< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
Şi acum dă ascultare, Israele, la statutele şi la judecăţile care vă învăţ, ca să le faceţi, ca să trăiţi şi să intraţi şi să stăpâniţi ţara pe care v-o dă DOMNUL Dumnezeul părinţilor voştri.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
Să nu adăugaţi la cuvântul pe care vi-l poruncesc eu, nici să nu scădeţi din el, ca să păziţi poruncile DOMNULUI Dumnezeul vostru pe care vi le poruncesc.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
Ochii voştri au văzut ce a făcut DOMNUL din cauza lui Baal-Peor; DOMNUL Dumnezeul tău a nimicit dintre voi pe toţi bărbaţii care l-au urmat pe Baal-Peor.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
Dar voi, care v-aţi lipit de DOMNUL Dumnezeul vostru, sunteţi astăzi fiecare în viaţă.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Iată, v-am învăţat statute şi judecăţi, precum mi-a poruncit DOMNUL Dumnezeul meu, ca astfel să faceţi în ţara în care intraţi să o stăpâniţi.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
Ţineţi-le de aceea şi faceţi-le, pentru că aceasta este înţelepciunea voastră şi înţelegerea voastră înaintea ochilor naţiunilor care vor auzi toate aceste statute şi vor spune: Cu adevărat această naţiune mare este un popor înţelept şi priceput.
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
Fiindcă ce naţiune este atât de mare şi să aibă pe Dumnezeu atât de aproape de ei, precum este DOMNUL Dumnezeul nostru în orice îl chemăm?
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Şi ce naţiune este atât de mare, încât să aibă statute şi judecăţi atât de drepte ca toată legea aceasta, pe care o pun în această zi înaintea voastră?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Numai ia seama la tine însuţi şi păzeşte-ţi sufletul cu atenţie, ca nu cumva să uiţi lucrurile pe care ochii tăi le-au văzut, şi să se depărteze de inima ta în toate zilele vieţii tale, ci să le predai fiilor tăi şi fiilor fiilor tăi;
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
Mai ales în ziua când ai stat în picioare înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău în Horeb, când DOMNUL mi-a spus: Adună-mi poporul şi îi voi face să audă cuvintele mele, ca să înveţe să se teamă de mine în toate zilele cât vor trăi pe pământ şi să îi înveţe pe copiii lor.
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
Şi v-aţi apropiat şi aţi stat în picioare la poalele muntelui; şi muntele ardea cu foc până în inima cerului, cu întuneric, nori şi întuneric adânc.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
Şi DOMNUL v-a vorbit din mijlocul focului; aţi auzit vocea cuvintelor, dar nu aţi văzut nicio înfăţişare, aţi auzit numai o voce.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
Şi el v-a spus legământul său, pe care v-a poruncit să îl împliniţi, adică cele zece porunci; şi le-a scris pe două table de piatră.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
Şi DOMNUL mi-a poruncit în acel timp să vă învăţ statute şi judecăţi, să le împliniţi în ţara în care treceţi să o stăpâniţi.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
De aceea luaţi bine seama la voi, pentru că nu aţi văzut niciun fel de înfăţişare în ziua în care v-a vorbit DOMNUL în Horeb, din mijlocul focului,
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
Ca nu cumva să vă stricaţi şi să vă faceţi chip cioplit, înfăţişarea vreunui chip, asemănarea unei părţi bărbăteşti sau femeieşti,
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
Asemănare a oricărui animal de pe pământ, asemănare a oricărei păsări înaripate care zboară în văzduh,
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
Asemănare a oricărei târâtoare care se târăşte pe pământ, asemănare a oricărui peşte care este în apele de sub pământ,
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
Şi ca nu cumva să îţi ridici ochii spre cer şi când vezi soarele şi luna şi stelele, adică toată oştirea cerului, să fii împins să te închini la ele şi să le serveşti, celor pe care DOMNUL Dumnezeul tău le-a împărţit tuturor naţiunilor de sub tot cerul.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
Dar DOMNUL v-a luat şi v-a scos din cuptorul de fier, din Egipt, să îi fiţi un popor al moştenirii, precum sunteţi în această zi.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
Mai mult, DOMNUL s-a mâniat pe mine din cauza voastră şi a jurat că eu nu voi trece Iordanul şi nu voi intra în acea ţară bună, pe care DOMNUL Dumnezeul tău ţi-o dă ca moştenire,
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
Ci eu trebuie să mor în ţara aceasta, nu trebuie să trec peste Iordan, dar voi să treceţi dincolo şi să stăpâniţi această ţară bună.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Luaţi seama la voi înşivă, ca nu cumva să uitaţi legământul DOMNULUI Dumnezeul vostru, pe care l-a făcut cu voi, şi să vă faceţi un chip cioplit, sau asemănarea vreunui lucru, ceea ce DOMNUL Dumnezeul tău ţi-a interzis.
