wast thou in the land of Egypt, and that Yahweh thy God brought thee forth from thence, with a firm hand, and with a stretched-out arm, —for this cause, hath Yahweh thy God commanded thee to keep the sabbath day:
16 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Honour thy father and thy mother, as Yahweh thy God hath commanded thee, —that thy days may be prolonged and that it may go well with thee, upon the soil which Yahweh thy God is about to give unto thee:
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
Thou shalt not commit murder:
18 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
Neither shalt thou commit adultery:
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
Neither shalt thou steal:
20 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Neither shalt thou testify against thy neighbour with a witness of falsehood:
21 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéji rẹ, oko rẹ̀, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéji rẹ.”
Neither shalt thou covet thy neighbour’s wife, —neither shalt thou desire thy neighbour’s house, his field, or his servant, or his handmaid, his ox or his ass, or anything that is thy neighbour’s.
22 Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrín iná, ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri, kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú wàláà méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
These words, spake Yahweh unto all the convocation of you in the mount out of the midst of the fire the cloud and the thick gloom, a loud voice, and added not, —and he wrote them upon two tables of stone, and gave them unto me.
23 Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọ iná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn àgbàgbà yín tọ̀ mí wá.
And it came to pass, when ye heard the voice out of the midst of the darkness, the mountain also burning with fire, then drew ye near unto me, even all the heads of your tribes and your elders,
24 Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárín iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láààyè lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá bá a sọ̀rọ̀.
and ye said—Lo! Yahweh our God hath let us see his glory and his greatness, his voice also, have we heard out of the midst of the fire, —this day, have we seen, that God may speak with man who yet may live.
25 Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.
Now, therefore why should we die? for this great fire, will consume, us, —if we ourselves, hear the voice of Yahweh our God any more, we shall die.
26 Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Ọlọ́run alààyè láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?
For who [is there] of all flesh, that ever heard the voice of a Living God speaking out of the midst of fire as we, and yet lived?
27 Súnmọ́ tòsí ibẹ̀ kí o sì gbọ́ gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò sọ, nígbà náà sọ ohunkóhun tí Olúwa Ọlọ́run wa sọ fún ọ fún wa. A ó sì fetísílẹ̀, a ó sì gbọ́rọ̀.”
Go, thou, near, and hear, all that Yahweh our God shall say, —so shalt thou speak unto us, all that Yahweh our God shall speak unto thee and we will hear and do.
28 Olúwa ń gbọ́ nígbà tí ẹ̀yin ń bá mi sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn ènìyàn yí sọ fún ọ. Gbogbo ohun tí wọ́n sọ dára,
And Yahweh heard the voice of your words, when ye spake unto me, —and Yahweh said unto me—I have heard the voice of the words of this people which they have spoken unto thee, they have well said all which they have spoken.
29 ìbá ti dára tó, bí ọkàn wọn bá lè bẹ̀rù mi, tí ó sì ń pa gbogbo òfin mi mọ́ nígbà gbogbo, kí ó bá à lè dára fún wọn, àti àwọn ọmọ wọn láéláé.
Oh that this their heart might remain in them to revere me, and to keep all my commandments all the days, —that it might be well with them and with their sons unto times age-abiding.
30 “Lọ sọ fún wọn kí wọn padà sínú àgọ́ wọn.
Go, say unto them, —Return ye to your tents.
31 Ṣùgbọ́n ìwọ túbọ̀ dúró síbí pẹ̀lú mi, kí n bá à lè fún ọ ní àwọn àṣẹ tí o gbọdọ̀ fi kọ́ wọn láti máa tẹ̀lé ní ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún wọn láti ní.”
Thou, therefore here stand with me and let me speak unto thee—all the commandment and the statutes and the regulations which thou shalt teach them, —that they may do [them] in the land which I am giving unto them to possess it.
32 Torí èyí, ẹ ṣọ́ra láti máa ṣe ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín tí pa ní àṣẹ fún un yín; ẹ má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì.
So then ye must observe to do, as Yahweh your God hath commanded you, —ye must not turn aside to the right hand or to the left.
33 Ẹ rìn ní gbogbo ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ bá à le yè, kí ó sì dára fún un yín, kí ọjọ́ ọ yín bá à lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò gbà.
In all the way which Yahweh your God hath commanded you, must ye walk, —that ye may live and it be well with you, and that ye may prolong your days in the land, which ye shall possess.

< Deuteronomy 5 >