< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
Teraz więc, o Izraelu, słuchaj nakazów i praw, których uczę was wypełniać, abyście żyli i weszli, i posiedli ziemię, którą daje wam PAN, Bóg waszych ojców.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
Nie dodawajcie do słowa, które ja wam nakazuję, ani z niego nie ujmujcie, abyście przestrzegali przykazań PANA, waszego Boga, które ja wam nakazuję.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
Wasze oczy widziały, co PAN uczynił z powodu Baal-Peora, jak każdego człowieka, który poszedł za Baal-Peorem, PAN, twój Bóg, wytracił spośród was.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
A wy, którzy przylgnęliście do PANA, swojego Boga, żyjecie wszyscy aż do dziś.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Spójrzcie, nauczyłem was nakazów i praw, jak mi nakazał PAN, mój Bóg, abyście tak czynili w tej ziemi, do której wchodzicie, aby ją wziąć w posiadanie.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
Przestrzegajcie [ich] więc i wypełniajcie je; to bowiem [jest] wasza mądrość i wasz rozum w oczach narodów, które usłyszą o wszystkich tych nakazach i powiedzą: Zaprawdę, ten wielki naród jest mądrym i rozumnym ludem.
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
Który bowiem naród jest tak wielki, by mieć bogów tak bliskich jak PAN, nasz Bóg, we wszystkim, ilekroć go wzywamy?
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Albo który naród [jest tak] wielki, by mieć nakazy i prawa [tak] sprawiedliwe jak całe to prawo, które dziś wam przedkładam?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Tylko miej się na baczności i strzeż swej duszy pilnie, abyś nie zapomniał o tych rzeczach, które twoje oczy widziały, i aby nie odstępowały [one] od twego serca po wszystkie dni twego życia. Ale ucz ich swoich synów i synów swoich synów.
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
[Nie zapominaj] o dniu, w którym stałeś przed PANEM, swoim Bogiem, na Horebie, gdy PAN powiedział do mnie: Zgromadź mi lud, abym im przekazał swoje słowa, aby nauczyli się mnie bać przez wszystkie dni swego życia na ziemi i żeby uczyli [tego] swoich synów.
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
Wtedy zbliżyliście się i stanęliście pod górą, a góra płonęła ogniem aż po samo niebo, [okryta] ciemnością, obłokiem i mrokiem.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
I PAN przemówił do was spośród ognia. Usłyszeliście dźwięk słów, lecz nie widzieliście żadnej postaci, tylko głos [usłyszeliście].
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
Wówczas oznajmił wam swoje przymierze, które nakazał wam wypełniać, dziesięć przykazań, które napisał na dwóch kamiennych tablicach.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
W tym czasie PAN rozkazał mi nauczać was nakazów i praw, abyście je wypełniali w ziemi, do której idziecie, aby ją wziąć w posiadanie.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
Strzeżcie więc pilnie swoich dusz, gdyż nie widzieliście żadnej postaci w dniu, w którym PAN przemówił do was na Horebie spośród ognia;
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
Abyście się nie zepsuli i nie czynili sobie rzeźbionego posągu, podobizny wszelkiej postaci w kształcie mężczyzny lub kobiety;
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
W kształcie jakiegokolwiek zwierzęcia, które jest na ziemi, w kształcie wszelkiego ptaka skrzydlatego, który lata w powietrzu;
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
W kształcie czegokolwiek, co pełza po ziemi, w kształcie wszelkiej ryby, która jest w wodach pod ziemią.
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
I abyś – gdy podniesiesz swoje oczy ku niebu i ujrzysz słońce, księżyc i gwiazdy, cały zastęp niebios – nie dał się zwieść, by oddać im pokłon i im służyć, ponieważ PAN, twój Bóg, przydzielił je wszystkim ludom pod całym niebem.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
Lecz PAN was wziął i wyprowadził z pieca do topienia żelaza, z Egiptu, abyście byli jego ludem, jego dziedzictwem, jak dziś [jesteście].
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
I PAN rozgniewał się na mnie z waszego powodu, i przysiągł, że nie przejdę Jordanu i nie wejdę do tej dobrej ziemi, którą PAN, twój Bóg, daje tobie w dziedzictwo.
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
Ja bowiem umrę w tej ziemi, nie przejdę Jordanu. Wy zaś przejdziecie i posiądziecie tę dobrą ziemię.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Strzeżcie się, abyście nie zapomnieli o przymierzu PANA, swojego Boga, które z wami zawarł, i nie czynili sobie żadnego rzeźbionego posągu lub podobizny czegokolwiek, czego ci zakazał PAN, twój Bóg.
