< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
Så hør nu, Israel, de lover og de bud som jeg lærer eder å holde, forat I må leve og komme inn i det land som Herren, eders fedres Gud, gir eder, og ta det i eie!
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
I skal ikke legge noget til det ord jeg byder eder, og I skal ikke ta noget fra, men I skal holde Herrens, eders Guds bud som jeg gir eder.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
I har med egne øine sett hvad Herren gjorde da det hendte det med Ba'al Peor; hver mann som holdt sig til Ba'al Peor, utryddet Herren din Gud av din midte,
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
men I som holdt fast ved Herren eders Gud, I lever alle den dag idag.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Se, jeg har lært eder lover og bud, således som Herren min Gud bød mig, forat I skal gjøre efter dem i det land I drar inn i og skal ta i eie.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
Så skal I da ta vare på dem og holde dem; det vil bli regnet for visdom og forstand hos eder av andre folk; for når de får høre om alle disse lover, vil de si: Sannelig, et vist og forstandig folk er dette store folk.
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
For hvor finnes det et folk, om det er aldri så stort, som har guder som er det så nær som Herren vår Gud er oss, så titt vi kaller på ham?
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Og hvor finnes det et folk, om det er aldri så stort, som har så rettferdige lover og bud som hele denne lov jeg legger frem for eder idag?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Vokt dig bare og ta dig vel i akt at du ikke glemmer det dine øine har sett, så det ikke går ut av din hu alle ditt livs dager, men kunngjør det for dine barn og dine barnebarn,
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
det du så den dag du stod for Herrens, din Guds åsyn ved Horeb, da Herren sa til mig: Kall folket sammen for mig, forat jeg kan la dem høre mine ord, så de kan lære å frykte mig alle de dager de lever på jorden, og også lære sine barn dem.
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
Da kom I nær til og stod nedenfor fjellet, mens fjellet stod i brennende lue like inn i himmelen, og der var mørke og skyer og skodde.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
Og Herren talte til eder midt ut av ilden; I hørte lyden av ordene, men nogen skikkelse blev I ikke var; I hørte bare lyden.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
Og han forkynte eder sin pakt, som han bød eder å holde, de ti ord; og han skrev dem på to stentavler.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
Og mig bød Herren på samme tid å lære eder lover og bud, som I skal leve efter i det land I drar over til og skal ta i eie.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
Så ta eder nu vel i vare, så sant I har eders liv kjært - for I så ingen skikkelse den dag Herren talte til eder på Horeb midt ut av ilden -
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
at I ikke forsynder eder med å gjøre eder noget utskåret billede, noget slags avgudsbillede, i skikkelse av mann eller kvinne
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
eller av noget firføtt dyr på jorden eller av nogen vinget fugl som flyver under himmelen,
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
eller av noget dyr som kryper på jorden, eller av nogen fisk i vannet nedenfor jorden,
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
og at du ikke, når du løfter dine øine op til himmelen og ser solen og månen og stjernene, hele himmelens hær, lar dig føre vill, så du tilbeder dem og dyrker dem, de som Herren din Gud har tildelt alle folkene under hele himmelen.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
Men eder har Herren tatt og ført ut av jernovnen, av Egypten, forat I skal være hans eiendomsfolk, således som det kan sees på denne dag.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
Og Herren blev vred på mig for eders skyld og svor at jeg ikke skulde få gå over Jordan og ikke komme inn i det gode land som Herren din Gud gir dig til arv.
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
For jeg må dø her i dette land, jeg kommer ikke over Jordan; men I skal gå over den og ta dette gode land i eie.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Ta eder da i vare at I ikke glemmer Herrens, eders Guds pakt, som han har gjort med eder, og gjør eder noget utskåret billede av noget slag; for det har Herren din Gud forbudt dig!
