< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
Сега слушай, Израилю, повеленията и съдбите, които ви уча да вършите, за да живеете, и да влезете и наследите земята, която ви дава Господ Бог на бащите ви.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
Да не притурите нищо на думите, които ви заповядвам, нито да отнемате от тях, за да пазите заповедите на Господа нашият Бог, които ви заповядвам.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
Очите ви са видели що направи Господ, поради Ваалфегора; защото Господ вашият Бог изтреби изсред вас всичките човеци, които се поведоха по Ваалфегора.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
А вие, които сте се привързали при Господа вашият Бог, всички сте живи днес.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Ето, аз ви научих повеления и съдби, според както Господ моят Бог ми заповяда, за да вършите според тях в земята, в която влизате да я наследите.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
И тъй, пазете и вършете ги; защото това е мъдростта ви и благоразумието ви пред очите на племената, които, като чуят за всички тия повеления, ще рекат: Ето, мъдри и разумни люде са тия на тоя велик народ.
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
Защото кой народ е толкова велик щото да има бог тъй близо при себе си, колкото е Иеова нашият Бог близо при нас всеки път, когато Го призоваваме?
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Или кой народ е толкова велик щото да има такива справедливи повеления и съдби, какъвто и целият тоя закон, който излагам пред вас днес?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Само внимавай на себе си и пази добре душата си, да не би да забравиш делата, които очите ти са видели, и да не би да се изгубят от сърцето ти, през всичките дни на живота ти; но предавай ги на чадата си и на внуците си;
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
предавай им за деня, в който ти застана пред Господа твоя Бог на Хорив, когато Господ ми каза: Събери Ми людете, и ще ги направя да чуят думите Ми, за да се научат да се боят от Мене през всичкото време догдето живеят на земята, и те да учат чадата си на това.
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
Вие се приближихте и застанахте под планината; и планината гореше в огън до сред небето, и имаше тъмнина, облак и мрак.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
Тогава Господ ви говори изсред огъня; вие чухте гласа на думите, но не видяхте никакъв образ; само глас чухте.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
И Той ви изяви завета Си, който ви заповяда да вършите, сиреч, десетте заповеди; и написа ги на две каменни плочи.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
И в онова време Господ ми заповяда да ви науча повеления и съдби, за да ги вършите в земята, към която преминавате да я притежавате.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
Прочее, внимавайте добре на себе си, (защото в деня, когато Господ ви говори на Хорив изсред огъня вие не видяхте никакъв образ),
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
да не би да се развратите и си направите идол, подобие на някой образ, подобие на мъж или на жена,
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
подобие на някое животно, което е на земята, подобие на някоя крилата птица, която лети на небето,
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
подобие на нещо, което пълзи по земята, подобие на някоя риба, която е във водите под земята;
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
и да не би, като подигнеш очи към небето, и видиш слънцето и луната, звездите и цялото небесно множество, да се мамиш, та да им се кланяш и да служиш на тях, които Господ твоят Бог разпредели на всичките народи под цялото небе.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
А вас взе Господ и ви изведе из железарската пещ, из Египет, да Му бъдете люде за наследство, както сте и днес.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
При това, Господ се разгневи на мене поради вас, и закле се да не премина Иордан и да не вляза в оная добра земя, който Господ твоят Бог ти дава за наследство,
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
но да умра в тая земя; аз няма да премина Иордан; а вие ще преминете и ще завладеете оная добра земя.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Внимавайте на себе си да не забравяте завета, който Господ вашият Бог направи с вас, да не би да си направите идол, подобие на нещо, което Господ твоят Бог ти е запретил;
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
защото Господ твоят Бог е огън пояждащ, Бог ревнив.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
Когато ти се родят чада и внуци, ако, като живеете дълго време на земята, се развратите и направите идол, образ на нещо и вършите зло пред Господа твоя Бог и Го разгневите,
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
днес викам небето и земята да свидетелствуват против вас, че непременно скоро ще изчезнете от земята, за превземането на която вие преминавате Иордан; няма да живеете дълго време в нея, а съвсем ще бъдете изтребени.
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
Господ ще ви разпръсне между племената, и ще останете малочислени между ония народи, всред които Господ ще ви отведе.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
Там ще служите на богове, дело на човешки ръце, на дърво и камък, които нито виждат нито чуват, нито ядат нито миришат.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
Но ако от там потърсите Господа твоя Бог, всеки от вас ще го намери, ако го потърси с цялото си сърце и с цялата си душа.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
Когато се намериш в скръб, и всичко това те постигне, ако най-после се обърнат към Господа твоя Бог и послушат гласа Му,
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
то, понеже Господ твоят Бог е Бог милостив, той няма да те остави, нито ще те изтреби, нито ще забрави завета, за който се е клел на бащите ти.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
Защото попитай сега за миналите времена, които бяха преди тебе, от деня когато Бог създаде човека на земята, и попитай от единия край на небето до другия: ставало ли е такова нещо, като това велико дело, или чувало ли се е подобно на него?
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
Люде чули ли са някога Божия глас да говори изсред огън, както ти си чул, и да останат живи?
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
Или предприел ли е Бог да дойде и вземе за себе си народ изсред друг народ, чрез изпитни, знамения и чудеса, и чрез бой, чрез силна ръка, чрез издигната мишца, и чрез големи ужаси, според всичко, което Господ вашият Бог е сторил за вас в Египет пред очите ви?
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
На тебе се даде да видиш това, за да познаеш, че Иеова, Той е Бог, и няма друг освен Него.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
За да те научи, Той те направи да чуеш гласа Му от небето, и показа ти на земята великия Си огън, и ти чу думите Му изсред огъня.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
И понеже Той обичаше бащите ти, за това избра тяхното потомство след тях, и с присъствието Си чрез голямата Си сила те изведе из Египет,
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
за да изгони от пред тебе народи по-големи и по-силни от тебе, да те въведе в земята им и да ти я даде в наследство, както прави днес.
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
Познай, прочее, днес и вложи в сърцето си, че Иеова е Бог на небето горе и на земята долу; няма друг.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
И пази повеленията Му и заповедите Му, които днес ти заповядвам, за да благоденствуваш, ти и потомците ти след тебе, и за всегда да се продължат дните ти на земята, който Господ твоят Бог ти дава.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Тогава Моисей отдели от града оттатък Иордан към изгрева на слънцето,
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
за да прибягва там оня убиец, който убие ближния си по погрешка, без да го е мразил по-напред, и като побегне в един от тия градове, да остане жив.
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
Те бяха: Восор в пустинята, в полянската земя на рувимците, Рамот в Галаад, в земята на гадците и Голан във Васан, в земята на манасийците.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
И ето законът, който Моисей изложи пред израилтяните;
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
ето, заявленията, повеленията и съдбите, които Моисей изказа на израилтяните, когато бяха излезли из Египет
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
оттатък Иордан, в долината срещу Вет-фегор, в земята на аморейския цар Сион, който живееше в Есевон, когото Моисей и израилтяните поразиха, след като бяха излезли из Египет,
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
като превзеха земята му и земята на васанския цар Ог, двамата аморейски царе, които бяха оттатък Иордан към изгрева на слънцето,
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
от Ароир, който е при устието на реката Арнон, до планината Сион (която е Ермон),
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
и цялото поле оттатък Иордан на изток, до морето на полето, под Асдот-фасга.

< Deuteronomy 4 >