< Deuteronomy 33 >

1 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
Eyi ne nhyira a Onyankopɔn nipa Mose de hyiraa Israelfo no ansa na ɔrewu:
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
Ose, “Awurade fi Sinai bae ofi Seir baa wɔn so; ɔhran fi Paran bepɔw so. Ɔde akronkronfo pii bae fi anafo fam ne mmepɔw nsian so.
3 Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
Nokware ni, wo na wodɔ nnipa no, akronkronfo nyinaa wɔ wo nsam. Wɔn nyinaa kotow wo nan ase, na wonya nkyerɛkyerɛ fi wo hɔ,
4 òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
mmara a Mose de maa yɛn no; Yakob nkurɔfo agyapade.
5 Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Ɔyɛɛ ɔhene wɔ Yeshurun bere a nnipa no ntuanofo hyiae, wɔne Israel mmusuakuw no.
6 “Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
“Ma Ruben nya nkwa na onwu, na mma ne nkurɔfo so nhuan.”
7 Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
Na ɔkaa eyi faa Yuda ho: “Tie, Awurade, tie Yuda sufrɛ; fa no brɛ ne nkurɔfo. Ɔde nʼankasa nsa bɔ ne ho ban. Ao, yɛ ne boafo tia nʼatamfo!”
8 Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
Asɛm a ɔka faa Lewi abusuakuw ho: “Awurade, wode ade kronkron ama wʼasomfo nokwafo Lewifo. Wosɔɔ wɔn hwɛe wɔ Masa wɔne wɔn koe wɔ Meriba asu ho.
9 Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
Lewifo tiee wʼasɛm bɔɔ wʼapam no ho ban. Wodii wo nokware sen sɛnea wodii wɔn awofo, abusuafo ne wɔn mma nokware.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
Afei, ma wɔnkyerɛ Yakob wo mmara no. Ma wɔmfa wo nkyerɛkyerɛ no mma Israelfo. Wɔde aduhuam bɛba wʼanim Abɛbɔ ɔhyew afɔre wɔ afɔremuka so.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
Hyira Lewifo, Ao Awurade na ma wɔn nsa ano nnwuma nsɔ wʼani. Bubu wɔn atamfo; bɔ wɔn atamfo hwe fam a wɔnsɔre bio.”
12 Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
Asɛm a Mose ka faa Benyamin abusuakuw ho: “Ma Awurade dɔ nnye ntin wɔ Benyamin nkurɔfo mu, efisɛ ɔbɔ wɔn ho ban daa nyinaa, na nea Awurade dɔ no no nhome wɔ ne nwini ase daa.”
13 Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
Asɛm a Mose ka faa Yosef mmusuakuw ho: “Awurade mfa ne sorosoro bosu a ɛsom bo ne bun mu nsu a efi asase ase no, nhyira wɔn nsase.
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
Ɔmfa ne nnepa efi owia mu ba ne adonne a ebetumi apue afi ɔsram so;
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
ne nnɔbae pa a efi tete mmepɔw mu ne nea abu so wɔ nkoko a etim hɔ daa mu
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
ne akyɛde a ɛso nni a efi asase ne ne mayɛ mu, ne adom a efi nea na ɔte nwura a ɛhyew mu no. Saa nhyira yi nyinaa mmra Yosef ti so, nea ɔyɛ ne nuanom mu ɔheneba no anintɔn mu.
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
Yosef sɛ nantwinini a ɔyɛ abakan wɔ ahenni mu. Ne ahoɔden te sɛ ɔtrɔm mmɛn. Ɔde bɛwowɔ aman no, wɔn a wɔwɔ asase ano no mpo. Eyinom ne Efraim mpem du du no; eyinom ne Manase mpempem no.”
18 Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
Asɛm a Mose ka faa Sebulon ne Isakar mmusuakuw ho: “Sebulon asefo, munni anigye wɔ mo adifi mu. Isakar asefo, munni anigye wɔ mo ntamadan mu.
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
Wɔbɛfrɛ nnipa ahorow akɔ bepɔw no so kɔbɔ trenee afɔre wɔ hɔ; wobefi po mu adenya mmoroso mu ato pon afi ademude a ahintaw wɔ nwea mu.”
20 Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
Asɛm a Mose ka faa Gad abusuakuw ho: “Nhyira nka obi a ɔtrɛw Gad mantam mu! Gad te hɔ sɛ gyata a ɔretetew abasa anaa eti.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
Gad nkurɔfo paw asase pa no maa wɔn ho; ɔkannifo kyɛfa na wɔde maa wɔn. Bere a nkurɔfo no mpanyimfo hyiae no, wɔyɛɛ Awurade atɛntrenee apɛde no, ne nʼatemmu a ɛfa Israelfo ho no.”
22 Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
Asɛm a Mose ka faa Dan abusuakuw ho: “Dan yɛ gyata ba a, ɔrepue afi Basan.”
23 Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
Asɛm a Mose ka faa Naftali abusuakuw ho: “Naftali wɔ adom bebree na Awurade nhyira ayɛ wo ma; ɔtare no anafo fam bɛyɛ wo kyɛfa.”
24 Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
Asɛm a Mose ka faa Aser abusuakuw ho: “Mma no mu nea wɔahyira no koraa ne Aser; wɔmma ne nuanom mpɛ nʼasɛm, na ɔmfa ngo nguare nʼanan ase.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
Wʼapon ho nkyerewa nyɛ dade ne kɔbere mfrafrae; wʼahoɔden ne wo nkwanna bɛsae so.
26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
“Onyankopɔn biara nni hɔ sɛ Yeshurun Nyankopɔn; a ɔnam ɔsorosoro ne nʼahenni mu mununkum so ba bɛboa wo.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
Onyankopɔn a ɔwɔ hɔ daa yɛ wo guankɔbea; nea ɛwɔ ase no ne abasa a ɛwɔ hɔ daa no. Ɔbɛpam wʼatamfo afi wʼanim; ɔbɛka se, ‘Sɛe wɔn!’
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
Enti, Israel bɛtena ase dwoodwoo; Yakob benya bammɔ wɔ asase a atoko ne nsa foforo wɔ so, faako a ɔsoro bosu gugu.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”
Nhyira nka mo, Israel! Hena na ɔte sɛ mo, nnipa a Awurade agye mo nkwa. Ɔyɛ mo nkatabo ne boafo ne mo anuonyam afoa! Mo atamfo bɛkotow mo anim, na moatiatia wɔn sorɔnsorɔmmea.”

< Deuteronomy 33 >