< Deuteronomy 4 >
1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
And now O Israel listen to the statutes and to the judgments which I [am] about to teach you to observe so that you may live and you will go and you will take possession of the land which Yahweh [the] God of ancestors your [is] about to give to you.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
Not you must add to the word which I [am] about to command you and not you must diminish from it to keep [the] commandments of Yahweh God your which I [am] about to command you.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
Own eyes your [are] the [ones which] saw [that] which he did Yahweh at Baal Peor for every person who he walked after Baal Peor he destroyed him Yahweh God your from midst your.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
And you who were clinging on Yahweh God your [are] alive all of you this day.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
See - I have taught you statutes and judgments just as he commanded me Yahweh God my to do thus in [the] midst of the land where you [are] about to go there towards to take possession of it.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
And you will take care and you will observe [them] for that [will be] wisdom your and understanding your to [the] eyes of the peoples which they will hear! all the statutes these and they will say certainly [is] a people wise and understanding the nation great this.
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
For who? [is] a nation great which [belongs] to it a god near to it like Yahweh God our in all calling we to him.
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
And who? [is] a nation great which [belongs] to it statutes and judgments righteous like all the law this which I [am] setting before you this day.
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Only take heed to yourself and guard self your exceedingly lest you should forget the things which they have seen eyes your and lest they should depart from heart your all [the] days of life your and you will make known them to children your and to [the] children of children your.
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
[the] day When you stood before Yahweh God your at Horeb when said Yahweh to me assemble to me the people so I may make hear them words my that they will learn! to fear me all the days which they [will be] alive on the land and children their they will teach!
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
And you drew near! and you stood! under the mountain and the mountain [was] burning with fire to [the] heart of the heavens darkness cloud and thick darkness.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
And he spoke Yahweh to you from [the] middle of the fire a sound of words you [were] hearing and a form not you [were] seeing except a voice.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
And he declared to you covenant his which he commanded you to observe [the] ten the words and he inscribed them on two tablets of stone.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
And me he commanded Yahweh at the time that to teach you statutes and judgments to observe you them in the land where you [are] about to pass over there towards to take possession of it.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
And you will take heed exceedingly to selves your for not you saw any form on [the] day [when] he spoke Yahweh to you at Horeb from [the] middle of the fire.
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
Lest you should act corruptly! and you will make for yourselves an image of a form of any figure a likeness of a male or a female.
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
A likeness of any animal which [is] on the earth a likeness of any bird of wing which it flies in the heavens.
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
A likeness of any creeping [thing] on the ground a likeness of any fish which [is] in the waters from under to the earth.
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
And lest you should lift up eyes your the heavens towards and you will see the sun and the moon and the stars all [the] host of the heavens and you will be drawn aside and you will bow down to them and you will serve them which he has assigned Yahweh God your them to all the peoples under all the heavens.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
And you he took Yahweh and he brought out you from [the] furnace of iron from Egypt to become for him a people of inheritance as the day this.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
And Yahweh he was angry with me on words your and he swore to not to pass over I the Jordan and to not to go into the land good which Yahweh God your [is] about to give to you an inheritance.
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
For I [am] about to die in the land this not I [am] about to pass over the Jordan and you [are] about to pass over and you will take possession of the land good this.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Take heed to yourselves lest you should forget [the] covenant of Yahweh God your which he has made with you and you will make for yourselves an image a form of anything which he commanded you Yahweh God your.
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
For Yahweh God your [is] a fire consuming he a God jealous.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
For you will father children and children of children and you will grow old in the land and you will act corruptly and you will make an image of a form of anything and you will do the evil in [the] eyes of Yahweh God your to provoke to anger him.
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
I call as witnesses against you this day the heavens and the earth that certainly you will perish! quickly from on the land where you [are] about to pass over the Jordan there towards to take possession of it not you will prolong! days on it for utterly you will be destroyed!
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
And he will scatter Yahweh you among the peoples and you will be left men of number among the nations where he will drive away Yahweh you there towards.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
And you will serve there gods [the] work of [the] hands of a human wood and stone which not they see! and not they hear! and not they eat! and not they smell!
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
And you will seek from there Yahweh God your and you will find [him] for you will seek him with all heart your and with all being your.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
When it is distress to you and they will come upon you all the things these at [the] end of the days and you will return to Yahweh God your and you will listen to voice his.
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
For [is] a God compassionate Yahweh God your not he will abandon you and not he will destroy you and not he will forget [the] covenant of ancestors your which he swore to them.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
That ask please to days former which they were before you from the day when he created God - humankind on the earth and to from [the] end of the heavens and to [the] end of the heavens ¿ has it happened like the thing great this or ¿ has it been heard like it.
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
¿ Has it heard a people [the] voice of a god speaking from [the] middle of the fire just as you have heard you and has it lived?
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
Or - ¿ has it attempted a god to come to take for itself a nation from [the] midst of a nation by trials by signs and by wonders and by battle and by a hand strong and by an arm outstretched and by terrors great like all that he did for you Yahweh God your in Egypt to eyes your.
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
You you were shown to know that Yahweh he [is] God there not [is] still more from to alone him.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
From the heavens he caused to hear you voice his to discipline you and on the earth he showed you fire his great and words his you heard from [the] middle of the fire.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
And because that he loved ancestors your and he chose offspring his after him and he brought out you by own presence his by power his great from Egypt.
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
To dispossess nations great and mighty more than you from before you to bring in you to give to you land their an inheritance as the day this.
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
And you will know this day and you will bring back to heart your that Yahweh he [is] God in the heavens above and on the earth beneath there not [is] still more.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
And you will keep statutes his and commandments his which I [am] commanding you this day that it will go well for you and for children your after you and so that you may prolong days on (the land *L(abh)*) which Yahweh God your [is] about to give to you all the days.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Then he set apart Moses three cities on [the] other side of the Jordan [the] rising of towards [the] sun.
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
To flee there towards a killer who he will kill neighbor his with no knowledge and he not [was] hating him from yesterday [the] third day and he will flee to one of the cities these and he will live.
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
Bezer in the wilderness in [the] land of the plain for the Reubenite[s] and Ramoth in Gilead for the Gadite[s] and Golan in Bashan for the Manassite[s].
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
And this [is] the law which he set Moses before [the] people of Israel.
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
These [are] the testimonies and the statutes and the judgments which he spoke Moses to [the] people of Israel when came out they from Egypt.
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
On [the] other side of the Jordan in the valley opposite to Beth Peor in [the] land of Sihon [the] king of the Amorite[s] who [was] dwelling in Heshbon whom he struck down Moses and [the] people of Israel when came out they from Egypt.
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
And they took possession of land his and [the] land of - Og [the] king of Bashan [the] two [the] kings of the Amorite[s] who [was] on [the] other side of the Jordan [the] rising of [the] sun.
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
From Aroer which [is] on [the] edge of [the] wadi of Arnon and to [the] mountain of Siyon that [is] Hermon.
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
And all the Arabah [the] other side of the Jordan east-wards and to [the] sea of the Arabah under [the] slopes of Pisgah.