< Deuteronomy 5 >

1 Mose sì pe gbogbo Israẹli jọ, ó sì wí pé, Gbọ́ ìwọ Israẹli, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etí ìgbọ́ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.
And Moses summoned all of Israel, and he said to them: “Listen, O Israel, to the ceremonies and judgments, which I am speaking to your ears on this day. Learn them, and fulfill them in deed.
2 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Horebu.
The Lord our God formed a covenant with us at Horeb.
3 Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láààyè níbí lónìí.
He did not make the covenant with our fathers, but with us, who are alive and in the present time.
4 Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrín iná lórí òkè.
He spoke to us face to face on the mountain, from the midst of fire.
5 (Ní ìgbà yìí, mo wà láàrín ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè.) Ó sì wí pé,
I was the mediator, for I was in the middle between the Lord and you, at that time, to announce his words to you. For you were afraid of the fire, and so you did not ascend to the mountain. And he said:
6 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
‘I am the Lord your God, who led you away from the land of Egypt, from the house of servitude.
7 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
You shall not have strange gods in my sight.
8 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
You shall not make for yourself a graven image, nor the likeness of anything, which is in heaven above, or on earth below, or which abides in the waters under the earth.
9 Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
You shall not adore and you shall not worship these things. For I am the Lord your God, a jealous God, repaying the iniquity of the fathers upon the sons to the third and fourth generation to those who hate me,
10 Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
and acting with mercy in thousands of ways to those who love me and keep my precepts.
11 Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
You shall not use the name of the Lord your God in vain. For he will not go unpunished who takes up his name over an unimportant matter.
12 Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.
Observe the day of the Sabbath, so that you may sanctify it, just as the Lord your God has instructed you.
13 Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ.
For six days, you shall labor and do all your work.
14 Ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti akọ màlúù rẹ, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, àti ohun ọ̀sìn rẹ kan, àti àlejò tí ń bẹ nínú ibodè rẹ; kí ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin kí ó lè sinmi gẹ́gẹ́ bí ìwọ.
The seventh is the day of the Sabbath, that is, the rest of the Lord your God. You shall not do any work in it, nor shall your son, nor daughter, nor man servant, nor woman servant, nor ox, nor donkey, nor any of your cattle, nor the sojourner who is within your gates, so that your men and woman servants may rest, just as you do.
15 Sì rántí pé, ìwọ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yọ ọ́ kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe pàṣẹ fún ọ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
Remember that you also were servants in Egypt, and the Lord your God led you away from that place with a strong hand and an outstretched arm. Because of this, he has instructed you so that you would observe the Sabbath day.
16 Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
Honor your father and mother, just as the Lord your God has instructed you, so that you may live a long time, and so that it may be well with you in the land, which the Lord your God will give to you.
17 Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
You shall not murder.
18 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
And you shall not commit adultery.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
And you shall not commit theft.
20 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
Neither shall you speak false testimony against your neighbor.
21 Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéji rẹ, oko rẹ̀, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéji rẹ.”
You shall not covet your neighbor’s wife, nor his house, nor his field, nor his man servant, nor his woman servant, nor his ox, nor his donkey, nor anything out of all that is his.’
22 Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrín iná, ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri, kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú wàláà méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
The Lord spoke these words to the entire multitude of you on the mountain, from the midst of the fire and the cloud and the darkness, with a loud voice, adding nothing more. And he wrote them on two tablets of stone, which he delivered to me.
23 Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọ iná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn àgbàgbà yín tọ̀ mí wá.
Then, after you heard the voice from the midst of the darkness, and you saw the mountain burning, you approached me, all you leaders of the tribes and those greater by birth. And you said:
24 Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárín iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láààyè lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá bá a sọ̀rọ̀.
‘Behold, the Lord our God has revealed to us his majesty and his greatness. We have heard his voice from the midst of fire, and we have proven today that, though God is speaking with man, man has lived.
25 Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.
Therefore, why should we die, and why should this very great fire devour us? For if we hear the voice of the Lord our God any longer, we will die.
26 Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Ọlọ́run alààyè láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?
What is all flesh, that it would hear the voice of the living God, who speaks from the midst of fire, just as we have heard it, and be able to live?
27 Súnmọ́ tòsí ibẹ̀ kí o sì gbọ́ gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò sọ, nígbà náà sọ ohunkóhun tí Olúwa Ọlọ́run wa sọ fún ọ fún wa. A ó sì fetísílẹ̀, a ó sì gbọ́rọ̀.”
Instead, you should approach and listen to all the things that the Lord our God will say to you. And you will speak to us, and we will listen and do these things.’
28 Olúwa ń gbọ́ nígbà tí ẹ̀yin ń bá mi sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn ènìyàn yí sọ fún ọ. Gbogbo ohun tí wọ́n sọ dára,
But when the Lord had heard this, he said to me: ‘I have heard the voice of the words of this people, which they spoke to you. All this, they have spoken well.
29 ìbá ti dára tó, bí ọkàn wọn bá lè bẹ̀rù mi, tí ó sì ń pa gbogbo òfin mi mọ́ nígbà gbogbo, kí ó bá à lè dára fún wọn, àti àwọn ọmọ wọn láéláé.
Who will grant to them to have such a mind, so that they may fear me, and may keep all my commandments at all times, so that it may be well with them and with their sons forever?
30 “Lọ sọ fún wọn kí wọn padà sínú àgọ́ wọn.
Go and say to them: Return to your tents.
31 Ṣùgbọ́n ìwọ túbọ̀ dúró síbí pẹ̀lú mi, kí n bá à lè fún ọ ní àwọn àṣẹ tí o gbọdọ̀ fi kọ́ wọn láti máa tẹ̀lé ní ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún wọn láti ní.”
But as for you, stand here with me, and I will speak to you all my commandments and ceremonies, as well as judgments. These, you shall teach them, so that they may do them in the land, which I will give to them as a possession.
32 Torí èyí, ẹ ṣọ́ra láti máa ṣe ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín tí pa ní àṣẹ fún un yín; ẹ má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì.
And so, keep and do the things which the Lord God has commanded you. You shall not turn aside, neither to the right, nor to the left.
33 Ẹ rìn ní gbogbo ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ bá à le yè, kí ó sì dára fún un yín, kí ọjọ́ ọ yín bá à lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò gbà.
For you shall walk in the way that the Lord your God has instructed, so that you may live, and it may be well with you, and your days may be extended in the land of your possession.’”

< Deuteronomy 5 >