< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
And now, thou Israel, here the comaundementis and domes whiche Y teche thee, that thou do tho, and lyue, and that thow entre and welde the lond which the Lord God of youre fadris schal yyue to you.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
Ye schulen not adde to the word which Y speke to you, nether ye schulen take awei `fro it; kepe ye the comaundementis of youre Lord God, which Y comaunde to you.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
Youre iyen sien alle thingis whiche the Lord dide ayens Belphegor; how he alto brak alle the worschiperis `of hym fro the myddis of you.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
Forsothe ye that cleuen to youre Lord God lyuen alle `til in to present day.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Ye witen that Y tauyte you the comaundementis and riytfulnessis, as my Lord God comaundide to me; so ye schulen do tho in the lond whiche ye schulen welde,
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
and ye schulen kepe, and schulen fille in werk. For this is youre wisdom and vndurstondyng bifor puplis, that alle men here these comaundementis, and seie, Lo! a wise puple and vnderstondynge! a greet folk!
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
Noon other nacioun is so greet, `not in noumbre ether in bodili quantite, but in dignite, that hath Goddis neiyynge to it silf, as oure God is redi to alle oure bisechyngis.
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
For whi what other folk is so noble, that it hath cerymonyes and iust domes, and al the lawe which Y schal `sette forth to dai bifor youre iyen?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Therfor kepe thi silf, and thi soule bisili; foryete thou not the wordis whiche thin iyen sien, and falle tho not doun fro thin herte, in alle the daies of thi lijf. Thou schalt teche tho thi sones and thi sones sones.
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
Telle thou the day in which thou stodist bifor thi Lord God in Oreb, whanne the Lord spak to me, and seide, Gadere thou the puple to me, that it here my wordis, and lerne for to drede me in al tyme in which it lyueth in erthe, and teche hise sones.
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
And ye neiyiden to the `roote of the hille, that brente `til to heuene; and derknessis, and cloude, and myist weren therynne.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
And the Lord spak to you fro the myddis of fier; ye herden the vois of hise wordis, and outirli ye sien no fourme.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
And he schewide to you his couenaunt, which he comaundide, that ye schulden do, and `he schewide ten wordis, whiche he wroot in two tablis of stoon.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
And he comaundide to me in that tyme, that Y schulde teche you cerymonyes and domes, whiche ye owen to do in the lond whiche ye schulen welde.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
Therfor kepe ye bisili youre soulis; ye sien not ony licnesse in the dai in which the Lord spak to you in Oreb, fro the myddis of the fier;
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
lest perauenture ye be disseyued and make to you a grauun licnesse, ether an ymage of male, ether of female;
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
a licnesse of alle beestis that ben on erthe, ether of bridis fleynge vndur heuene,
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
and of crepynge beestis that ben moued in erthe, ether of fischis that dwellen vndur the erthe in watris; lest perauenture,
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
whanne thin iyen ben reisid to heuene, thou se the sonne, and moone, and alle the sterris of heuene, and be disseyued bi errour, and worschipe tho, `bi outermer reuerence, and onour, `bi ynner reuerence, `tho thingis whiche thi Lord God made of nouyt, in to seruyce to alle folkis that ben vndur heuene.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
Forsothe the Lord took you, and ledde out of the yrun furneys of Egipt, that he schulde haue a puple of eritage, as it is in `present dai.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
And the Lord was wrooth ayens me for youre wordis, and swoor that Y schulde not passe Jordan, and schulde not entre in to the beeste lond, which he schal yyue to you.
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
Lo! Y die in this erthe; Y schal not passe Jordan; ye schulen passe, and schulen welde the noble lond.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Be thou war, lest ony tyme thou foryete the couenaunt of thi Lord God, which he made with thee, and lest thou make to thee a grauun licness of tho thingis whiche the Lord forbeed to make.