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
For Herren din Gud er en fortærende ild, en nidkjær Gud.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
Når du får barn og barnebarn og I blir gamle i landet, og I forsynder eder med å gjøre noget utskåret billede av noget slag, så I gjør hvad ondt er i Herrens, eders Guds øine og dermed egger ham til vrede,
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
så tar jeg idag himmelen og jorden til vidne mot eder at I visselig snart skal utryddes av det land som I nu drar inn i over Jordan og skal ta i eie; I skal ikke leve mange dager der, men bli helt ødelagt.
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
Herren skal sprede eder blandt folkene, så bare en liten flokk av eder blir tilbake blandt de hedningefolk Herren fører eder bort til.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
Og der skal I dyrke guder som er gjort av menneskehender, stokk og sten, som ikke ser og ikke hører og ikke eter og ikke lukter.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
Der skal I søke Herren din Gud, og du skal finne ham når du søker ham av alt ditt hjerte og av all din sjel.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
Når du er i trengsel, og alle disse ting kommer over dig, i de siste dager, da skal du omvende dig til Herren din Gud og høre på hans røst.
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
For Herren din Gud er en barmhjertig Gud; han skal ikke slippe dig og ikke la dig gå til grunne; han skal ikke glemme den pakt med dine fedre som han tilsvor dem.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
For spør bare om de fremfarne dager, som var før din tid, like fra den dag da Gud skapte menneskene på jorden, og spør fra den ene ende av himmelen til den andre om det er hendt eller hørt noget som er så stort som dette,
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
om noget folk har hørt Guds røst tale midt ut av ilden, således som du har gjort, og er blitt i live,
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
eller om Gud har prøvd på å komme og ta sig et folk midt ut av et annet folk ved prøvelser, ved tegn og undergjerninger og ved krig og med sterk hånd og utrakt arm og store, forferdelige gjerninger, således som du med egne øine har sett Herren eders Gud gjorde med eder i Egypten.
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
Du har fått se alt dette, forat du skal vite at Herren han er Gud, og ingen uten han alene.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
Fra himmelen har han latt dig høre sin røst for å lære dig, og på jorden har han latt dig se sin store ild, og hans ord har du hørt midt ut av ilden.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
Og fordi han elsket dine fedre og utvalgte deres efterkommere, så førte han dig selv med sin store kraft ut av Egypten
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
for å drive ut for dig større og sterkere folk enn du er, og føre dig inn og gi dig deres land til arv, som det kan sees på denne dag.
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
Så skal du da idag vite og ta dig det til hjerte at Herren han er Gud både i himmelen der oppe og på jorden her nede, han og ingen annen.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
Og du skal ta vare på hans lover og hans bud, som jeg gir dig idag, forat det kan gå dig vel og dine barn efter dig, og forat du kan leve mange dager i det land Herren din Gud gir dig til evig eie.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
På den tid skilte Moses ut tre byer på hin side Jordan, på østsiden,
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
forat en manndraper som hadde slått sin næste ihjel av vanvare og uten før å ha båret hat til ham, kunde fly dit - til en av disse byer - og redde livet;
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
det var Beser i ørkenen på sletten for rubenittene, og Ramot i Gilead for gadittene, og Golan i Basan for manassittene.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
Og dette er den lov som Moses la frem for Israels barn;
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
dette er de vidnesbyrd og forskrifter og bud som Moses forkynte Israels barn da de var gått ut av Egypten,
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
på hin side Jordan i dalen midt imot Bet-Peor, i det land som hadde tilhørt amorittenes konge Sihon, han som bodde i Hesbon, og som Moses og Israels barn slo da de var gått ut av Egypten;
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
da inntok de både hans land og Basan-kongen Ogs land, begge amoritterkongenes land på hin side Jordan, på østsiden,
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
fra Aroer, som ligger ved bredden av Arnon-åen, til fjellet Sion, det er Hermon,
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
og hele ødemarken på hin side Jordan, på østsiden, like til Ødemarks-havet nedenfor Pisga-liene.

< Deuteronomy 4 >