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
Bo PAN, twój Bóg, jest ogniem trawiącym, Bogiem zazdrosnym.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
Gdy urodzisz synów i wnuki i zestarzejecie się w tej ziemi, jeśli popsujecie się i uczynicie [sobie] rzeźbiony posąg lub podobiznę czegokolwiek, i dopuścicie się zła w oczach PANA, swojego Boga, pobudzając go do gniewu;
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
To biorę dziś na świadków przeciwko wam niebo i ziemię, że prędko wyginiecie doszczętnie z ziemi, do której przejdziecie przez Jordan, aby ją posiąść; nie przedłużycie w niej swych dni, bo zostaniecie całkowicie wytępieni.
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
PAN rozproszy was między narodami i mało z was zostanie pośród narodów, do których PAN was zaprowadzi.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
Tam będziecie służyli bogom, dziełom ludzkich rąk, drewnu i kamieniowi, które nie widzą ani nie słyszą, nie jedzą ani nie wąchają.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
Jeśli jednak stamtąd będziesz szukać PANA, swego Boga, wtedy znajdziesz [go], jeśli będziesz go szukał całym swym sercem i całą swą duszą.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
Gdy znajdziesz się w ucisku i spotka cię to wszystko w ostatnich dniach, jeśli wtedy zawrócisz do PANA, swego Boga, i będziesz słuchał jego głosu;
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
Ponieważ PAN, twój Bóg, jest miłosiernym Bogiem, nie opuści cię ani cię nie zniszczy, ani nie zapomni o przymierzu z twoimi ojcami, które im poprzysiągł.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
Zapytaj się bowiem dawnych czasów, które były przed tobą od dnia, kiedy Bóg stworzył człowieka na ziemi, i od jednego krańca nieba aż do drugiego, czy stała się kiedykolwiek rzecz podobna do tej tak wielkiej albo czy słyszano kiedykolwiek o czymś takim?
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
Czy słyszał [kiedykolwiek jakiś] naród głos Boga mówiącego spośród ognia, tak jak ty słyszałeś, i pozostał żywy?
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
Albo czy Bóg spróbował przyjść i wziąć sobie naród spośród [innego] narodu przez doświadczenia, przez znaki, przez cuda i przez wojny, potężną ręką i wyciągniętym ramieniem, wśród wielkich i strasznych [dzieł] jak to wszystko, co na twoich oczach PAN, wasz Bóg, uczynił dla was w Egipcie?
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
Tobie to ukazano, abyś wiedział, że PAN jest Bogiem i nie ma innego oprócz niego.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
Dał ci słyszeć swój głos z nieba, aby cię pouczyć, a na ziemi ukazał ci swój wielki ogień i usłyszałeś jego słowa spośród ognia.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
A ponieważ umiłował twoich ojców, wybrał ich potomstwo po nich i wyprowadził cię z Egiptu przed sobą swoją wielką mocą;
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
Aby wypędzić przed tobą narody większe i potężniejsze od ciebie, by cię wprowadzić i dać ci ich ziemię w dziedzictwo, jak to [jest] dzisiaj.
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
Poznaj więc dziś i weź to sobie do swego serca, że PAN jest Bogiem wysoko na niebie i nisko na ziemi. Nie ma innego.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
Przestrzegaj więc jego nakazów i przykazań, które dziś tobie nakładam, aby się dobrze powodziło tobie i twoim synom po tobie; abyś też przedłużył swe dni na ziemi, którą PAN, twój Bóg, daje tobie przez wszystkie dni.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Wtedy Mojżesz wydzielił trzy miasta po tej stronie Jordanu na wschodzie;
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
Aby mógł tam uciec zabójca, który zabił swego bliźniego nieumyślnie i wcześniej nie nienawidził go, aby uciekł [on] do jednego z tych miast i pozostał żywy:
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
Beser na pustyni, w ziemi równinnej Rubenitów, Ramot w Gileadzie Gadytów i Golan w Baszanie Manassytów.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
Oto prawo, które Mojżesz przedłożył synom Izraela.
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
To są świadectwa, nakazy i prawa, które Mojżesz ogłosił synom Izraela, kiedy wyszli z Egiptu;
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
Po tej stronie Jordanu, w dolinie naprzeciw Bet-Peor, w ziemi Sichona, króla Amorytów, mieszkającego w Cheszbonie, którego Mojżesz i synowie Izraela pobili po wyjściu z Egiptu;
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
I posiedli jego ziemię i ziemię Oga, króla Baszanu – dwóch królów Amorytów, którzy [byli] po tej stronie Jordanu na wschodzie;
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
Od Aroeru, leżącego nad brzegiem rzeki Arnon, aż do góry Sirion, czyli Hermon;
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
I całą równinę po tej stronie Jordanu na wschodzie aż do Morza Pustego, pod zdrojami Pizga.

< Deuteronomy 4 >