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
For thi Lord God is fier wastynge; `God, a feruent louyere.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
If ye gendren sones, and sones of sones, and ye dwellen in the lond, and ye be disceyued, and make to you ony licnesse, and doen yuel bifor youre Lord God, that ye terren hym to greet wrathe,
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
Y clepe witnesses to dai heuene and erthe, `that is, ech resonable creature beynge in heuene and in erthe, that ye schulen perische soone fro the lond, which ye schulen welde, whanne ye han passid Jordan; ye schulen not dwelle long tyme therynne, but the Lord schal do awey you,
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
and schal scatere `in to alle hethen men, and ye schulen leeue fewe among naciouns, to whiche the Lord schal lede you.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
And there ye schulen serue to goddis, that ben maad bi `the hond of men, to a tre and a stoon, that `seen not, nether heren, nether eten, nether smellen.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
And whanne thou hast souyt there thi Lord God, thou schalt fynde hym; if netheles thou sekist with al the herte, and with al the tribulacioun of thi soule.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
Aftir that alle thingis han founde thee, that ben biforseid, forsothe in the laste tyme, thou schalt turne ayen to thi Lord God, and thou schalt here his vois.
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
For thi Lord God is merciful God; he schal not forsake thee, nethir he schal do awey outirli, nethir he schal foryete the couenaunt, in which he swoor to thi fadris.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
Axe thou of elde daies that weren bifor thee, fro the day in which thi Lord God made of nouyt man on erthe, axe thou fro that oon ende of heuene `til to the tother ende therof, if sich a thing was doon ony tyme, ether if it was euere knowun,
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
that a puple herde the vois of God spekynge fro the myddis of the fier, as thou herdist, and siest;
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
if God `dide, that he entride, and took to him silf a folc fro the middis of naciouns, bi temptaciouns, myraclis, and grete wondris, bi batel, and strong hond, and arm holdun forth, and orrible siytis, bi alle thingis whiche youre Lord God dide for you in Egipt, `while thin iyen sien;
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
that thou schuldist wite, that the Lord hym silf is God, and noon other is, outakun oon.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
Fro heuene he made thee to here his vois, that he schulde teche thee; and in erthe he schewide to thee his grettiste fier, and thou herdist the wordis `of hym fro the myddis of the fier;
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
for he louyde thi fadris, and chees her seed aftir hem. And he ledde thee out of Egipt, and yede bifore in his greet vertu,
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
that he schulde do awei grettiste naciouns, and strongere than thou, in thin entryng, and that he schulde lede thee ynne, and schulde yyue to thee the lond `of hem in to possessioun, as thou seest in `present day.
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
Therfor wite thou to dai, and thenke in thin herte, that the Lord him silfe is God in heuene aboue, and in erthe bynethe, and noon other is.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
Kepe thou hise heestis, and comaundementis, whiche Y comaunde to thee, that it be wel to thee, and to thi sones after thee, and that thou dwelle mych tyme on the lond, which thi Lord God schal yyue to thee.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Thanne Moises departide thre citees biyende Jordan at the eest coost,
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
that he fle to tho, that sleeth his neighbore not wilfuli, and was not enemy bifore oon and `the tother dai, and that he mai fle to summe of these citees;
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
Bosor in the wildirnesse, which is set in the feeldi lond, of the lynage of Ruben; and Ramoth in Galaad, which is in the lynage of Gad; and Golan in Basan, which is in the lynage of Manasses.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
This is the lawe which Moises `settide forth bifor the sones of Israel,
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
and these ben the witnessyngis, and cerymonyes, and domes, whiche he spak to the sones of Israel, whanne thei yeden out of Egipt,
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
biyende Jordan, in the valey ayens the temple of Phegor, in the lond of Seon, kyng of Ammorreis, that dwellide in Esebon, whom Moises killide. And the sones of Israel yeden out of Egipt, and weldiden `the lond of him,
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
and the lond of Og, kyng of Basan, twei kyngis of Ammoreis, that weren biyende Jordan, at the rysyng of the sunne;
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
fro Aroer which is set on the brenke of the stronde of Arnon, `til to the hil of Seon, which is Hermon;
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
thei weldiden al the pleyn biyende Jordan, at the eest coost, `til to the see of wildirnesse, and `til to the rootis of the hil of Phasga.

< Deuteronomy 4 >