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
Fiindcă DOMNUL Dumnezeul tău este un foc mistuitor, un Dumnezeu gelos.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
După ce vei naşte copii şi copii ai copiilor şi după ce veţi fi rămas mult în ţară şi vă veţi strica şi vă veţi face un chip cioplit, sau o asemănare a ceva, şi veţi face rău înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău, pentru a-l provoca la mânie;
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
Iau astăzi cerul şi pământul ca martori împotriva voastră, că veţi pieri curând în întregime din ţara în care treceţi Iordanul, ca să o stăpâniţi; nu vă veţi lungi zilele în ea, ci veţi fi nimiciţi în întregime.
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
Şi DOMNUL vă va împrăştia printre naţiuni şi veţi rămâne puţini la număr printre păgânii, la care DOMNUL vă va conduce.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
Şi acolo veţi servi unor dumnezei, lucrarea mâinilor oamenilor, lemn şi piatră, care nici nu văd, nici nu aud, nici nu mănâncă, nici nu miros.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
Dar dacă de acolo vei căuta pe DOMNUL Dumnezeul tău, îl vei găsi, dacă îl vei căuta cu toată inima ta şi cu tot sufletul tău.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
Când vei fi în necaz şi toate aceste lucruri vor fi venit asupra ta, în zilele de pe urmă, dacă te întorci la DOMNUL Dumnezeul tău şi vei face ce porunceşte vocea lui;
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
(Pentru că DOMNUL Dumnezeul tău este un Dumnezeu milostiv), el nu te va părăsi, nici nu te va nimici, nici nu va uita legământul părinţilor tăi pe care li l-a jurat.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
Pentru că, întreabă acum despre zilele care au trecut, care au fost înainte de tine, din ziua în care l-a creat Dumnezeu pe om pe pământ şi întreabă de la o margine a cerului până la cealaltă, dacă a mai fost ceva ca acest lucru mare, sau dacă s-a mai auzit altceva asemenea lui?
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
A mai auzit vreun popor vocea lui Dumnezeu vorbind din mijlocul focului, precum ai auzit tu, şi să trăiască?
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
Sau a încercat Dumnezeu să meargă şi să îşi ia o naţiune din mijlocul altei naţiuni, prin ispitiri, prin semne şi prin minuni şi prin război şi printr-o mână tare şi printr-un braţ întins şi prin mari înfricoşări, conform cu tot ce a făcut DOMNUL Dumnezeul vostru pentru voi în Egipt înaintea ochilor tăi?
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
Ţie ţi s-a arătat, ca să cunoşti că DOMNUL, el este Dumnezeu, nu este altul în afară de el.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
Din cer te-a făcut să auzi vocea lui, ca să te instruiască şi pe pământ ţi-a arătat focul său cel mare; şi ai auzit cuvintele lui din mijlocul focului.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
Şi pentru că a iubit pe părinţii tăi, de aceea a ales sămânţa lor după ei şi te-a scos din Egipt înaintea vederii lui cu puterea lui cea mare;
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
Ca să alunge dinaintea ta naţiuni mai mari şi mai puternice decât tine, ca să te aducă înăuntru, să îţi dea ţara lor ca moştenire, precum este în ziua aceasta.
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
Să ştii dar astăzi şi ia aminte în inima ta, că DOMNUL, el este Dumnezeu în cer deasupra şi peste pământul de jos, nu este altul.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
Să ţii de aceea statutele lui şi poruncile lui, pe care ţi le poruncesc astăzi, ca să îţi fie bine, ţie şi copiilor tăi după tine, şi să îţi lungeşti zilele tale pe pământul, pe care DOMNUL Dumnezeul tău ţi-l dă ţie pentru totdeauna.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Atunci Moise a despărţit trei cetăţi de partea aceasta a Iordanului, spre răsăritul soarelui,
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
Ca ucigaşul, care l-a ucis fără intenţie pe aproapele său şi nu l-a urât mai înainte, să fugă acolo; şi fugind într-una din aceste cetăţi, să trăiască,
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
Adică, Beţer în pustiu, în ţinutul podişului, pentru rubeniţi; şi Ramotul în Galaad, pentru gadiţi; şi Golan în Basan, pentru manasiţi.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
Şi aceasta este legea pe care a pus-o Moise înaintea copiilor lui Israel,
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
Acestea sunt mărturiile şi statutele şi judecăţile, pe care Moise le-a vorbit copiilor lui Israel, după ce au ieşit din Egipt,
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
De această parte a Iordanului, în valea din dreptul Bet-Peorului, în ţara lui Sihon, împăratul amoriţilor, care locuia la Hesbon, pe care Moise şi copiii lui Israel l-au bătut, după ce au ieşit din Egipt,
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
Şi au stăpânit ţara lui şi ţara lui Og, împăratul Basanului, doi împăraţi ai amoriţilor, care erau dincoace de Iordan, spre răsăritul soarelui;
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
De la Aroer, care este pe malul râului Arnon, până la Muntele Sion, care este Hermon,
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
Şi toată câmpia de dincoace de Iordan spre est, chiar până la marea câmpiei, sub izvoarele lui Pisga.

< Deuteronomy 4 >